< 2 Samuel 12 >

1 Jehova Nyasaye nooro Nathan ir Daudi. Kane ochopo ire nowachone niya, “Ne nitie ji ariyo moko e dala moro; achiel ne jamoko to machielo nodhier.
Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
2 Jamoko ne nigi rombe mangʼeny gi dhok,
Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
3 to ngʼat modhier to ne onge gimoro makmana nyarombo ma sibini achiel mane osengʼiewo. Norite maber mana kaka norito nyithinde owuon. Nyarombono nopogone chiembe mochamo, ne omodho e okombene kendo nonindo e bade. Ne ochalne mana ka nyathine ma nyako.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
4 “Koro jawuoth moro nobiro ir jamoko-cha, to jamokono ne ok okawo achiel kuom rombe kata dhoge mondo oyangʼ ni jawuodhno mane obiro ireno. Kata kamano, nyarombo ma sibini mar jadhierno ema noyangʼone wendo mane obiro ire.”
“Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
5 Mirima malich ne omako Daudi gi ngʼatno mowachone Nathan niya, “Akwongʼora gi nying Jehova Nyasaye mangima ni ngʼat mane otimo kama owinjore otho!
Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
6 Nyaka ochul kar rombono moloyo nyadingʼwen, nikech ne otimo gima chalo kama, ka chunye onge gi kech.”
Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
7 Eka Nathan nodimbo wach ne Daudi niya, “In e ngʼatno! Ma e gima Jehova Nyasaye, ma Nyasach Israel wacho: ‘Ne awiri mondo ibed ruoth Israel, ne agoli e lwet Saulo.
Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
8 Ne amiyi od ruodhi mondo obed mari, kendo naketo monde ruodhi e lweti. Ne amiyi dhout Israel gi dhood Juda. To ka magi ne ok oromi to pod ne anyalo miyi moko.
Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
9 Angʼo momiyo isechayo wach Jehova Nyasaye ka itimo gima rach machal kama e wangʼe? Ne inego Uria ja-Hiti gi ligangla mi ikawo chiege mondo obed mari iwuon. Ne inege gi ligangla jo-Amon.
Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
10 Kuom mano, negruok gi ligangla ok norum e odi, nikech ne ichaya mi ikawo chi Uria ja-Hiti mobedo mari iwuon.’
Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
11 “Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: ‘Anakelni masira kowuok e odi iwuon. Mana kineno kama gi wangʼi iwuon abiro kawo mondi kendo miyogi achiel kuom joma chiegni kodi, kendo obiro terore kod mondegi odiechiengʼ alanga.
“Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
12 Nitimo gino apanda, to an abiro timo ma odiechiengʼ alanga e nyim jo-Israel.’”
Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
13 Eka Daudi nowachone Nathan niya, “Asekethone Jehova Nyasaye.” Nathan nodwoko niya, “Jehova Nyasaye oseweyoni richoni. Ok ibi tho.
Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
14 To nikech gima isetimo, isemiyo jowasigu ojaro Jehova Nyasaye, omiyo wuodi monywolno biro tho.”
Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
15 Bangʼ kane Nathan osedhi dala, Jehova Nyasaye nogoyo nyathi ma chi Uria nosenywolo ni Daudi gi tuo.
Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
16 Daudi nolamo Nyasaye mondo kik nyathi tho. Notweyo chiemo kendo nodhi e ode mi onindo piny e lowo otieno ka otieno.
Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
17 Jodongo mag ode nochungʼ bathe mondo gichunge owe nindo piny e lowo, to notamore, kendo ne ok onyal chamo chiemo moro amora.
Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
18 To chiengʼ mar abiriyo nyathi notho, jotij Daudi ne luor nyise ni nyathi osetho, nikech negiparo niya, “Kane nyathi pod ngima, ne wawuoyo gi Daudi to ne ok owinjowa. Koro to wadhi wacho ne nangʼo ka nyathi osetho? Onyalo timo gimoro marach.”
Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
19 Daudi noneno ka jotije kuodho wach kendgi mine ongʼeyo ni nyathi osetho. Nopenjo niya, “Nyathi osetho?” Negidwoke niya, “Ee, osetho.”
Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
20 Daudi noa malo e lowo. Kane oseluokore, nowirore gi mo moloko lewni mane orwako, nodhi e od Jehova Nyasaye mi olemo. Bangʼe nodhi e ode owuon, mine okwayo chiemo momiye mochamo.
Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
21 Jotije nopenje niya, “Itimori kama nangʼo? Kane nyathi pod ngima, ne itweyo chiemo kendo ne iywak. To ka nyathi koro osetho, to ichungʼ kendo ichiemo!”
Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
22 Nodwokogi niya, “Kane nyathi pod ngima ne atweyo chiemo kendo aywak. Nikech ne aparo ni, ‘Ngʼama dingʼe? Dipo ka Jehova Nyasaye nyalo timona ngʼwono miwe nyathi obed mangima.’
Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
23 To nikech koro osetho, angʼo dimi atwe chiemo? Bende daduoge obed mangima? An ema abiro dhi ire to en ok onyal duogo ira.”
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
24 Daudi nohoyo Bathsheba chiege, nodhi ire mobedo kode e achiel. Nonywolo wuowi kendo negichake ni Solomon. Jehova Nyasaye ne ohere;
Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
25 kendo nikech Jehova Nyasaye nohere, nomiyo Nathan janabi wach ni mondo ochake ni Jedidia.
Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
26 Kata kamano Joab nodhi nyime kedo gi Raba e piny jo-Amon kendo nomako kar ruoth mochiel motegno.
Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
27 Joab nooro joote ir Daudi, kowacho niya, “Asekedo gi Raba ma amako kargi mar pi.
Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
28 Koro bi gi jolweny duto mondo ilwor dala maduongʼ kendo ikawe. Ka ok kamano to abiro kawo dala maduongʼno kendo ibiro luonge gi nyinga.”
Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
29 Omiyo Daudi nochoko jolweny duto modhigo Raba mi omonje kendo okawe.
Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
30 Nogolo osimbo mar duongʼ ewi ruodhgi, ma pek dhahabu mane olosego ne romo kilo piero adek gangʼwen kendo noduse gi kite ma nengogi tek mi osidhne Daudi. Noyako gik mangʼeny e dala maduongʼno
Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
31 kendo nokawo ji duto mane ni e dalano, moketogi e tij ngʼeto gi musimeno kod tiyo gi chumbe gi ledhi; bende ne oketogi jolos matafare. Notimo ma ni mier duto mag jo-Amon. Eka Daudi gi jolwenje duto nodok Jerusalem.
Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.

< 2 Samuel 12 >