< Wuok 15 >
1 Eka Musa gi jo-Israel nowero wendni ni Jehova Nyasaye: “Abiro wer ni Jehova Nyasaye, nimar nyinge oromo mi duongʼ. Oseumo faras kod jariembne ei nam.
Nígbà náà ni Mose àti àwọn ọmọ Israẹli kọ orin yìí sí Olúwa, Èmi yóò kọrin sí Olúwa, nítorí òun pọ̀ ní ògo. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún ni ó ti sọ sínú Òkun.
2 “Jehova Nyasaye e tekrena bende en e wenda; kendo osebedo warruokna. Anapake nimar en Nyasacha, ma Nyasach wuora, kendo abiro miyo nyinge duongʼ.
Olúwa ni agbára àti orin mi; òun ti di Olùgbàlà mi, òun ni Ọlọ́run mi, èmi ó yìn ín, Ọlọ́run baba mi, èmi ó gbé e ga.
3 Jehova Nyasaye en jalweny; Jehova Nyasaye e nyinge.
Ológun ni Olúwa, Olúwa ni orúkọ rẹ,
4 Noimo geche Farao kod jolwenje ei Nam Makwar. Jodong Farao mogen duto noimo e nam makwar.
kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti ogun rẹ̀ ni ó mú wọ inú Òkun. Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáfáfá jùlọ ni ó rì sínú Òkun Pupa.
5 Pige matut oseimogi duto, kendo gisenimo nyaka e bwo pi mana ka kidi.
Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀; wọ́n sì rì sí ìsàlẹ̀ omi òkun bí òkúta.
6 “Yaye Jehova Nyasaye, lweti ma korachwich ne nigi teko maduongʼ. Yaye, Jehova Nyasaye lweti ma korachwich ema isetiekogo wasigu.
“Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, pọ̀ ní agbára. Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, fọ́ àwọn ọ̀tá túútúú.
7 “Kuom tekoni maduongʼ, ne iloyo jogo mane opiem kodi. Ne inyiso mirimbi mager mi nomwonyogi kaka lum.
“Nínú agbára ńlá rẹ ti ó tóbi ìwọ bi àwọn ti ó dìde sí ọ ṣubú. Ìwọ rán ìbínú gbígbóná rẹ; tí ó run wọ́n bí àgémọ́lẹ̀ ìdí koríko.
8 Muya mawuok e umi nomiyo pige ogingore malo. Apaka mar pi nogingore mochungʼ ka kor ot; pige man kuonde matut nochokore e chuny nam.”
Pẹ̀lú èémí imú rẹ ni omi fi ń wọ́jọ pọ̀. Ìṣàn omi dìde dúró bí odi; ibú omi sì dìpọ̀ láàrín Òkun.
9 Jawasigu nosungore kawacho niya, “Abiro lawogi, abiro jukogi. Abiro pogo mwandugi; abiro yako gimoro amora. Abiro golo liganglana kendo lweta biro tiekogi.
Ọ̀tá ń gbéraga, ó ń wí pé, ‘Èmi ó lépa wọn, èmi ó bá wọn. èmi ó pín ìkógun; èmi ó tẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ mi lọ́run lára wọn. Èmi yóò fa idà mi yọ, ọwọ́ mi yóò pa wọ́n run.’
10 Kane ikudho muchi kende, to nam noimogi. Ne ginimo ka chuma e apaka maduongʼ.
Ìwọ fẹ́ èémí rẹ, òkun ru bò wọ́n mọ́lẹ̀. Wọ́n rì bí òjé ni àárín omi ńlá.
11 “En ngʼa machal kodi e kind nyiseche, yaye Jehova Nyasaye? En ngʼa machalo kodi: in miler moloyo, in ma in-gi duongʼ moloyo kendo matimo honni?
Ta ni nínú àwọn òrìṣà tó dàbí rẹ, Olúwa? Ta ló dàbí rẹ: ní títóbi, ní mímọ́ Ẹlẹ́rù ni yìn, tí ń ṣe ohun ìyanu?
12 Ne irieyo badi ma korachwich ma piny omwonyogi.
“Ìwọ na apá ọ̀tún rẹ, ilẹ̀ si gbé wọn mì.
13 “Kuom herani ma ok rum, ibiro telone oganda ma isereso. Kuom tekoni ibiro telonegi nyaka kar dakni maler.
Nínú ìfẹ́ rẹ ti kì í sákí Ìwọ ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn náà tí Ìwọ ti rà padà. Nínú agbára rẹ Ìwọ yóò tọ́ wọn, lọ sí ibi ìjókòó rẹ mímọ́.
14 Pinje biro winjo mi tetni, kihondko biro mako jo-Filistia.
Orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ wọn yóò wárìrì. Ìkáàánú yóò mi àwọn ènìyàn Filistia.
15 Jodong Edom kibaji biro goyo, bende jotend Moab biro tetni, to jo-Kanaan chunygi biro nyosore;
Ìbẹ̀rù yóò mú àwọn ìjòyè Edomu, àwọn olórí Moabu yóò wárìrì. Àwọn ènìyàn Kenaani yóò sì yọ́ dànù.
16 kibaji kod kihondko biro biro kuomgi. Kuom teko mar lweti gibiro lingʼ thi ka kidi, nyaka ogandani kadhi, yaye Jehova Nyasaye, nyaka jogi mane ichweyo kadhi.
Ìbẹ̀rù bojo yóò ṣubú lù wọ́n, nítorí nína títóbi apá rẹ̀ wọn yóò dúró jẹ́ẹ́ láì mira bí i òkúta, títí àwọn ènìyàn rẹ yóò fi rékọjá, Olúwa, títí tí àwọn ènìyàn tí o ti rà yóò fi rékọjá.
17 Yaye Jehova Nyasaye, ibiro kelogi mi gidonji kendo ibiro miyo gibedi ewi godi mar girkeni, ma en kama ne iloso kaka kar dakni, kendo kama ler mar lemo mane iloso gi lweti, yaye Ruoth Nyasaye.
Ìwọ yóò mú wọn wá láti gbìn wọ́n ni orí òkè ti ìwọ jogún, ní ibi ti ìwọ ṣe fún ara rẹ, Olúwa. Láti máa gbé ibi mímọ́ ti ìwọ fi ọwọ́ rẹ gbé kalẹ̀, Olúwa.
18 Jehova Nyasaye biro locho nyaka chiengʼ.”
“Olúwa yóò jẹ ọba láé àti láéláé.”
19 Ka farese Farao gi gecheni kod joidh faresene ne odhi e nam, Jehova Nyasaye nomiyo pi nam odok e wangʼe mi oimogi, to jo-Israel nongʼado nam kawuotho ewi lowo motwo.
Nígbà ti ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ inú Òkun, Olúwa mú kí omi òkun padà bò wọ́n mọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli rìn lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ la òkun kọjá.
20 Eka Miriam janabi madhako ma nyamin Harun, nokawo oyieke e lwete kendo mon duto noluwo bangʼe ka gin gi oyieke kendo ka gimiel.
Miriamu wòlíì obìnrin, arábìnrin Aaroni, mú ohun èlò orin ni ọwọ́ rẹ̀, gbogbo àwọn obìnrin sì jáde tẹ̀lé e pẹ̀lú ìlù òun ijó.
21 Miriam nowernegi niya, “Weruru ni Jehova Nyasaye, nimar otingʼe malo ahinya. Oseimo faras gi jaithne ei nam.”
Miriamu kọrin sí wọn báyìí pé, “Ẹ kọrin sí Olúwa, nítorí òun ni ológo jùlọ. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún, ni òun bi ṣubú sínú Òkun.”
22 Eka Musa notelo ni Israel kagiwuok e Nam Makwar kendo negidhi ei thim mar Shur. Kuom ndalo adek ne giwuotho e thim ma ok giyudo pi.
Nígbà náà ni Mose ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Òkun Pupa lọ sínú ijù Ṣuri. Wọ́n lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú ijù náà, wọn kò sì rí omi.
23 Kane gichopo Mara, ne ok ginyal modho pi makanyo nikech nokech. (Mano emomiyo kanyo iluongo ni Mara.)
Nígbà tí wọ́n dé Mara, wọn kò lè mu omi Mara nítorí omi náà korò. (Nítorí náà ni a ṣe pe ibẹ̀ ni Mara: ibi ìkorò.)
24 Kuom mano ogandano nongʼur ne Musa kawacho niya, “Wabiro modho angʼo?”
Àwọn ènìyàn ń kùn sí Mose wí pé, “Kí ni àwa yóò mu?”
25 Eka Musa noywak ne Jehova Nyasaye kendo Jehova Nyasaye nonyise yien moro. Nobole ei pi mi pi obedo mamit. Kanyo ema Jehova Nyasaye nomiyogie buche kod chike kendo notemogi.
Mose sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi igi kan hàn án, ó sì sọ igi náà sínú omi, omi náà sì dùn. Níbẹ̀ ni Olúwa ti gbé ìlànà àti òfin kalẹ̀ fún wọn, níbẹ̀ ni ó sì ti dán wọn wò.
26 Nowachonegi niya, “Ka uchiko itu maber ne wach Jehova Nyasaye ma Nyasachu ma utimo gima kare e nyim wangʼe, ka urito chikene kendo umako buchene duto, to ok anakel kuomu tuo moro amora mane akelo ne jo-Misri, nimar an Jehova Nyasaye machangou.”
Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí òfin Olúwa Ọlọ́run, ti ìwọ sì ṣe ohun tí ó tọ́ ni ojú rẹ̀, ti ìwọ sì tẹ̀lé ohun tí ó pàṣẹ, ti ìwọ si pa ìlànà rẹ̀ mọ́. Èmi kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí nínú àwọn ààrùn wọ̀n-ọn-nì ti mo mú wá sórí àwọn ará Ejibiti wá sí ara rẹ, nítorí Èmi ni Olúwa ti ó mú ọ láradá.”
27 Eka negichopo Elim, kama ne nitie sokni apar gariyo kod yiende mag othidhe piero abiriyo mine gibworo kanyo machiegni gi pi.
Nígbà ti wọ́n dé Elimu, níbi ti kànga omi méjìlá àti àádọ́rin ọ̀pẹ gbé wà, wọ́n pàgọ́ síbẹ̀ ni etí omi.