< 2 Samuel 24 >
1 Mirima nochako omako Jehova Nyasaye kod Israel omiyo nochwalo Daudi motimo gimoro madihinygi, kowachone niya, “Dhiyo mondo ikwan jo-Israel gi jo-Juda.”
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
2 Omiyo ruoth nowachone Joab kod jotend jolweny mane ni kode niya, “Dhiuru e dhoudi duto mag Israel kochakore Dan nyaka Bersheba mondo ukwan jolweny, eka angʼe ni gin ji adi.”
Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
3 To Joab nodwoko ruoth niya, “Mad Jehova Nyasaye ma Nyasachi med jolweny nyadi mia achiel ka ruodha ma en ruoth neno gi wangʼe. To en angʼo momiyo ruoth ma en ruodha didwar timo gima chal kama?”
Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
4 Kata kamano ruoth notamo Joab gi jotelo mag lweny; kuom mano ne giwuok e nyim ruoth mondo gidhi gikwan jolweny e Israel.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
5 Bangʼ kane gisengʼado aora Jordan, negibuoro machiegni gi Aroer, man yo milambo mar dala manie geng holo, eka negikadho Gad ma gidhi nyaka Jazer.
Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
6 Negidhi Gilead kod gwenge mag Tatim Hodshi, mi gikadho nyaka Dan Jaan kendo negigomo ka gichiko Sidon.
Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
7 Bangʼe negichiko dala mochiel gohinga mar Turo kod dala duto mag jo-Hivi kod mago mag jo-Kanaan. Mogik, negidhi Bersheba man Negev e piny Juda.
Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
8 Bangʼ dweche ochiko gi ndalo piero ariyo kane gisewuotho e piny duto, negidwogo Jerusalem.
Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
9 Joab nokelo ne ruoth kar kwan jolweny kama: Kuom jo-Israel ne nitie ji alufu mia aboro maroteke mane nyalo kedo gi ligangla to kuom jo-Juda ne nitie ji alufu mia abich.
Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
10 Daudi chunye nochandore bangʼ kane osekwano jolweny, mi nowachone Jehova Nyasaye niya, “Asetimo richo maduongʼ kuom gima asetimoni. Yaye Jehova Nyasaye, akwayi mondo igol richoni kuom jatichni, nimar asetimo gima ofuwo.”
Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
11 Kane Daudi pok ochiewo kinyne gokinyi, wach Jehova Nyasaye nosebiro ne Gad janabi, mane en jakor wach mar Daudi:
Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
12 “Dhiyo iwach ni Daudi ni, ‘Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: Aketo weche adek e nyimi, yier achiel kuomgi monego atimni.’”
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
13 Omiyo Gad nodhi ir Daudi mowachone niya, “Diyier mondo kech omak piny kuom higni adek? Koso diyier dweche adek kiringo wasiki malawi? Koso diyier ndalo adek mag masira? Koro par ane mondo imiya dwoko matero ni ngʼama ne oora.”
Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
14 Daudi nodwoko Gad niya, “An-gi chuny lit ahinya. Ber mondo alwar e lwet Jehova Nyasaye, nikech ngʼwonone duongʼ, to kik iweya alwar e lwet ji.”
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
15 Omiyo Jehova Nyasaye nokelo masira kuom jo-Israel chakre okinyino nyaka kinde mane oketi norumo, kendo ji alufu piero abiriyo notho chakre Dan nyaka Bersheba.
Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
16 To kane malaika orieyo bade mondo oketh Jerusalem, chuny Jehova Nyasaye ne lit nikech masirano mi nowacho ni malaika mane nego ji niya, “Oromo! Dwok lweti piny.” Malaika mar Jehova Nyasaye noyudo ochungʼ e kar dino cham mar Arauna ja-Jebus.
Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
17 Kane Daudi oneno malaika mane nego ji, nowachone Jehova Nyasaye niya, “An ema asetimo richo kendo aseketho. Magi to mana rombe, angʼo magiseketho? Akwayi ni an ema ikuma kaachiel gi joga to kik iwe masira odongʼ kuom jogi.”
Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
18 Chiengʼno Gad nodhi ir Daudi mowachone niya, “Dhi malo mondo iger kendo mar misango ni Jehova Nyasaye e laru mar dino mar Arauna ja-Jebus.”
Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
19 Omiyo Daudi nodhi malo mana kaka Jehova Nyasaye nosechike kokadho kuom Gad.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
20 Kane Arauna ogoyo wangʼe moneno ruoth gi joge kabiro ire, nowuok mokulore e nyim ruoth nyaka e lowo.
Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
21 Arauna nopenje niya, “Angʼo mokelo ruodha ma en ruoth ir jatichne?” Daudi nodwoke niya, “Abiro ngʼiewo laru mar dino cham, mondo agerie kendo mar misango ni Jehova Nyasaye, eka tho manego ji orum.”
Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
22 Arauna nowacho ne Daudi niya, “We ruodha ma en ruoth okawe kendo otim kode gima chunye dwaro mondo otimgo misango. Rwedhi mag timo misango miwangʼo pep kod yiend dino kaachiel gi jok minyalo tigo kaka yien nika.
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
23 Gigi duto, yaye ruoth, Arauna ema osechiwo ne ruoth.” Arauna nomedo wachone niya, “Mad Jehova Nyasaye ma Nyasachi yie kodi.”
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
24 To ruoth nodwoko Arauna niya, “Ooyo, nyaka achuli. Ok abi timo ne Jehova Nyasaye ma Nyasacha misango miwangʼo pep gi gik mayudo nono.” Omiyo Daudi nochulo fedha madirom nus kilo kongʼiewogo laru mar dino kaachiel gi rwedhi.
Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
25 Daudi nogero kendo mar misango ni Jehova Nyasaye kanyo kendo nochiwo misengini miwangʼo pep kaachiel misengini mag lalruok. Eka Jehova Nyasaye nowinjo lamo mane olemogo ni piny, kendo nogengʼo masira mane ni e piny Israel.
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.