< 2 Ruodhi 6 >

1 Kanyakla mar jonabi nowachone Elisha niya, “Neye, kaka kama wadakie kodini tin.
Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
2 Wadhiuru Jordan mondo ngʼato ka ngʼato otongʼ yien kendo wagergo kama waduto wanyalo dakie.” Nowachonegi niya, “Dhiuru.”
Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
3 Eka achiel kuom jonabi nowachone Elisha niya, “Donge ber idhi kodwa?” Elisha nodwoke niya, “Abiro dhi kodu.”
Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
4 Kuom mano nodhi kodgi. Negidhi Jordan ma gichako tongʼo yien.
Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
5 To kane achiel kuomgi ne tongʼo yien, leye nolwar e pi. Noywak niya, “Yaye ruodha, korka ne en le mokwa!”
Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
6 Ngʼat Nyasaye nopenje niya, Ne olwar gi kanye? Kane onyise kama ne olwarie, Elisha nongʼado luth, monyume kanyo kendo wi le nolewore.
Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
7 Eka nowachone niya, “Kawe.” Eka ngʼatno norieyo lwete mokawe.
Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
8 Ruoth Aram nenie e lweny gi jo-Israel. Bangʼ kane osewinjore gi jodonge, nowacho niya, “Abiro goyo kambina kama chalo kama.”
Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
9 Ngʼat Nyasaye nooro wach ne ruodh Israel kama: “Bed motangʼ kikalo kanyo nikech jo-Aram dhi buto kuno.”
Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
10 Omiyo ruodh Israel nokalo kanyo kotangʼ kaluwore gi wach mane ngʼat Nyasaye onyise. Kinde ka kinde Elisha ne siemo ruoth, mondo obed motangʼ ne kuondego.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
11 Wachni nochwanyo chuny ruodh Aram. Noluongo jodonge mowachonegi niya, “Bende unyalo wachona ngʼat ma jakorwa makonyo ruodh Israel?”
Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
12 Achiel kuom jodonge nowacho niya, “Ruodha onge ngʼatwa moro makonye, makmana Elisha janabi man Israel ema nyiso ruodh Israel gik moko duto miwacho kata ka in e odi mar nindo.”
Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
13 Ruoth nogolo chik kawacho niya, “Dhiuru mondo udwar kama entie mondo adhi aor ji omake.” Wach noduogo kama: “En Dothan.”
Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
14 Eka ne ooro farese, geche lweny kod jolweny motegno kuno. Negidhi kuno gotieno ma gilworo dala maduongʼno.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
15 Kane jatich ngʼat Nyasaye ochiewo mo mondo kiny gokinyi, jolweny man-gi farese kod geche lweny ne oseluoro dala maduongʼno. Jatich nopenjo niya, “Yaye, ruodha, wabiro timore nade?”
Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
16 Janabi nodwoke niya, “Kik ubed maluor, nimar joma ni kodwa ngʼeny moloyo joma ni kodgi.”
“Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
17 Kendo Elisha nolemo niya, “Jehova Nyasaye, yaw wangʼe mondo onen.” Eka Jehova Nyasaye noyawo wangʼ jatijno, kendo noneno farese kod geche lweny ewi got kolworo Elisha.
Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
18 Kane oneno wasigu kalor biro machiegni kode, Elisha nolamo Jehova Nyasaye niya, “Lok jogi muofu.” Omiyo noloko jogi muofni mana kaka Elisha nosekwayo.
Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
19 Elisha nokonegi niya, “Ma ok en yo kendo ma ok en dala maduongʼ. Luw-uru bangʼa kendo abiro terou nyaka ir ngʼat ma udwarono.” Kendo noterogi nyaka Samaria.
Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
20 Bangʼ kane gisedonjo e dala maduongʼno, Elisha nowacho niya, “Jehova Nyasaye yaw wangʼ jogi mondo ginen.” Eka Jehova Nyasaye noyawo wengegi kendo ka wengegi noyawore, to negiyudo ka gin Samaria.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
21 Kane ruodh Israel onenogi nopenjo Elisha niya, Wuora, anyalo negogi?
Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
22 Nodwoke niya, “Kik ineg-gi. Bende dineg joma isemako gi liganglani kata tongʼ? Migi chiemo gicham kod pi mondo gimodhi, eka mondo gidog ir ruodhgi.”
“Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
23 Omiyo ne olosonegi nyasi maduongʼ kendo kane gisetieko chiemo kod metho, ne oorogi ma gidok ir ruodhgi. Kuom oganda lweny mag Aram noweyo monjo piny Israel.
Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
24 Bangʼ ndalo moko, Ben-Hadad ruodh Aram nochoko jolweny mage duto momonjo Samaria.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
25 Negilworo dalano amingʼa ma kech maduongʼ mane omako Samaria nomedore ma wi punda ne ingʼiewo gi fedha ma pekne romo kilo achiel, to ondongʼ mar owuoch akuru ningʼiewo gi fedha ma pekne romo achiel kuom apar mar kilo.
Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
26 Kane ruodh Israel kalo machiegni gi ohinga mar dala maduongʼno, dhako moro noywak malit kawacho niya, “Konya, ruodha!”
Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
27 Ruoth nodwoke niya, “Ka Jehova Nyasaye ok konyi, ere kama dayudnie konyruok.” Dobed kar dino cham, koso kar biyo divai?
Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
28 Eka nopenje niya, “Angʼo marach?” To nodwoke niya, “Dhakoni nowachona mondo agol wuoda mondo wacham kawuono to kiny en bende nogol wuode mondo wacham.”
Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
29 Omiyo ne watedo wuoda kendo wachamo. Kinyne ne awachone niya, In bende gol wuodi mi wacham, kare en to nosepando wuode.
Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
30 Kane ruoth owinjo weche dhakono noyiecho lepe. Wachni notimore ka ruoth ne wuotho ewi ohinga, mi ji nongʼiye, moneno korwako pien gugru ei lepe.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
31 Nowacho niya, “Mad Nyasaye chwada malit ka dipo kawuono ok angʼado wi Elisha wuod Shafat oko!”
Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
32 Koro noyudo Elisha obet e ode ka en gi jodonge. Ruoth nooro jootene motelo e nyime, to kane pok ochopo, Elisha nowachone jodonge niya, “Donge uneno ka koro janekni oro ngʼato mondo obi onega? Winjuru, ka jaote ochopo, to ulor dhoot matek ma kik odonji, nimar ruodhe luwo bangʼe machiegni.”
Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
33 Kane pod owuoyonegi, jaote nochopo ire. Kendo ruoth nowachone niya, “Masirani oa mana kuom Jehova Nyasaye, omiyo onge tiende medo geno kuom Jehova Nyasaye.”
Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”

< 2 Ruodhi 6 >