< 2 Ruodhi 9 >

1 Elisha janabi noluongo achiel kuom jonabi mowachone niya, “Ngʼwan lawi e nungoni, kendo ikaw morni idhigo e piny Ramoth Gilead.
Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
2 Ka ichopo kanyo, to imany Jehu wuod Jehoshafat, ma wuod Nimshi. Dhi ire igole oko e kind ji kendo itere nyaka ei ot kar kende.
Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
3 Bangʼ mano, kaw puga motingʼo mo iol e wiye kiwacho niya, ‘Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: Asewali bedo ruodh Israel.’ Bangʼ timo ma to iyaw dhoot; kendo ring piyo, kik ideki!”
Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
4 Eka wuowi matin ma janabi nodhi Ramoth Gilead.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
5 Kane ochopo noyudo ka jotend lweny obet kanyakla. Nowachone jatend lweny niya, “An-gi wach moro madwaro wachoni.” Jehu nopenje niya, “En ngʼa kuomwa ka midwaro losogo?” Nodwoke niya, “En mana in, jatend lweny.”
Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
6 Jehu nochungʼ malo modhi kode ei ot. Bangʼ mano janabino noolo mo ewi Jehu kowachone niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye ma Nyasach Israel wacho: ‘Asewali mondo ibed ruodh Israel ma gin jo-Jehova Nyasaye.
Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
7 Nyaka itiek od Ahab ma ruodhi, kendo abiro chulo kuor nikech remb jotichna ma jonabi kendo nikech remb jotich Jehova Nyasaye mane ochwer gi Jezebel.
Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
8 Abiro tieko od Ahab duto. Abiro tieko chwo manie od Ahab e piny Israel bedni gin wasumbini kata joma ni thuolo.
Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
9 Abiro keto od Ahab chal gi od Jeroboam wuod Nebat kendo ochal kaka od Baasha wuod Ahija.
Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
10 To ne Jezebel guogi ema nocham ringre e puodho manie paw Jezreel kendo onge ngʼama noyike.’” Bangʼ mano noyawo dhoot moringo odhi.
Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
11 Kane Jehu odok ir jotend lweny wetene achiel kuomgi nopenje niya, “Bende weche duto beyo? To angʼo mane janekono obirone iri?” Jehu nodwokogi niya, “Ungʼeyo ngʼatno, to gi gik ma onyalo wacho.”
Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
12 Negikwere niya, “Mano en miriambo, wachnwa adier.” Jehu nodwokogi niya, “Ma e gima nonyisa: ‘Ni Jehova Nyasaye owacho: Asewiri mondo ibed ruodh Israel.’”
“Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
13 Negigolo lepgi piyo piyo ma gipedho ewi raidhi mondo Jehu owuothie. Eka negigoyo turumbete ka gigoyo koko niya, “Jehu en ruoth!”
Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
14 Eka Jehu wuod Jehoshafat ma wuod Nimshi nochano lingʼ-lingʼ mondo omonj Joram. (Koro Joram gi jo-Israel duto nosebedo kakedo mondo gisir Ramoth Gilead kuom monj moa kuom Hazael ruodh Aram,
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
15 to ruoth Joram noduogo Jezreel mondo ochangi kuom adhonde mane oyudo kuom lweny mane ni e kinde gi Hazael ruodh jo-Aram). Jehu mowachone niya, “Ka ma e kaka uparo, to kik iyie ngʼato angʼata wuogi e dala maduongʼ ka mondo odhi ohul wachni e piny Jezreel.”
ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
16 Eka nodhi moidho gache mar lweny moringo odhi Jezreel nikech Joram ne ni kuno kendo Ahazia ruodh Juda bende noyudo ni kuno kaka wendone.
Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
17 Ka jangʼicho mane ni ewi ohinga man Jezreel noneno jolweny Jehu kabiro, nogoyo koko niya, “Aneno ka jolweny biro.” Joram nokone niya, “Or ngʼato gi faras mondo odhi openjgi ka gibiro e yor kwe.”
Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
18 Jariemb faras noringo moromo gi Jehu mowachone niya, “Ruodha penjo kama: ‘Bende ubiro e yor kwe?’” Jehu nodwoke niya, “Kwe to obadhi angʼo? Luw bangʼa.” Jangʼicho nodwoko wach ni Joram ni, “Jaote osechopo irgi, to ok ane koduogo.”
Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
19 Kuom mano ruoth nooro jariemb faras mar ariyo. Kane ochopo irgi nowachonegi niya, “Ruodha penjo kama: ‘Bende ubiro e yor kwe?’” Jehu nodwoke niya, “Kwe to obadhi e angʼo? Luw bangʼa.”
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
20 Jangʼicho noduogo wach ne Joram niya, “Osechopo irgi, to ok ane koduogo. Jariemb gari cha chalo mana gi Jehu wuod Nimshi, kendo oriembo mana ka janeko.”
Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
21 Joram nogolo chik niya, “Ikna gacha.” To kane giseikone gache, Joram ruodh Israel kod Ahazia ruodh Juda noriembo gechegi, ka ngʼato ka ngʼato ni e gache owuon mondo girom gi Jehu. Negiromo kode e puodho mane mar Naboth ja-Jezreel.
“Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
22 Kane Joram oneno Jehu nopenje niya, “Ibiro e yor kwe koso?” Jehu nodwoke niya, “Ere kaka kwe nyalo betie kapod Jezebel minu dhi nyime gi lamo nyiseche manono kod timo timbe jwok?”
Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
23 Joram nolokore moa gi ngʼwech kokok ne Ahazia niya, “Ja-andhoga Ahazia!”
Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
24 Eka Jehu noywayo atungʼ modiro asere kendo ochwoyo kind ngʼede Joram. Asere nopowo dho chunye molwar piny oa ewi gache.
Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
25 Jehu nowachone Bidkar jatend gechene mag lweny niya, “Kawe ibole e puodho mane mar Naboth ja-Jezreel. Par kaka in kod an ne wariembo gechewa kanyachiel bangʼ Ahab ma wuon-gi kane Jehova Nyasaye okoro wachni kuome kama:
Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
26 ‘Nyoro ne aneno remb Naboth gi remb yawuote kendo adiera abiro miyo gichul kuom chwero remo e puodho manie pap,’ Jehova Nyasaye owacho. Kaweuru kendo ubole e puodhono kaluwore gi wach Jehova Nyasaye.”
‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
27 Kane Ahazia ruodh Juda oneno gima otimore noringo kotony gi yor Beth-Hagan. Jehu nolawe kakok niya, “En bende negeuru!” Ne gihinye ewi gache mar lweny koringo ochomo Gur man but Ibleam, to notony kodhi Megido kuma nothoe.
Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
28 Jotichne nokawe gi gach lweny nyaka Jerusalem moike kod kwerene e bure mantiere e Dala Maduongʼ mar Daudi.
Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
29 E higa mar apar gachiel mar Joram wuod Ahab, Ahazia nobedo ruoth e piny Juda.
(Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
30 Kane Jehu odhi Jezreel, Jezebel nowinjo birone kanyo, mi obuko wangʼe kendo oloso wiye kongʼicho gie dirisa.
Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
31 Kane Jehu odonjo e dhorangach nopenjo niya, “Ibiro e yor kwe, in Zimri ma janek ruodheni?”
Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
32 Nongʼiyo malo e dirisa mopenjo niya, “En ngʼa ma jakora? En ngʼa?” Eka ji ariyo kata adek mabwoch nongʼiye gi kwinyo.
Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
33 Jehu nowachonegi niya, “Diruru dhakono piny!” Omiyo negidire piny ma rembe moko okirore e kor ohinga ka farase nyone piny.
Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
34 Jehu nodonjo e dalano mochiemo kendo ometho. Eka nowachonegi niya, “Kawuru dhako mokwongʼno udhi uyiki, nimar ne en nyar ruoth.”
Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
35 To kane gidhi yike onge gima negiyudo makmana hanga wiye, tiendene gi lwetene.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
36 Negidok ma giwachone Jehu wachno, mane owacho niya, “Ma e wach mane Jehova Nyasaye owacho kokadho kuom jatichne Elija ja-Tishbi: E puodho manie paw Jezreel guogi nokidh ringre Jezebel.
Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
37 Ringre Jezebel nochal ka owuoyo moyar e pewe mag Jezreel, maonge ngʼama nyalo wacho ni ma Jezebel.”
Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”

< 2 Ruodhi 9 >