< 2 Samuel 7 >
1 Bangʼe ka ruoth nosedonjo e ode mar ruoth kendo Jehova Nyasaye nosemiye kwe e kinde gi wasike duto mane olwore,
Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.
2 nowacho ni Nathan janabi niya, “Koro anto adak e od ruoth moger gi yiend sida, to Sandug muma mar Nyasaye to osiko e hema.”
Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”
3 Nathan nodwoko ruoth niya, “Gimoro amora manie pachi, to dhi nyime mondo itim, nikech Jehova Nyasaye ni kodi.”
Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
4 Otienono wach mar Jehova Nyasaye ne obiro ni Nathan, kawacho niya,
Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Natani wá pé,
5 “Dhiyo mondo inyis jatichna Daudi niya, ‘Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: In ema digerna ot mondo adagie?
“Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.
6 Pok adak e ot chakre ndalo mane agolo jo-Israel e piny Misri nyaka kawuono. Asebedo kawuotho kuonde miguroe hema mopogore kaka kar dakna.
Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Israẹli gòkè ti ilẹ̀ Ejibiti wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.
7 Kuonde duto masewuothoe gi jo-Israel duto, bende asewachoe gimoro ni jotendgi mane aketo mondo orit joga Israel niya, “Angʼo momiyo pok ugerona ot mar yiend sida?”’
Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Israẹli, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kedari kọ́ ilé fún mi.”’
8 “Omiyo koro wach ni jatichna Daudi niya, ‘Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego wacho kama: Ne agoli e lek kuma ne ikwayoe rombe mondo ibed jatend joga Israel.
“Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli.
9 Asebedo kodi kuonde duto misedhiye, kendo asetieko wasiki duto e nyimi. Koro abiro miyo nyingi bed maduongʼ kaka humb jomadongo manie piny.
Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sá à gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.
10 Kendo abiro chiwo piny ni joga Israel, abiro gurogi mondo gibed gi pinygi giwegi mondo kik chandgi kendo. Jomahundu ok nochak osandgi kendo kaka negitimonegi mokwongo,
Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó tiwọn, wọn kì yóò sì sípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójúmọ́, bí ìgbà àtijọ́.
11 kendo kaka gisetimo nyaka chakre ne ayier jotelo marito joga Israel. Bende abiro miyo ibed gi kwe e kindi gi wasiki duto. “‘Jehova Nyasaye owacho ni en Jehova Nyasaye owuon ema obiro geroni ot.
Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ. “‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ.
12 Ka ndaloni orumo mitho kendo iluwo kwereni to abiro keto kothi moro mondo okaw kari, manobed kothi owuon kendo anagur pinyruodhe.
Nígbà tí ọjọ́ rẹ bá pé, tí ìwọ ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ, èmi yóò sì gbé irú-ọmọ rẹ lékè lẹ́yìn rẹ, èyí tí ó ti inú rẹ jáde wá, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀.
13 En ema noger ot ni nyinga, kendo anagur lochne gi pinyruodhe nyaka chiengʼ.
Òun ó sì kọ́ ilé fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ láéláé.
14 Anabed wuon-gi to enobed wuoda. Ka otimo marach, to anakume, ka achwade gi lwet dhano kendo noyud chwat koa kuom ji.
Èmi ó máa ṣe baba fún un, òun yóò sì máa jẹ́ ọmọ mi. Bí òun bá dẹ́ṣẹ̀, èmi yóò sì fi ọ̀pá ènìyàn nà án, àti ìnà àwọn ọmọ ènìyàn.
15 To herana to ok nogol kuome kaka ne agole kuom Saulo, mane agolo e nyimi.
Ṣùgbọ́n àánú mi kì yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú un kúrò lọ́dọ̀ Saulu, tí èmi ti mú kúrò níwájú rẹ.
16 Odi gi pinyruodhi nosik nyaka chiengʼ e nyima kendo lochni nogurre nyaka chiengʼ.’”
A ó sì fi ìdílé rẹ àti ìjọba rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ títí láé, a ó sì fi ìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ títí láé.’”
17 Nathan nonyiso Daudi weche duto mane ofwenyne.
Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìran yìí, bẹ́ẹ̀ ni Natani sì sọ fún Dafidi.
18 Eka ruoth Daudi nodonjo e hema mobet piny e nyim Jehova Nyasaye mowacho niya, “An to an ngʼa? Yaye Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto, jooda to gin angʼo, momiyo isetimona gigi duto?
Dafidi ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?
19 To ka gima kamano ok oromo e nyim wangʼi, yaye Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto, to isewuoyo kuom gik mabiro timore e od jatichni kinde mabiro. Bende ma e kaka itiyo gi dhano, yaye Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto?
Nǹkan kékeré ni èyí sá à jásí lójú rẹ, Olúwa Olódùmarè; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí ha ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Olódùmarè?
20 “En angʼo ma Daudi dimed wachoni? Nimar ingʼeyo jatichni, yaye Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto.
“Àti kín ní ó tún kù tí Dafidi ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Olódùmarè mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
21 Nikech wach misewacho kendo koluwore gi dwaroni, isetimo tim maduongʼni bende isemiyo ongʼere ni jatichni.
Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
22 “Mano kaka iduongʼ yaye Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto! Onge ngʼama chalo kodi, kendo onge Nyasaye moro makmana in, kaka wasewinjo gi itwa wawegi?
“Ìwọ sì tóbi, Olúwa Olódùmarè! Kò sì sí ẹni tí ó dàbí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.
23 Ere oganda machal gi jogi Israel? Bende nitiere oganda moro e piny mane Nyasaye osedhi moreso mondo obed joge owuon kendo mosemiyogo nyinge ongʼere mi otimogo honni madongo kendo malich koriembo ogendini gi nyisechegi ka gia e nyim joge, mane oreso kogolo Misri?
Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli, àwọn tí Ọlọ́run lọ rà padà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Ejibiti wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.
24 Iseguro loch jogi ma jo-Israel kaka jogi iwuon nyaka chiengʼ to in yaye Jehova Nyasaye isebedo Nyasachgi.
Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.
25 “To koro Jehova Nyasaye rit singruok misetimo gi jatichni kod ode osik nyaka chiengʼ. Tim mana kaka ne isingori,
“Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.
26 mondo nyingi obed maduongʼ nyaka chiengʼ. Eka ji biro wacho ni, ‘Jehova Nyasaye Maratego en Nyasach jo-Israel!’ Kendo dhood jatichni Daudi nogurre e nyimi.
Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Israẹli!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dafidi ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.
27 “Yaye Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach Israel, isefwenyo ni jatichni wechegi kiwacho ni, ‘Abiro geroni ot.’ Omiyo jatichni osebet gi chir mar lami gi lemoni.
“Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.
28 Yaye Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto, in Nyasaye! Wecheni ogen, kendo isesingo gik mabeyogi ni jatichni.
Ǹjẹ́, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
29 To koro yie mondo igwedh od jatichni, mondo osik e nyimi nyaka chiengʼ; nimar, yaye Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto, isewuoyo to gi gwethni, isegwedho dhood jatichni gweth mosiko.”
Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ́ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa Olódùmarè, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípasẹ̀ ìbùkún rẹ.”