< 2 Samuel 21 >

1 E ndalo loch Daudi, ne nitie kech kuom higni adek moluwore; omiyo Daudi nolamo koywak ni Jehova Nyasaye. To Jehova Nyasaye nowacho ni, “Ma ne otimore nikech remo mane Saulo gi ode ochwero, nikech nonego jo-Gibeon.”
Ìyàn kan sì mú lọ́jọ́ Dafidi ní ọdún mẹ́ta, láti ọdún dé ọdún; Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa sì wí pé, “Nítorí ti Saulu ni, àti nítorí ilé rẹ̀ tí ó kún fún ẹ̀jẹ̀, nítorí pé ó pa àwọn ará Gibeoni.”
2 Ruoth noluongo jo-Gibeon mowuoyo kodgi. To koro jo-Gibeon ne ok gin achiel kuom jo-Israel to ne gin jo-Amor ma notony, kendo jo-Israel nosekwongʼore ni biro weyogi ma ok onegogi, to Saulo kane dwaro gi chunye duto mondo jo-Israel gi jo-Juda ogurre motegno, notemo tiekogi.
Ọba sì pe àwọn ará Gibeoni, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; àwọn ará Gibeoni kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Israẹli, ṣùgbọ́n wọ́n jẹ́ àwọn tí ó kù nínú àwọn ọmọ Amori; àwọn ọmọ Israẹli sì ti búra fún wọn, Saulu sì ń wá ọ̀nà àti pa wọ́n ní ìtara rẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli àti Juda.
3 Daudi nopenjo jo-Gibeon niya, “Atimnu angʼo? Ere kaka dalos winjruok mane okethore mondo ugwedhi oganda Jehova Nyasaye?”
Dafidi sì bi àwọn ará Gibeoni léèrè pé, “Kí ni èmi ó ṣe fún un yín? Àti kín ni èmi ó fi ṣe ètùtù, kí ẹ̀yin lè súre fún ilẹ̀ ìní Olúwa?”
4 Jo-Gibeon nodwoke niya, “Waonge ratiro mar dwaro fedha kata dhahabu kuom joka Saulo, to bende waonge gi teko mar nego jo-Israel.” Eka Daudi nopenjogi niya, “Angʼo mudwaro mondo atimnu?”
Àwọn ará Gibeoni sì wí fún un pé, “Kì í ṣe ọ̀rọ̀ fàdákà tàbí wúrà láàrín wa àti Saulu tàbí ìdílé rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fẹ́ kí ẹ pa ẹnìkan ní Israẹli.” Dafidi sì wí pé, “Èyí tí ẹ̀yin bá wí ni èmi ó ṣe?”
5 Ne gikwayo ruoth niya, “To kuom ngʼat mane onegowa kendo mane ochano yo mar hinyowa momiyo waserumo kendo wabedo maonge kar dak kamoro amora e Israel,
Wọ́n sì wí fún ọba pé, “Ọkùnrin tí ó run wá, tí ó sì rò láti pa wá rẹ́ ki a má kù níbikíbi nínú gbogbo agbègbè Israẹli.
6 yie imiwa nyikwaye machwo abiriyo mondo onegi kendo owegi e nyim Jehova Nyasaye e Gibea e dala Saulo ma en ngʼat Jehova Nyasaye moyier.” Omiyo ruoth nowacho niya, “Abiro miyougi.”
Mú ọkùnrin méje nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún wá, àwa ó sì so wọ́n rọ̀ fún Olúwa ní Gibeah ti Saulu ẹni tí Olúwa ti yàn.” Ọba sì wí pé, “Èmi ó fi wọ́n fún yín.”
7 To ruoth ne ongʼwono ma ok ochiwo Mefibosheth wuod Jonathan, ma wuod Saulo, nikech singruok mane Daudi gi Jonathan wuod Saulo otimo e nyim Jehova Nyasaye.
Ṣùgbọ́n ọba dá Mefiboṣeti sí, ọmọ Jonatani, ọmọ Saulu, nítorí ìbúra Olúwa tí ó wà láàrín Dafidi àti Jonatani ọmọ Saulu.
8 To ruoth nokawo Armoni gi Mefibosheth ma yawuot Rizpa nyar Aiya mane onywolo ni Saulo, to gi yawuowi abich ma Merab nyar Saulo nonywolo ni Adriel wuod Barzilai, ma ja-Mehola.
Ọba sì mú àwọn ọmọkùnrin méjèèjì tí Rispa ọmọbìnrin Aiah bí fún Saulu, àní Ammoni àti Mefiboṣeti àwọn ọmọkùnrin márààrún ti Merabu, ọmọbìnrin Saulu, àwọn tí ó bí fún Adrieli ọmọ Barsillai ará Mehola.
9 Nochiwogi ni jo-Gibeon mano onegogi moweyogi ewi got nyim Jehova Nyasaye. Giduto ji abiriyogo notho kanyakla kane oneg-gi e kinde mokwongʼo mag keyo, mana ka ichako kayo shairi.
Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Gibeah lọ́wọ́, wọ́n sì so wọ́n rọ̀ lórí òkè níwájú Olúwa: àwọn méjèèjì sì ṣubú lẹ́ẹ̀kan, a sì pa wọ́n ní ìgbà ìkórè, ní ìbẹ̀rẹ̀, ìkórè ọkà barle.
10 Rizpa nyar Aiya nokawo pien gugru mopedho ewi lwanda mondo obedie, chakre ndalo keyo nyaka koth nochako chue ka goyo ringre jogo. To noriembo winy mafuyo godiechiengʼ kod le mawuotho gotieno mondo kik cham ringregi.
Rispa ọmọbìnrin Aiah sì mú aṣọ ọ̀fọ̀ kan, ó sì tẹ́ fún ará rẹ̀ lórí àpáta ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè, títí omi fi dà sí wọn lára láti ọ̀run wá, kò sì jẹ́ kí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run bà lé wọn lọ́sàn, tàbí àwọn ẹranko igbó lóru.
11 Kane onyis Daudi gima Rizpa nyar Aiya mane en achiel kuom mond Saulo mamoko, nosetimo,
A sì ro èyí, tí Rispa ọmọbìnrin Aiah obìnrin Saulu ṣe, fún Dafidi.
12 nodhi mokawo choke Saulo gi mag wuode Jonathan ka ogologi kuom oganda jo-Jabesh Gilead. Ne gisekawogi lingʼ-lingʼ koa e paw dala man Beth Shan, kuma jo-Filistia nolierogie bangʼ nego Saulo Gilboa.
Dafidi sì lọ ó sì kó egungun Saulu, àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi, àwọn tí ó jí wọn kúrò ní ìta Beti-Ṣani, níbi tí àwọn Filistini gbé so wọ́n rọ̀, nígbà tí àwọn Filistini pa Saulu ní Gilboa.
13 Daudi nokelo choke Saulo gi mag wuode Jonathan koa kuno, kod choke mag joma ne oneg mowe oko nochokgi kamoro achiel.
Ó sì mú egungun Saulu àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ láti ibẹ̀ náà wá; wọ́n sì kó egungun àwọn tí a ti so rọ̀ jọ.
14 Negiiko choke Saulo gi mag Jonathan ma wuode e liend Kish wuon Saulo, e Zela e piny Benjamin kendo negitimo gik moko duto ma ruoth nochiko. Bangʼ mano Nyasaye nodwoko lemo mane ilamo ni piny.
Wọ́n sì sin egungun Saulu àti ti Jonatani ọmọ rẹ̀ ní ilé Benjamini, ní Ṣela, nínú ibojì Kiṣi baba rẹ̀, wọ́n sì ṣe gbogbo èyí tí ọba paláṣẹ, lẹ́yìn èyí ni Ọlọ́run si gba ẹ̀bẹ̀ nítorí ilẹ̀ náà.
15 Lweny nochako bet kendo e kind jo-Filistia gi jo-Israel. Daudi nodhi gi joge mondo oked gi jo-Filistia, kendo nobedo mool.
Ogun sì tún wà láàrín àwọn Filistini àti Israẹli; Dafidi sì sọ̀kalẹ̀, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì bá àwọn Filistini jà, ó sì rẹ Dafidi.
16 To Ishbi-Benob ma en achiel kuom nyikwa Rafa, mane omanore gi tongʼ ma pek mula mane olosgo wiye ne romo kilo adek gi nus kendo ne en-gi ligangla manyien, nowacho ni obiro nego Daudi.
Iṣbi-Benobu sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn Rafa, ẹni tí ọ̀kọ̀ rẹ̀ wọn ọ̀ọ́dúnrún ṣékélì idẹ, ó sì sán idà tuntun, ó sì gbèrò láti pa Dafidi.
17 To Abishai wuod Zeruya nobiro moreso Daudi mi nogoyo ja-Filistia monego. Eka jolweny mag Daudi nosingorene kawacho niya, “Ok inichak iwuog kodwa kidhi e lweny, nikech dipo ka tach Israel otho.”
Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah ràn án lọ́wọ́, ó sì kọlu Filistini náà, ó sì pa á. Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì búra fún un pé, “Ìwọ kì yóò sì tún bá wa jáde lọ sí ibi ìjà mọ́ kí ìwọ má ṣe pa iná Israẹli.”
18 Bangʼ kinde manok, ne nitie lweny machielo gi jo-Filistia e piny Gob. E kindeno Sibekai ma ja-Hushath nonego Saf, achiel kuom nyikwa Rafa.
Lẹ́yìn èyí, ìjà kan sì tún wà láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini ní Gobu, nígbà náà ni Sibekai ará Huṣati pa Safu, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú àwọn Rafa.
19 E lweny machielo gi jo-Filistia e piny Gob Elhanan wuod Jare-Oregim ma ja-Bethlehem nonego Goliath, ja-Giti ma bond tonge chalo lodi.
Ìjà kan sì tún wà ní Gobu láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini, Elhanani ọmọ Jairi ará Bẹtilẹhẹmu sì pa arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni tí ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ dàbí ìdábùú apásá ìhunṣọ.
20 Lweny machielo nochako owuok Gath, kama ne nitie ngʼat marabet mane nigi lith lwedo auchiel gi lith tielo auchiel koni gi koni, lith lwetene gi mag tiendene koriw to ne romo piero ariyo gangʼwen. En bende ne en nyakwar Rafa.
Ìjà kan sì tún wà ní Gati, ọkùnrin kan sì wà tí ó ga púpọ̀, ó sì ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ kan, àti ọmọ ẹsẹ̀ mẹ́fà ní ẹsẹ̀ kan, àpapọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ mẹ́rìnlélógún; a sì bí òun náà ní Rafa.
21 En bende kane ojaro jo-Israel to Jonathan wuod Shimea ma owadgi Daudi nonege.
Nígbà tí òun sì pe Israẹli ní ìjà. Jonatani ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì pa á.
22 Ji angʼwen-gi mane nyikwa Rafa ma ja-Gath, nonegi gi Daudi kod joge.
Àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ni ìran Rafa ní Gati, wọ́n sì ti ọwọ́ Dafidi ṣubú àti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.

< 2 Samuel 21 >