< Wuok 7 >

1 Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Ne, aseketi kaka Nyasaye ni Farao, kendo Harun owadu biro bedoni janabi.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Wò ó, Èmi ti ṣe ọ bí Ọlọ́run fún Farao, Aaroni arákùnrin rẹ ni yóò jẹ́ agbẹnusọ rẹ.
2 Nyaka iwach gik moko duto ma achiki, kendo Harun owadu nonyis Farao mondo owe jo-Israel owuog e pinye.
Ìwọ yóò sì sọ ohun gbogbo tí Èmi ti pàṣẹ fún ọ, Aaroni arákùnrin rẹ yóò sísọ fún Farao kí ó jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ rẹ̀.
3 Abiro keto chuny Farao bedo matek, ma kata obedo ni abiro nwoyo honni kod ranyisi e piny Misri,
Ṣùgbọ́n èmi yóò sé Farao lọ́kàn le. Bí Mo tilẹ̀ ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu ni Ejibiti,
4 to Farao ok nowinju. Omiyo anasand jo-Misri gi masiche madongo kakumogi malich mi anagol joga ma jo-Israel e piny Misri.
síbẹ̀ òun kì yóò fi etí sí ọ. Nígbà náà ni Èmi yóò gbé ọwọ́ mi lé Ejibiti, pẹ̀lú agbára ìdájọ́ ńlá mi ni èmi yóò mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.
5 Kendo jo-Misri nongʼe ni an Jehova Nyasaye e kinde ma anakumgi ka agolo jo-Israel kuomgi.”
Àwọn ará Ejibiti yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa ní ìgbà tí mo bá na ọwọ́ mi jáde lé Ejibiti, tí mo sì mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò níbẹ̀.”
6 Musa kod Harun notimo mana kaka Jehova Nyasaye nochikogi.
Mose àti Aaroni sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn.
7 E kinde mane giwuoyo gi Farao, Musa ne ja-higni piero aboro to Harun to ne ja-higni piero aboro gadek.
Mose jẹ́ ọmọ ọgọ́rin ọdún Aaroni sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́tàlélọ́gọ́rin ni ìgbà tí wọ́n bá Farao sọ̀rọ̀.
8 Jehova Nyasaye nowacho ne Musa kod Harun niya,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni,
9 “Ka Farao onyisou ni mondo utim hono moro, to in Musa nyis Harun ni, ‘Kaw ludhi kendo dire piny e nyim Farao,’ kendo obiro lokore thuol.”
“Ní ìgbà tí Farao bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ ṣe iṣẹ́ ìyanu kan,’ sọ fún Aaroni ní ìgbà náà pé, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ níwájú Farao,’ yóò sì di ejò.”
10 Kuom mano, Musa kod Harun ne odhi ir Farao mi gitimo mana kaka Jehova Nyasaye nochikogi. Harun nodiro ludhe piny e nyim Farao kod jodonge mi nolokore thuol.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn, Aaroni ju ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀ ní iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò.
11 Farao noluongo jorieko kod ajuoke mag Misri mine gitimo gik machal gi mane Harun otimo ka gitiyo gi teko mag yedhegi mopondo.
Farao sì pe àwọn amòye, àwọn oṣó àti àwọn onídán ilẹ̀ Ejibiti jọ, wọ́n sì fi idán wọn ṣe ohun tí Mose àti Aaroni ṣe.
12 Ngʼato ka ngʼato kuomgi nodiro ludhe piny kendo nolokore thuol. To ludh Harun nomwonyo ludhegigo.
Ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sọ ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò. Ṣùgbọ́n ọ̀pá Aaroni gbé ọ̀pá tiwọn mì.
13 To kata kamano, chuny Farao ne odoko matek kendo ne ok onyal winjogi mana kaka Jehova Nyasaye ne osewacho.
Síbẹ̀ ọkàn Farao sì yigbì, kò si fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
14 Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Chuny Farao pod tek, odagi weyo joga mondo odhi.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọkàn Farao ti di líle, ó kọ̀ láti jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà ó lọ.
15 Dhi ir Farao gokinyi ka odhi e aora. Rite e bath aora Nael mondo irom kode, bende kaw luth mane olokore thuol cha e lweti.
Tọ Farao lọ ni òwúrọ̀ kùtùkùtù bí ó ti ń lọ sí etí odò, dúró ni etí bèbè odò Naili láti pàdé rẹ, mú ọ̀pá rẹ tí ó di ejò ni ọwọ́ rẹ.
16 Eka inyise ni, ‘Jehova Nyasaye, ma Nyasach jo-Hibrania, oseora mondo anyisi niya: We joga odhi, mondo gilama e thim. To nyaka chop koroni pok iwinjo.
Sọ fún un pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu rán mi sí ọ láti sọ fún ọ pé, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè sìn mi ni aginjù. Ṣùgbọ́n títí di àkókò yìí, ìwọ kò gba.
17 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: Ranyisini biro miyo ingʼe ni an Jehova Nyasaye: Abiro chwado pi aora Nael gi luth mantie e lwetani kendo pigno biro lokore remo.
Èyí ni Olúwa wí, nípa èyí ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa. Wò ó, èmi yóò fi ọ̀pá ti ó wà ní ọwọ́ mi, èmi yóò ná omi tí ó wà nínú odò Naili yóò sì di ẹ̀jẹ̀.
18 Rech manie aora Nael biro tho, kendo aora biro dungʼ, jo-Misri ok nomodh pigno.’”
Àwọn ẹja tí ó wà nínú odò Naili yóò kú, odò náà yóò sì máa rùn, àwọn ará Ejibiti kò sì ni lè mu omi rẹ̀.’”
19 Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Nyis Harun ni, ‘Kaw ludhi mondo irie badi ewi pige mag Misri, ma gin aore matindo kod madongo, yewni kod kuonde duto mag kano pi, kendo gibiro lokore remo.’ Remo biro bedo kamoro amora e piny Misri nyaka ei agulni molos gi kite.”
Olúwa sọ fún Mose, “Sọ fún Aaroni, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì na ọwọ́ rẹ jáde lórí àwọn omi Ejibiti. Lórí àwọn odò kéékèèké àti odò ńlá, lórí àbàtà àti adágún omi, wọn yóò sì di ẹ̀jẹ̀.’ Ẹ̀jẹ̀ yóò wà ni ibi gbogbo ni Ejibiti, àní nínú ọpọ́n àti nínú kete omi àti nínú ìkòkò tí a pọn omi sí nínú ilé.”
20 Musa kod Harun notimo mana kaka Jehova Nyasaye nochikogi. Notingʼo ludhe e nyim Farao kod jodonge duto mi ochwado aora Nael kendo pige duto nolokore remo.
Mose àti Aaroni sí ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Ó gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè ni iwájú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ó sì lu omi odò Naili, omi odò náà sì yípadà sí ẹ̀jẹ̀.
21 Rech manie aora Nael notho, kendo aora nodungʼ marach ma jo-Misri ne ok nyal modho pige. Remo ne nitie kamoro amora e piny Misri.
Ẹja inú odò Naili sì kú, odò náà ń rùn gidigidi tí ó fi jẹ́ pé àwọn ará Ejibiti kò le è mu omi inú rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ sì wà ni ibi gbogbo ni ilẹ̀ Ejibiti.
22 To ajuoke mag Misri notimo mana gik machal kamano gi tijegi mag ajuoke mi chuny Farao nomedo doko matek; ne ok onyal winjo wach Musa kod Harun mana kaka Jehova Nyasaye nosewacho.
Ṣùgbọ́n àwọn apidán ilẹ̀ Ejibiti sì ṣe bákan náà pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn, ọkàn Farao sì yigbì síbẹ̀ kò sì fetí sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
23 To kata kamano nodok e kare mar dak, kendo ne ok odewo wechegi.
Dípò bẹ́ẹ̀, ó yíjú padà, ó sì lọ sí ààfin rẹ̀, kò sì jẹ́ kí àwọn nǹkan wọ̀nyí wà ni oókan àyà rẹ̀.
24 Jo-Misri duto nokunyo bath aora Nael mondo giyud pi modho, nikech ne ok ginyal modho pi aorano.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí í gbẹ́ etí odò Naili láti wá omi tí wọn yóò mu, nítorí wọn kò le è mu omi tí ó wà nínú odò náà.
25 Ndalo abiriyo norumo bangʼ ka Jehova Nyasaye nosechwado aora Nael.
Ọjọ́ méje sì kọjá ti Olúwa ti lu odò Naili.

< Wuok 7 >