< 2 Weche Mag Ndalo 21 >

1 Jehoshafat notho kaka kwerene kendo noyike but kwerene e Dala Maduongʼ mar Daudi kendo Jehoram wuode nobedo ruoth kare.
Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
2 Owete Jehoram ma yawuot Jehoshafat ne gin Azaria gi Jehiel gi Zekaria kod Azariahu gi Mikael kod Shefatia. Magi duto ne gin yawuot Jehoshafat ruodh Israel.
Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
3 Wuon-gi nosemiyogi mwandu mangʼeny mag fedha gi dhahabu gi gik moko ma nengogi tek kaachiel gi mier mag Juda mochiel gohinga motegno, kata kamano loch pinye nomiyo Jehoram pinyruoth nikech ne en wuode makayo.
Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
4 Kane Jehoram nosegurore motegno e kom duongʼ wuon mare, nonego owetene gi ligangla kaachiel gi joka dhood ruoth mamoko mag Israel.
Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
5 Jehoram ne ja-higni piero adek gariyo kane obedo ruoth, kendo norito piny kodak Jerusalem kuom higni aboro.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
6 Noluwo timbe mag ruodhi Israel mana kaka jood Ahab notimo nimar nokendo nyar Ahab. Notimo timbe mamono e nyim Jehova Nyasaye.
Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
7 Kata kamano Jehova Nyasaye ne ok otieko od Daudi nikech noparo singruok mane otimo kode. Nosesingore ne Daudi gi ogandane ni ginibed e loch nyaka chiengʼ.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
8 E ndalo loch Jehoram, Edom nongʼanyo ne Juda mi gibedo gi ruodhgi giwegi.
Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
9 Omiyo Jehoram nodhi kuno gi jotende kod gechene duto mag lweny. Jo-Edom nolwore kaachiel gi jotend gechene mag lweny, to nochiewo gotieno momwomogi.
Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
10 Nyaka chil kawuono jo-Edom pod ongʼanyo ne jo-Juda. Jo-Libna bende nongʼanyo e ndalono nikech Jehoram noweyo Jehova Nyasaye ma Nyasach kwerene.
Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
11 Bende ne osegero kuonde motingʼore malo mag lemo e gode matindo mag Juda kendo nomiyo jo-Jerusalem oweyo Nyasaye kendo omiyo jo-Juda bende orwenyo.
Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
12 Jehoram nonwangʼo baruwa koa ir Elija janabi mawacho niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye ma Nyasach kwaru Daudi wacho, ‘Ok iseluwo yore wuonu Jehoshafat kata mago mag Asa ruodh Juda.
Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
13 To isewuotho e yore mag ruodhi mag Israel, omiyo isemiyo jo-Juda kod jo-Jerusalem oseweyo luwa mana kaka dhood Ahab notimo. Bende isenego oweteni monywoligo ma nyithind wuonu hie, joma ne ber moloyi.
Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
14 Koro omiyo Jehova Nyasaye biro chwado jogi, yawuoti kod mondi kod gimoro amora miluongo ni mari, noyud chwat malit.
Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
15 In iwuon nibed gi tuo marach manocham nyimbiyi, kendo tuoni nomi nyimbiyi wuog oko.’”
Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
16 Jehova Nyasaye nomiyo jo-Filistia gi jo-Arabu modak mokiewo kod jo-Kush obedo mamono kod Jehoram.
Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
17 Negimonjo Juda magi kedo kode kendo negipeyo gik moko duto mane nitie e od ruoth kaachiel gi yawuote kod monde. Onge wuode mane odongʼ makmana wuode ma chogo miluongo ni Ahazia.
Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
18 Bangʼ mano Jehova Nyasaye nogoyo Jehoram gi tuo malich momako nyimbiye ma ok thiedhre.
Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
19 Bangʼ kinde manok madirom higni ariyo, tuone nomedore ma nyimbiye nowuok oko omiyo notho ka en gi rem malich. Joge ne ok olosone mach mar magenga kaka nolosne kwerene.
Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
20 Jehoram ne ja-higni piero adek gariyo ka nodoko ruoth, kendo norito piny kuom higni aboro kodak Jerusalem. Notho maonge ngʼama nokuyo kuom thone kendo noyike e Dala Maduongʼ mar Daudi to ok kuma iyikoe ruodhi.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.

< 2 Weche Mag Ndalo 21 >