< Amos 2 >
1 Jehova Nyasaye wacho niya, “Nikech richo adek ma jo-Moab osetimo, kata richo angʼwen, omiyo ok abi weyo ma ok akumogi. Nikech ne giwangʼo choke mag ruodh Edom molokore buru,
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
2 kuom mano abiro oro mach e piny Moab mondo owangʼ kuonde mochiel motegno mag Kerioth. Jo-Moab biro tho ei lweny mager, ka jolweny giyo sigich lweny kendo tungʼ ywak.
Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
3 Abiro nego ruodh Moab kaachiel gi jotend pinyno duto,” Jehova Nyasaye owacho.
Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
4 Jehova Nyasaye wacho niya, “Nikech richo adek ma jo-Juda osetimo, kata richo angʼwen, omiyo ok abi weyo ma ok akumogi. Nikech gisetamore rito chike Jehova Nyasaye kod buchene, kendo osewuondgi mi gisebaro giluwo bangʼ nyiseche manono mag kweregi,
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
5 kuom mano abiro oro mach e piny Juda, kod kuonde mochiel motegno mag Jerusalem.”
Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
6 Jehova Nyasaye wacho niya, “Nikech richo adek ma jo-Israel osetimo, kata richo angʼwen, omiyo ok abi weyo ma ok akumogi. Nikech ungʼiewo joma kare gi fedha, to joma odhier ma ok nyal chudo, to ungʼiewo gi pat pat.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
7 Unyono jochan piny mana ka buru kendo ok ungʼad bura makare, ne joma odhier. Wuowi gi wuon mare terore gi nyako achiel kendo udwanyo Nyinga Maler.
Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
8 Ginindo piny e lewni mosing but kende mag misango. Divai ma gikawo kuom joma gigoyo faini gimadho e od nyasachgi.
Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
9 “Ne atieko jo-Amor mana ka gineno, kata obedo nine gin roboche ka yiend sida, kendo roteke ka yiend ober. Ne aketho olembene kod tiendene!
“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 Ne agolou e piny Misri, mi atelonu higni piero angʼwen e thim, ni mondo amiu piny jo-Amor.
Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
11 “Ne awalo yawuotu mondo obed jonabi, to moko e dieru naketo mondo obed jo-Nazir. Donge mano en adier, yaye jo-Israel?” Jehova Nyasaye owacho.
“Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
12 “Ne umiyo jo-Nazir omadho divai, kendo nukwero jonabi ni kik gikor wach.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
13 “Sani koro abiro diyou piny kama untie, mana ka cham mopongʼo gari mayiecho gari.
“Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 Joma ongʼeyo ngʼwech sani koro ok bi tony, joma rateke abiro keto bedo mool, bende nyaka jalweny manenore ni ger ok bi konyo ngimane.
Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
15 Kata jadir asere ok noyud thuolo mar ringo, kendo jangʼwech ma jalweny ok noresre, kaachiel gi jalweny moidho faras bende ok notony.
Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
16 To kata mana jolweny mathuondi moloyo noring duge chiengʼno,” Jehova Nyasaye owacho.
Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.