< 2 Samuel 11 >

1 E ndalo mar chwiri, e kinde ma ruodhi dhi e lweny, Daudi nooro Joab gi joka ruoth to gi jolweny mag Israel duto. Negigoyo jo-Amon mi gitiekogi kendo negimako dala mar Raba. To Daudi nodongʼ e Jerusalem.
Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba máa ń jáde ogun, Dafidi sì rán Joabu, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Israẹli; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ammoni, wọ́n sì dó ti Rabba. Dafidi sì jókòó ní Jerusalẹmu.
2 Odhiambo moro Daudi noa malo e kitandane mowuotho alwora mar wi tado mar ode ka en ewi tado noneno dhako moro kaluokore. To dhakono ne jaber ahinya,
Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dafidi sì dìde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.
3 omiyo Daudi nooro ngʼato mondo odhi onon ni en dhako mane. Ngʼatno nowacho, “Donge mano en Bathsheba, ma nyar Eliam ma chi Uria ja-Hiti?”
Dafidi sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, “Èyí ha kọ́ ni Batṣeba, ọmọbìnrin Eliamu, aya Uriah ará Hiti.”
4 Eka Daudi nooro jaote mondo odhi okele, mi dhakono nobiro ire kendo noterore kode. Ma noyudo ka koro eka otieko kindene mar neno malo kendo nosepwodhore. Bangʼ mano Bathsheba nodok dala.
Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀, nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
5 Dhakono nomako ich mi nooro ni Daudi wach kowacho niya, “Ayach.”
Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti lóyún.”
6 Omiyo Daudi nooro wach ni Joab niya, “Orna Uria ja-Hiti.” Eka Joab noore ir Daudi.
Dafidi sì ránṣẹ́ sí Joabu, pé, “Rán Uriah ará Hiti sí mi.” Joabu sì rán Uriah sí Dafidi.
7 Kane Uria obiro ire, Daudi nopenje ngima Joab gi mar jolweny to gi kaka lweny bende dhi.
Nígbà tí Uriah sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dafidi sì bi í léèrè báwo ni Joabu ti ṣe àti àlàáfíà àwọn ènìyàn náà, àti bí ogun náà ti ń ṣe.
8 Eka Daudi nowachone ni Uria niya, “Dhi mwalo e odi mondo ilwok tiendi.” Omiyo Uria nowuok oa e dala ruoth, eka bangʼe ruoth noorone mich.
Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ, kí o sì wẹ ẹsẹ̀ rẹ.” Uriah sì jáde kúrò ní ilé ọba, oúnjẹ láti ọ̀dọ̀ ọba wá sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
9 To Uria nonindo e dhorangach mar dala gi jotich mamoko mag ruoth to ne ok olor odhi e ode.
Ṣùgbọ́n Uriah sun ní ẹnu-ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
10 Kane owach ne Daudi ni Uria ne ok odhi ode, nopenje niya, “Donge isebudho oko, angʼo momoni dhi odi?”
Nígbà tí wọ́n sì sọ fún Dafidi pé, “Uriah kò sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀,” Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Ṣe bí ọ̀nà àjò ni ìwọ ti wá? Èéha ti ṣe tí ìwọ kò fi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ.”
11 Uria nowachone Daudi niya, “Sandug Muma gi Israel gi Juda dak e hembe, to jatenda ma Joab gi jo-ruodha obuoro oko e pap. Ere kaka anyalo dhi e oda mondo achiem, kendo amethi, mi ariwra e achiel gi chiega? Akwongʼora e nyimi ni ok datim gima kamano.”
Uriah sì wí fún Dafidi pé, “Àpótí ẹ̀rí, àti Israẹli, àti Juda jókòó nínú àgọ́; àti Joabu olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá, èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ àti láti mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láààyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”
12 Eka Daudi nowachone niya, “Bed ka kawuono kiny naweyi idog.” Omiyo Uria noriyo Jerusalem chiengʼno gi kinyne.
Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sì dúró níhìn-ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Uriah sì dúró ní Jerusalẹmu ní ọjọ́ náà, àti ọjọ́ kejì.
13 Daudi noluonge mochiemo mi ometho kode kendo Daudi nomiye math momer. To kotieno nochopo Uria nowuok modhi onindo e pare kaachiel gi jotij ruodhe; to ne ok odhi ode.
Dafidi sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
14 To gokinyi Daudi nondiko ne Joab baruwa moorogo Uria mondo oter.
Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dafidi sì kọ̀wé sí Joabu, ó fi rán Uriah.
15 Ei baruwano nondikoe niya, “Ket Uria e laini manyime kama lweny gerie ahinya. Eka weyeuru kende mondo ogoye manege.”
Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Uriah síwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fàsẹ́yìn, kí wọn lè kọlù ú, kí ó sì kú.”
16 Omiyo kane Joab olworo dala maduongʼno mondo gimaki, noketo Uria kama ongʼeyo ni wasigu mager kendo tek nitie.
Ó sì ṣe nígbà tí Joabu ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Uriah sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.
17 Kane jo-dala maduongʼno owuok mondo oked gi Joab, jolwenj Daudi moko nonegi; to Uria ja-Hiti bende nonegi.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Joabu jà, díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.
18 Joab nooro wach ne Daudi konyise gik moko duto mosetimore e lweny.
Joabu sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dafidi.
19 Nochiko jaote niya, “Ka isetieko nyiso ruoth wechegi duto matimore e lweny,
Ó sì pàṣẹ fún ìránṣẹ́ náà pé, “Nígbà tí ìwọ bá sì parí àti máa ro gbogbo nǹkan ogun náà fún ọba.
20 kamoro mirima nyalo mako ruoth, mi openji ni, ‘Angʼo momiyo ne usudo machiegni ahinya gi dala maduongʼ mondo ukedi? Donge ne ungʼeyo niginyalo chielou gi aserenigi ewi ohinga?
Bí ó bá ṣe pé, ìbínú ọba bá ru, ti òun sì wí fún ọ pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi súnmọ́ ìlú náà láti bá wọn jà, ẹ̀yin kò mọ̀ pé wọn ó tafà láti orí odi wá.
21 En ngʼa ma nonego Abimelek wuod Jerub-Besheth? Dhako donge ema nodiro pongʼ rego gi ewi ohinga, mine otho Thebez? Angʼo momiyo ne udhi machiegni ahinya gi ohinga?’ Kopenji penjoni, to wachne ni, ‘Jatichni Uria ja-Hiti bende otho.’”
Ta ni ó pa Abimeleki ọmọ Jerubu-Beṣeti? Kì í ṣe obìnrin ni ó yí òkúta-ọlọ lù ú láti orí odi wá, tí ó sì kú ní Tebesi? Èéha ti rí tí ẹ̀yin fi súnmọ́ odi náà? Ìwọ yóò sì wí fún un pé, Uriah ìránṣẹ́ rẹ ará Hiti kú pẹ̀lú.’”
22 Jaote nowuok modhi, kane ochopo nonyiso Daudi weche duto mane Joab oore mondo owachi.
Ìránṣẹ́ náà sì lọ, ó sì wá, ó sì jẹ́ gbogbo iṣẹ́ tí Joabu rán an fún Dafidi.
23 Jaoteno nowachone Daudi niya, “Jogo nochako loyowa mi giwuok e pap mondo giked kodwa to ne wariembogi ma wadwokogi chien nyaka e dhoranga dala maduongʼ.
Ìránṣẹ́ náà sì wí fún Dafidi pé, “Nítòótọ́ àwọn ọkùnrin náà lágbára jù wá lọ, wọ́n sì jáde tọ̀ wá wá ní pápá, àwa sì tẹ̀lé wọn títí wọ́n fi dé ẹ̀yìn odi.
24 Eka jodir aserni nobayo jotichni gi ewi ohinga, kendo jotich ruoth moko nonegi. Uria ja-Hiti ma jatichni bende ginego.”
Àwọn tafàtafà sì ta sí ìránṣẹ́ rẹ láti orí odi wá, díẹ̀ nínú àwọn ìránṣẹ́ ọba sì kú, ìránṣẹ́ rẹ̀ Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.”
25 Daudi nowachone jaote niya, “Wachne Joab kama: Kik wachno chandi; ligangla nego jakoni gi jakocha. Med kedo matek gi dala maduongʼno mi ikethe chuth. Wachne wechegi mondo ijiwego.”
Dafidi sì wí fún ìránṣẹ́ náà pé, “Báyìí ni ìwọ yóò wí fún Joabu pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí nǹkan yìí burú ní ojú rẹ, nítorí pé idà a máa pa lọ́tùn ún lósì, mú ìjà rẹ le sí ìlú náà, kí o sì bì í ṣubú.’ Kí ìwọ sì mú un lọ́kàn le.”
26 Kane chi Uria owinjo ni chwore otho, noywage.
Nígbà tí aya Uriah sì gbọ́ pé Uriah ọkọ rẹ̀ kú, ó sì ṣọ̀fọ̀ nítorí ọkọ rẹ̀.
27 Bangʼ ka ndalo ywak norumo, Daudi nowacho mondo okele e ode, mane obedo chiege monywolone nyathi ma wuowi. To gima Daudi notimo ne ok omoro Jehova Nyasaye.
Nígbà tí ìṣọ̀fọ̀ náà sì kọjá tan, Dafidi sì ránṣẹ́, o sì mú un wá sí ilé rẹ̀, ó sì di aya rẹ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un, ṣùgbọ́n nǹkan náà tí Dafidi ṣe burú níwájú Olúwa.

< 2 Samuel 11 >