< 1 Samuel 9 >
1 Ne nitie ja-Benjamin moro mongʼere ma nyinge Kish wuod Abiel, ma wuod Zeror, ma wuod Bekorath, ma wuod Afia ma ja-Benjamin.
Ará Benjamini kan wà, ẹni tí ó jẹ́ aláàánú ọlọ́rọ̀, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiṣi, ọmọ Abieli, ọmọ Serori, ọmọ Bekorati, ọmọ Afiah ti Benjamini.
2 Ne en gi wuowi miluongo ni Saulo, ne en rawera ma jaber e kind jo-Israel bende ne en rabora ma ji moko ne rem mana e goke.
Ó ní ọmọkùnrin kan tí à ń pè ní Saulu, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó yanjú, tí ó jẹ́ arẹwà, tí kò sí ẹni tó ní ẹwà jù ú lọ láàrín gbogbo àwọn ọmọ Israẹli—láti èjìká rẹ̀ lọ sí òkè, ó ga ju gbogbo àwọn ènìyàn tókù lọ.
3 Chiengʼ moro punde mag Kish wuon Saulo nolal kendo Kish nowachone wuode ma Saulo niya, “Kaw achiel kuom jotich mondo udhigo udwar punde.”
Nísinsin yìí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó jẹ́ ti Kiṣi baba Saulu sì sọnù. Nígbà náà, Kiṣi sọ fún Saulu ọmọ rẹ̀ pé, “Mú ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ pẹ̀lú rẹ kí ẹ lọ láti wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.”
4 Omiyo nokadho e piny got mar Efraim kod alwora mar Shalisha, to ok ne giyudogi. Negidhiyo ma gichopo e gwenge mag Shaalim, to punde ne onge kuondego. Eka nokadho e piny Benjamin, to ne ok giyudogi.
Bẹ́ẹ̀ ní ó kọjá láàrín àwọn ìlú olókè Efraimu, ó sì kọjá ní àyíká ilẹ̀ Ṣaliṣa, ṣùgbọ́n wọn kò rí wọn. Wọ́n sì kọjá lọ sí òpópó Ṣaalimu, ṣùgbọ́n àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kò sí níbẹ̀. Nígbà náà, ó kọjá ní agbègbè Benjamini, wọn kò sì rí wọn.
5 Kane gichopo e gwenge mag Zuf, Saulo nowachone jatich mane ni kode niya, “Bi wadogi, dipo ka wuora oweyo paro punde kendo mochako mana parowa.”
Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Sufu, Saulu sọ fún ìránṣẹ́ tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí á padà sẹ́yìn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, baba mi yóò dá ìrònú rẹ̀ dúró nípa àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yóò sì bẹ̀rẹ̀ àníyàn nípa wa.”
6 To jatich nodwoke kawachone niya, “Iwinjo, e dalano nitiere ngʼat Nyasaye moro marahuma kendo gik mowacho duto timore mana kaka owacho. Bi wadhi ire koro nikech onyalo nyisowa yo monego waluw.”
Ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ náà fún un ní èsì pé, “Wò ó, ní inú ìlú yìí ọkùnrin ènìyàn Ọlọ́run kan wà; ó jẹ́ ẹni tí wọ́n ń bu ọlá fún, àti gbogbo ohun tí ó bá sọ ní ó máa ń jẹ́ òtítọ́. Jẹ́ kí á lọ síbẹ̀ nísinsin yìí, bóyá yóò sọ fún wá ọ̀nà tí a yóò gbà.”
7 Saulo nowachone jatich niya, “To ka wadhi, en angʼo ma wabiro miyo ngʼatni? Chiemo mane ni e mifukewa oserumo. Waonge kod mich ma wanyalo tero ne ngʼat Nyasaye. En angʼo ma wan-go?”
Saulu sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀, “Tí àwa bá lọ, kín ni àwa lè fún ọkùnrin náà? Oúnjẹ inú àpò wa ti tán. A kò sì ní ẹ̀bùn láti mú lọ sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Kí ni a ní?”
8 Jatich nowachone kendo niya, “An-gi pesa moko manok. Abiro miye ngʼat Nyasaye mondo onyiswa yo monego waluw.”
Ìránṣẹ́ sì dá a lóhùn lẹ́ẹ̀kan sí i. “Wò ó,” ó wí pé, “Mo ní ìdámẹ́rin ṣékélì fàdákà lọ́wọ́. Èmi yóò fún ènìyàn Ọlọ́run náà kí ó lè fi ọ̀nà hàn wá.”
9 Chon e piny Israel kane ngʼato dhi penjo Nyasaye wach ne owacho niya, “Bi wadhi ka Janen,” nikech ngʼat miluongo ni janabi ndaloni ne iluongo ni janen.
(Tẹ́lẹ̀ ní Israẹli tí ọkùnrin kan bá lọ béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run, yóò wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì náà,” nítorí àwọn alásọtẹ́lẹ̀ ìsinsin yìí ni wọ́n ń pè ní wòlíì).
10 Saulo nowachone jatich niya, “Mano ber, bi wadhi.” Omiyo negiwuok ma gidhi e dala kama ngʼat Nyasaye nodakie.
Saulu sọ fún ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ pé ó dára, “Jẹ́ kí a lọ.” Wọ́n jáde lọ sí ìlú tí ènìyàn Ọlọ́run náà ń gbé.
11 Kane giidho got matin-no ka gichomo dalano negiromo gi nyiri moko kadhi umbo pi kendo ne gipenjogi niya, “Bende ngʼat makoro nika?”
Bí wọ́n ṣe ń lọ ní orí òkè sí ìlú náà, wọ́n pàdé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin tí ó ń jáde í bọ̀ láti wá pọn omí. Wọ́n sì bi wọ́n, “Ṣé wòlíì náà wà níbí?”
12 To negidwoko niya, “Ee entie, ero odhi nyimu kanyo, returu. Koro eka odonjo e dalawa kawuono nimar jowa timo misango e kama owal.”
“Ó wà,” wọ́n dáhùn. “Ó ń bẹ níwájú u yín, múra nísinsin yìí, ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wa lónìí ni, nítorí àwọn ènìyàn ní ẹbọ rírú ni ibi gíga.
13 E sa ma usedonjo e dala to ubiro yudo kapok oidho odhi malo kama owal mondo ochiem. Ji ok bi chako chiemo nyaka ochopi, nikech nyaka ogwedh gir timo misango eka bangʼe jomo oluongi nyalo chiemo. Returu mapiyo sani ema unyalo yude.
Kété tí ẹ bá ti wọ ìlú, ẹ ó rí i kí ó tó lọ sí ibi gíga láti lọ jẹun. Àwọn ènìyàn kò sì ní bẹ̀rẹ̀ sí jẹun títí tí yóò fi dé. Torí ó gbọdọ̀ bùkún ẹbọ náà; lẹ́yìn náà, àwọn tí a pè yóò jẹun. Gòkè lọ nísinsin yìí, ó yẹ kí ẹ rí i ní àkókò yìí.”
14 Ne giwuotho mi gidhi nyaka dala, to kane gidonjo kanyo to negineno Samuel, kabiro gwenyore kodgi kochiko kama owal.
Wọ́n gòkè lọ sí ìlú náà, bí wọ́n ti ń wọlé, níbẹ̀ ni Samuẹli, ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wọn bí ó ti ń lọ ibi gíga náà.
15 To chiengʼ motelone biro mar Saulo, noyudo ka Jehova Nyasaye osefwenyo ma ne Samuel.
Olúwa ti sọ létí Samuẹli ní ọjọ́ kan kí Saulu ó tó dé pé,
16 “Kiny kar sa ma kama abiro oro ngʼato moa e piny Benjamin. Wire mondo otel ne joga ma jo-Israel, enores joga e lwet jo-Filistia. Asekecho joga nimar ywakgi osechopona.”
“Ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò ran ọmọkùnrin kan sí ọ láti ilẹ̀ Benjamini. Fi òróró yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí lórí àwọn ọmọ Israẹli, yóò gba àwọn ènìyàn mi kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Filistini. Mo ti bojú wo àwọn ènìyàn mi, nítorí igbe wọn ti dé ọ̀dọ̀ mi.”
17 Kane Samuel ogoyo wangʼe kuom Saulo, Jehova Nyasaye ne owachone niya, “Ma e ngʼat mane awuoyoni kuome nibiro rito ogandana.”
Nígbà tí Samuẹli fojúrí Saulu, Olúwa sọ fún un pé, “Èyí ni ọkùnrin tí mo sọ fún ọ nípa rẹ̀, yóò darí àwọn ènìyàn mi.”
18 Saulo nodhi ir Samuel e dhorangach mopenje niya, “Kiyie to nyisa od janen?”
Saulu sì súnmọ́ Samuẹli ní ẹnu-ọ̀nà ìlú, ó sì wí pé, “Sọ fún mi èmi ń bẹ̀ ọ́ níbo ni ilé wòlíì náà wà.”
19 Samuel nodwoke niya, “An e janen. Tel nyima idhi kama owal maler nimar kawuono ibiro chiemo koda kendo kiny gokinyi abiro weyi idhi kendo ananyisi mago duto man e chunyi.
Samuẹli dáhùn pé, “Èmi ni wòlíì náà. Ẹ máa gòkè lọ ṣáájú mi, ní ibi gíga, ẹ ó sì bá mi jẹun lónìí. Ní òwúrọ̀ ni èmi yóò tó jẹ́ kí ẹ lọ, gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ ní èmi yóò sọ fún ọ.
20 Kor ka wach punde mane olal ndalo adek mokadho to owe chandi nimar oseyudgi. Koso en ngʼa ma chuny jo-Israel duto dwaro ka ok en in gi od wuonu?”
Fún ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sọnù fún ọjọ́ mẹ́ta sẹ́yìn, má ṣe dààmú nípa wọ́n: a ti rí wọn. Sí ta ni gbogbo ìfẹ́ Israẹli wà? Bí kì í ṣe sí ìwọ àti sí gbogbo ilé baba à rẹ.”
21 Saulo nodwoko niya, “Donge an ja-Benjamin, oganda matin ahinya ei Israel, to donge dhoodwa bende e dhoot matin, moloyo ei oganda mar Benjamin? Angʼo momiyo iwacho wechegi kuoma?”
Saulu dáhùn pé, “Ṣùgbọ́n èmi kì í há ṣe ẹ̀yà Benjamini? Kékeré nínú ẹ̀yà Israẹli. Ìdílé mi kò ha rẹ̀yìn jùlọ nínú gbogbo ẹ̀yà Benjamini? Èéṣì ti ṣe tí ìwọ sọ̀rọ̀ yìí sí mi?”
22 Eka Samuel nokelo Saulo gi jatije kar budho moketogi gibet e kom manyime kuom ji duto mane oluongo mane nyalo romo ji piero adek.
Nígbà náà ni Samuẹli mú Saulu pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ inú gbọ̀ngán, ó sì mú wọn jókòó sí iwájú àwọn tí a pè—tí wọn tó ọgbọ̀n.
23 Samuel ne onyiso jatedo niya, “Kel lemo mar ringʼo mane amiyi, mane anyisi ni iket tenge.”
Samuẹli sọ fún alásè pé, “Mú ìpín ẹran tí mo fún ọ wá, èyí tí mo sọ fún ọ pé kí o yà sọ́tọ̀.”
24 Eka jatedo nokawo em gi sembe moketo e nyim Saulo. Samuel nowacho niya, “Ma e gima nokan-ni, cham, nikech nokan-nigo ne nyasini, chakre e kinde mane aluongoe welo.” Eka Saulo nochiemo gi Samuel chiengʼno.
Alásè náà sì gbé ẹsẹ̀ náà pẹ̀lú ohun tí ó wà lórí i rẹ̀, ó sì gbé e síwájú Saulu. Samuẹli wí pé, “Èyí ni ohun tí a fi pamọ́ fún ọ. Jẹ, nítorí a yà á sọ́tọ̀ fún ọ, fún ìdí yìí, láti ìgbà tí mo ti wí pé, ‘Mo ní àlejò tí a pè.’” Saulu sì jẹun pẹ̀lú Samuẹli ní ọjọ́ náà.
25 Kane gisea e kama owal mi gidwogo e dala, Samuel nowuoyo gi Saulo ka gin kode ewi ode malo.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọn ti sọ̀kalẹ̀ láti ibí gíga náà wá sí inú ìlú, Samuẹli sì bá Saulu sọ̀rọ̀ lórí òrùlé ilé e rẹ̀.
26 Ne gichiewo ka piny yawore, eka Samuel noluongo Saulo ewi ot, kowachone niya, “Ikri abiro gonyi mondo ichak wuodhi.” Kane Saulo oseikore, en kod Samuel ne giwuok oko.
Wọ́n sì dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́, ó pe Saulu sórí òrùlé pé, “Múra, èmi yóò rán ọ lọ.” Nígbà tí Saulu múra tán òun àti Samuẹli jọ jáde lọ síta.
27 Kane oyudo gin e bath dala, Samuel nowachone Saulo niya, “Nyis jatichni mondo otel, in to dongʼ chien mondo amiyi wach moa kuom Nyasaye.” Omiyo jatijno notimo kamano.
Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìpẹ̀kun ìlú náà, Samuẹli wí fún Saulu pé, “Sọ fún ìránṣẹ́ náà kí ó máa lọ ṣáájú u wa,” ìránṣẹ́ náà sì ṣe bẹ́ẹ̀, “Ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó dúró díẹ̀, kí èmi kí ó lè sọ ọrọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún ọ.”