< 2 Samuel 16 >
1 Kane Daudi osewuotho matin koa ewi got, noyudo Ziba jarit mwandu mag Mefibosheth, karite mondo oromne. Ne osembo punde bwora motingʼo makati mia ariyo, gi olemb mzabibu mongʼin mag makati mia achiel gi olemb ngʼowu mongʼin bende mia achiel kod divai mool e dende.
Nígbà tí Dafidi sì fi díẹ̀ kọjá orí òkè náà, sì wò ó, Ṣiba ìránṣẹ́ Mefiboṣeti sì ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, òun àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí a ti dì ní gàárì, àti igba ìṣù àkàrà lórí wọn, àti ọgọ́rùn-ún síírí àjàrà gbígbẹ, àti ọgọ́rùn-ún èso ẹ̀rún, àti ìgò ọtí wáìnì kan.
2 Ruoth nopenjo Ziba niya, “Angʼo momiyo ikelo gigi?” Ziba nodwoke niya, “Pundegi gin ma jood ruoth nyalo idho, makati gi olembe to gin mar jogi mondo ocham, divai to en mar duogo chuny joma ool e thim mondo omadhi.”
Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Kí ni wọ̀nyí?” Ṣiba sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”
3 Eka ruoth nopenje niya, “To ere nyakwar ruodhi?” Ziba nowachone niya, “Odongʼ Jerusalem, nikech oparo ni, ‘Kawuononi jo-Israel dhi dwokona loch kwara.’”
Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jerusalẹmu; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Israẹli yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’”
4 Eka ruoth nowachone Ziba niya, “Gik moko duto ma mag Mefibosheth koro gin magi.” Ziba nowachone niya, “Erokamano. Mad ayud ngʼwono e wangʼ ruodha ma en ruoth.”
Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefiboṣeti jẹ́ tìrẹ.” Ṣiba sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, olúwa mi ọba.”
5 Ka ruoth Daudi nochimo Bahurim, ngʼat moro moa e dhoodgi Saulo nobiro koa kuno. Nyinge ne Shimei wuod Gera, nowuok kowacho weche mag kwongʼ.
Dafidi ọba sì dé Bahurimu, sì wò ó, ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Saulu wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣimei, ọmọ Gera, ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.
6 Nobayo Daudi gi jodong ruoth gi kite, kata obedo ni jolweny gi thuondi ne ogengʼo bath Daudi korachwich gi koracham.
Ó sì sọ òkúta sí Dafidi, àti sí gbogbo ìránṣẹ́ Dafidi ọba, àti sí gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
7 Shimei nokwongʼe kawacho niya, “Wuog idhi, wuog idhi in ngʼat mosechwero remo, kendo mofuwoni.
Báyìí ni Ṣimei sì wí nígbà tí ó ń yọ èébú, “Jáde, ìwọ ọkùnrin ẹ̀jẹ̀, ìwọ ọkùnrin Beliali.
8 Jehova Nyasaye osechuli kuom remo duto mane ichwero e dhood Saulo, ma isetiyo kar lochne. Jehova Nyasaye osemiyo wuodi Abisalom pinyruoth. Osetieki nikech in dhano mohero chwero remo.”
Olúwa mú gbogbo ẹ̀jẹ̀ ìdílé Saulu padà wá sí orí rẹ, ní ipò ẹni tí ìwọ jẹ ọba; Olúwa ti fi ìjọba náà lé Absalomu ọmọ rẹ lọ́wọ́: sì wò ó, ìwà búburú rẹ ni ó mú èyí wá bá ọ, nítorí pé ọkùnrin ẹ̀jẹ̀ ni ìwọ.”
9 Eka Abishai wuod Zeruya nowachone ruoth niya, “Guok mothoni to kwongʼo ruodha nangʼo? We adhi angʼad ngʼute oko.”
Abiṣai ọmọ Seruiah sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí òkú ajá yìí fi ń bú olúwa mi ọba? Jẹ́ kí èmi kọjá, èmi bẹ̀ ọ́, kí èmi sì bẹ́ ẹ́ lórí.”
10 To ruoth nodwoke niya, “Angʼo machandou koda un yawuot Zeruya? Ka okwongʼa nikech Jehova Nyasaye nowachone ni, ‘Kwongʼ Daudi,’ to en ngʼa madipenj ni, ‘Angʼo momiyo itimo kama?’”
Ọba sì wí pé, “Kín ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah? Bí ó bá ń bú èébú, nítorí tí Olúwa ti wí fún un pé, ‘Bú Dafidi!’ Ta ni yóò sì wí pé, ‘Kín ni ìdí tí o fi ṣe bẹ́ẹ̀.’”
11 Daudi nowachone Abishai gi jodonge duto niya, “Ka wuoda, manywolo ema dwaro tieko ngimana, to kare ja-Benjamin-ni ditimna marach maromo nade! Wereuru kode odhi nyime gi kwongʼ nimar Jehova Nyasaye osenyise mondo otim kamano.
Dafidi sì wí fún Abiṣai, àti fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, ọmọ mi tí ó ti inú mi wá, ń wá mi kiri, ǹjẹ́ mélòó mélòó ni ará Benjamini yìí yóò sì ṣe? Fi í sílẹ̀, sì jẹ́ kí o máa yan èébú; nítorí pé Olúwa ni ó sọ fún un.
12 Dipo ka Jehova Nyasaye oneno midhiero ma an-go motimona ngʼwono kar kwongʼ mayudo kawuononi.”
Bóyá Ọlọ́run yóò wo ìpọ́njú mi, Olúwa yóò sì fi ìre san án fún mi ní ipò èébú rẹ̀ lónìí.”
13 Omiyo Daudi gi joge nomedo wuotho kadhi nyime ka giluwo yo, ka Shimei bende ne wuotho e dir got mochimore kode ka odhi nyime gi kwongʼe to obaye gi kite kokiro gik mochido kuome.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń lọ ní ọ̀nà, Ṣimei sì ń rìn òdìkejì òkè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, ó sì ń yan èébú bí ó ti ń lọ, ó sì ń sọ ọ́ lókùúta, ó sì ń fọ́n erùpẹ̀.
14 Ruoth gi ji duto mane ni kode nochopo kama negidhiyoe ka giol. Kendo noyweyo kanyo.
Ọba, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì dé Jordani, ó sì rẹ̀ wọ́n, wọ́n sì sinmi níbẹ̀.
15 To gi e kindeno, Abisalom gi jo-Israel nobiro Jerusalem to Ahithofel ne ni kode.
Absalomu àti gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn ọkùnrin Israẹli sì wá sí Jerusalẹmu, Ahitofeli sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
16 Eka Hushai ja-Arki, mosiep Daudi nodhi ir Abisalom mowachone niya, “Ruoth mondo odag amingʼa! Ruoth mondo odag amingʼa!”
Ó sì ṣe, nígbà tí Huṣai ará Arki, ọ̀rẹ́ Dafidi tọ Absalomu wá, Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Kí ọba ó pẹ́! Kí ọba ó pẹ́.”
17 Abisalom nopenjo Hushai niya, “Ma e kaka inyiso hera ne osiepni? Marangʼo ne ok idhi gosiepni?”
Absalomu sì wí fún Huṣai pé, “Oore rẹ sí ọ̀rẹ́ rẹ ni èyí? Èéṣe tí ìwọ kò bá ọ̀rẹ́ rẹ lọ?”
18 Hushai nowachone Abisalom niya, “Ooyo to mana ngʼat moyier gi Jehova Nyasaye, moyier gi jogi to gi jo-Israel duto mano e ngʼat mabiro bedo jakore mi asik kode.
Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ nítorí ẹni tí Olúwa, àti gbogbo àwọn ènìyàn yìí, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli bá yàn, tirẹ̀ lèmi ó jẹ́, òun lèmi ó sì bá jókòó.
19 To moloyo kanyo, kare onego atine ngʼa? Donge onego atine wuode? Mana kaka natiyo ni wuonu, e kaka in bende abiro tiyoni.”
Àti pé, ta ni èmi ó sì sìn? Kò ha yẹ kí èmi ó máa sìn níwájú ọmọ rẹ̀? Gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń sìn rí níwájú baba rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sìn níwájú rẹ.”
20 Abisalom nowachone Ahithofel niya, “Ngʼadnwae rieko. En angʼo monego watim?”
Absalomu sì wí fún Ahitofeli pé, “Ẹ bá ará yín gbìmọ̀ ohun tí àwa ó ṣe.”
21 Ahithofel nodwoke niya, “Terri gi monde wuonu mamoko mane oweyo karito dala ruoth. Eka jo-Israel nowinj kaka isebedo mangʼwe e um wuonu, kendo ji duto man kodi nobed gi teko.”
Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ lọ, tí ó fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́ pé, ìwọ di ẹni ìríra sí baba rẹ, ọwọ́ gbogbo àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ yóò sì le.”
22 Omiyo negiguro hema ne Abisalom ewi ot malo kendo noterore gi monde wuon-gi mamoko mana ka jo-Israel duto neno.
Wọ́n sì tẹ́ àgọ́ kan fún Absalomu ní òrùlé; Absalomu sì wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ̀ lójú gbogbo Israẹli.
23 E ndalono rieko mane Ahithofel ngʼado nechalo mana ka ngʼat mopenjo Nyasaye wach. Mano e kaka Daudi gi Abisalom ne okawo rieko ma Ahithofel ne chiwo.
Ìmọ̀ Ahitofeli tí ó máa ń gbà ni ìgbà náà, ó dàbí ẹni pé ènìyàn béèrè nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ìmọ̀ Ahitofeli fún Dafidi àti fún Absalomu sì rí.