< 1 Samuel 20 >

1 Eka Daudi noringo koa Nayoth e gwengʼ Rama mine odhi ir Jonathan mopenje niya, “Angʼo masetimo? Ere kethona? Rach mane ma asetimo ne wuonu, momiyo odwaro kawo ngimana?”
Nígbà náà ni Dafidi sá kúrò ní Naioti ti Rama ó sì lọ sọ́dọ̀ Jonatani ó sì béèrè pé, “Kí ni mo ṣe? Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Báwo ni mo ṣe ṣẹ baba rẹ, tí ó sì ń wá ọ̀nà láti gba ẹ̀mí mi?”
2 Jonathan nodwoke niya, “Onge. Ok ibi tho! Winji, wuonwa ok tim gimoro amora, bedni oduongʼ kata otin, ma ok onyisa. Angʼo madimi opandna wachni? Ok en kamano!”
Jonatani dáhùn pé, “Kí a má rí i! Ìwọ kò ní kú! Wò ó baba mi kì í ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí tí ó kéré, láìfi lọ̀ mí. Èéṣe tí yóò fi fi èyí pamọ́ fún mi? Kò rí bẹ́ẹ̀.”
3 Daudi to nowacho ka kwongʼore niya, “Wuoru ongʼeyo malongʼo kaka igena mi osewacho e chunye ni, ‘Jonathan ok onego ngʼe wachni nikech chunye nyalo bedo gi lit.’ Kata kamano akwongʼora gi nying Jehova Nyasaye mangima to gi nyingi ni kinda gi tho odongʼ mana ondamo achiel.”
Ṣùgbọ́n Dafidi tún búra, ó sì wí pé, “Baba rẹ mọ̀ dáradára pé mo rí ojúrere ní ojú rẹ, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, ‘Jonatani kò gbọdọ̀ mọ èyí yóò sì bà á nínú jẹ́.’ Síbẹ̀ nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà láààyè, ìgbésẹ̀ kan ni ó wà láàrín ìyè àti ikú.”
4 Jonathan nowacho ni Daudi niya, “Gimoro amora midwaro ni atim abiro timoni.”
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe, èmi yóò ṣe é fún ọ.”
5 Omiyo Daudi nowacho niya, “Winji, kiny en Sawo mar Dwe manyien kendo nitie budho ma onego bed ni achiemo gi ruoth, to we adhi apondi oko nyaka chop odhiambo mar orucha.
Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Wò ó, ọ̀la ni oṣù tuntun, mo sì gbọdọ̀ bá ọba jẹun, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó lọ láti fi ara pamọ́ lórí pápá títí di àṣálẹ́ ọjọ́ kẹta.
6 Ka wuonu ok onena e nyasini, to nyise ni, ‘Daudi nokwaya mondo amiye thuolo odhi dalagi Bethlehem mapiyo piyo, nikech anywolagi duto nigi misango mar higa ka higa.’
Bí ó bá sì ṣe pé baba rẹ bá fẹ́ mi kù, kí o sì wí fún un pé, ‘Dafidi fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ béèrè ààyè láti sáré lọ sí Bẹtilẹhẹmu ìlú rẹ̀ nítorí wọ́n ń ṣe ẹbọ ọdọọdún ní ibẹ̀ fún gbogbo ìdílé rẹ̀.’
7 Ka owacho ni, ‘Mano ber,’ eka anabed gi adieri ni jatichni nigi kwe. To ka mirima omake, to ibiro bedo gi adiera ni oseketo chunye ni nyaka to onega.
Tí o bá wí pé, ‘Àlàáfíà ni,’ nígbà náà, ìránṣẹ́ rẹ wà láìléwu. Ṣùgbọ́n tí ó bá bínú gidigidi, ìwọ yóò mọ̀ dájú pé ó pinnu láti ṣe ìpalára mi.
8 In to koro bed ja-adiera ne jatichni, nikech isekwongʼori kode e nyim Jehova Nyasaye. To ka an jaketho to nega in iwuon! Angʼo ma dimi iketa e lwet wuonu?”
Ṣùgbọ́n ní tìrẹ ìwọ, fi ojúrere wo ìránṣẹ́ rẹ; nítorí tí ìwọ ti bá a dá májẹ̀mú pẹ̀lú rẹ níwájú Olúwa. Tí mo bá jẹ̀bi, pa mí fún ara rẹ! Èéṣe tí ìwọ yóò fi fi mí lé baba rẹ lọ́wọ́?”
9 Jonathan nowachone niya, “Mano ok nyal timore! Ka dine angʼeyo kata mana matin ni wuora dwaro timoni marach, donge danyisi?”
Jonatani wí pé, “Kí a má rí i! Ti mo bá ti gbọ́ tí baba mi ti pinnu láti pa ọ́ lára, ṣé èmi kò ní sọ fún ọ?”
10 Daudi nopenje niya, “Ngʼa mabiro wachona ka wuonu odwoki gi gero?”
Nígbà náà ni Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Ta ni yóò sọ fún mi tí baba rẹ̀ bá dá ọ lóhùn ní ohùn líle?”
11 Jonathan nowacho niya, “Bi wadhi kuma opondo.” Omiyo negidhi giduto.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Wá, jẹ́ kí a jáde lọ sórí pápá.” Nígbà náà wọ́n sì jáde lọ.
12 Eka Jonathan nowachone Daudi niya, “Gi nying Jehova Nyasaye ma Nyasach Israel, abiro wuoyo gi wuora e sa maka ma orucha! Ka en gi paro maber kuomi, to donge abiro anyisi?
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Mo fi Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli búra pé, èmi yóò rí i dájú pé mo gbọ́ ti ẹnu baba mi ní ìwòyí ọ̀la tàbí ní ọ̀túnla! Bí ó bá sì ní inú dídùn sí ọ, èmi yóò ránṣẹ́ sí ọ, èmi yóò sì jẹ́ kí o mọ̀?
13 To ka wuora nigi chuny mar hinyi, to aweyo ma ok anyisi kendo konyi mondo itony idhi gi kwe, to mondo Jehova Nyasaye ochwada malit. Mad Jehova Nyasaye obed kodi mana kaka osebedo gi wuora.
Ṣùgbọ́n tí baba mi bá fẹ́ pa ọ́ lára, kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí Jonatani; tí èmi kò bá jẹ́ kí o mọ̀, kí n sì jẹ́ kí o lọ ní àlàáfíà. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pẹ̀lú baba mi.
14 To yie itimna ngʼwono mana machal gi ngʼwono mosiko mar Jehova Nyasaye e ndalo duto mag ngimana, mondo kik nega,
Ṣùgbọ́n fi àìkùnà inú rere hàn mí bí inú rere Olúwa, níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè kí wọ́n má ba à pa mí.
15 kendo kik iwe timo ngʼwono ni jooda kata mana ka Jehova Nyasaye osetieko wasik Daudi e wangʼ piny.”
Má ṣe ké àánú rẹ kúrò lórí ìdílé mi títí láé. Bí Olúwa tilẹ̀ ké gbogbo ọ̀tá Dafidi kúrò lórí ilẹ̀.”
16 Omiyo Jonathan nokwongʼore gi joka Daudi, kowacho niya, “Mad Jehova Nyasaye mondo ongʼad bura ne wasik Daudi.”
Nígbà náà ni Jonatani bá ilé Dafidi dá májẹ̀mú wí pé, “Olúwa yóò pe àwọn àti Dafidi láti ṣírò.”
17 Omiyo Jonathan noketo Daudi mochako ojiwo kwongʼruokne nikech nohere, nimar nohere mana kaka oherore owuon.
Jonatani mú kí Dafidi tún ìbúra ṣe nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí i, nítorí tí ó fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti fẹ́ràn ara rẹ̀.
18 Eka Jonathan nowachone Daudi niya, “Kiny en Sawo mar dwe manyien kendo kiny nongʼere ni ionge nikech komi nobed nono.
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Lọ́la ní ibi àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun, a yóò fẹ́ ọ kù, nítorí ààyè rẹ yóò ṣófo.
19 To kochopo orucha kar odhiambo kanyo to idhi kama ne ipondoe mokwongo ka wechegi nochakore kendo irit but kit Ezel.
Ní ọ̀túnla lọ́wọ́ alẹ́ lọ sí ibi tí o sá pamọ́ sí nígbà tí ìṣòro yìí bẹ̀rẹ̀, kí o sì dúró níbi òkúta Eselu.
20 Abiro diro aserni adek e bathe kanyo, ka gima atemo lengʼo gimoro.
Èmi yóò ta ọfà mẹ́ta sí ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀, gẹ́gẹ́ bí i pé mo ta á sí àmì ibìkan.
21 Eka abiro oro rawera kawachone ni, ‘Dhi idwar aserni.’ To kawachone ni, ‘Ne, aserni ni e bathi koni; kelgi ka, eka ibi, nikech akwongʼora gi nying Jehova Nyasaye mangima ni onge gima biro hinyi kendo onge gima rach.’
Èmi yóò rán ọmọdékùnrin kan èmi yóò wí fún un wí pé, ‘Lọ, kí o lọ wá ọfà náà.’ Tí mo bá sọ fún un wí pé, ‘Wò ó, ọfà wọ̀nyí wà ní ibi báyìí ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ rẹ; kó wọn wá síbí,’ kí o sì wá, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà ní ààyè, o wà ní àlàáfíà; kò sí ewu.
22 To ka awachone rawera ni, ‘Ne, aserni ni nyimi,’ eka nyaka idhi nikech Jehova Nyasaye dwaro ni idhi adhiya.
Ṣùgbọ́n tí mo bá sọ fún ọmọdékùnrin náà pé, ‘Wò ó, àwọn ọfà náà ń bẹ níwájú rẹ,’ ǹjẹ́ máa bá tìrẹ lọ, nítorí Olúwa ni ó rán ọ lọ.
23 To kuom weche mawasewuoyoe to ipar, nimar Jehova Nyasaye en janeno e kindwa nyaka chiengʼ.”
Nípa ọ̀rọ̀ tí èmi àti ìwọ jọ sọ, rántí Olúwa jẹ́ ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti èmi títí láéláé.”
24 Omiyo Daudi nopondo oko kendo kane Sawo mar Dwe manyien ochopo, to ruoth nobet piny mondo ochiem.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.
25 Nobet kare mane ojabetie but kor ot, ka gimanyore gi Jonathan, Abner to nobet bath Saulo, kom Daudi to ne ninono.
Ọba sì jókòó gẹ́gẹ́ bí ipò o rẹ̀ ní ibi tí ó máa ń jókòó lórí ìjókòó tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri, ní òdìkejì Jonatani, Abneri sì jókòó ti Saulu, ṣùgbọ́n ààyè Dafidi sì ṣófo.
26 Saulo ne ok owacho gimoro chiengʼno, nikech noparo e chunye niya, “Nyaka bed ni Daudi osetimo gimoro marach, omiyo ok oler adiera emomiyo ok obiro e nyasi.”
Saulu kò sọ nǹkan kan ní ọjọ́ náà, nítorí ó rò pé, “Nǹkan kan ti ṣẹlẹ̀ sí Dafidi láti jẹ́ kí ó di aláìmọ́ lóòtítọ́ ó jẹ́ aláìmọ́.”
27 To kata mana kinyne, ma en chiengʼ mar ariyo mar dwe, kom Daudi ne pod ninono. Eka Saulo nowachone Jonathan wuode niya, “Angʼo momiyo wuod Jesse ok obiro e chiemo, chakre nyoro nyaka kawuono?”
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì, ní ọjọ́ kejì oṣù, ààyè Dafidi sì tún ṣófo. Nígbà náà ni Saulu wí fún ọmọ rẹ̀ Jonatani pé, “Kí ni ó dé tí ọmọ Jese kò fi wá sí ibi oúnjẹ, lánàá àti lónìí?”
28 Jonathan nodwoko niya, “Daudi nohomba kokwaya thuolo mondo odhi Bethlehem.”
Jonatani sì dáhùn pé, “Dafidi bẹ̀ mí tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ fún ààyè láti lọ sí Bẹtilẹhẹmu.
29 Nokwayo niya, “Yiena mondo adhi nikech joodwa timo misango e dala kendo owadwa nochika matek ni nyaka achop kuno. Koro akwayi ni yie ingʼwon-na mondo adhi ane owetena. Mano ema omiyo ok osebiro e mesa ruoth.”
Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí n lọ, nítorí pé ìdílé wa ń ṣe ìrúbọ ní ìlú, àwọn ẹ̀gbọ́n ọ̀n mi sì ti pàṣẹ fún mi láti wà níbẹ̀; tí èmi bá rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí n lọ láti lọ rí àwọn ẹ̀gbọ́n mi.’ Ìdí nìyìí tí kò fi wá sí orí tábìlì oúnjẹ ọba.”
30 Saulo notoyo mirimbe kuom Jonathan mowachone niya, “In wuod dhako ma wiye tek kendo ma ja-mahundu! Donge angʼeyo ni isebedo jakor wuod Jesse makelo wichkuot ne in iwuon kendo ne minu monywoli?
Ìbínú Saulu sì ru sí Jonatani ó sì wí fún un pé, “Ìwọ ọmọ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀ búburú yìí, ṣé èmi kò ti mọ̀ pé, ìwọ ti yan ọmọ Jese fún ìtìjú ti ara rẹ àti fún ìtìjú màmá rẹ tí ó bí ọ?
31 Ka wuod Jesse pod ngima e pinyni to in kata pinyruodhi ok nyal gurore. Koro or wach mondo okelnago nikech nyaka otho!”
Níwọ́n ìgbà tí ọmọ Jese bá wà láààyè lórí ilẹ̀ ayé, a kì yóò fi ẹsẹ̀ ìwọ tàbí ti ìjọba rẹ múlẹ̀. Nísinsin yìí ránṣẹ́ kí o sì lọ mú un wá fún mi, nítorí ó gbọdọ̀ kú!”
32 Jonathan nopenjo wuon-gi niya, “Angʼo momiyo nyaka otho? Angʼo mosetimo?”
Jonatani béèrè lọ́wọ́ baba rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwa yóò fi pa á? Kí ni ó ṣe?”
33 To Saulo nobaye gi tongʼ mondo onege. Eka Jonathan nongʼeyo ni kare wuon-gi dwaro nego Daudi.
Ṣùgbọ́n Saulu ju ọ̀kọ̀ rẹ̀ sí Jonatani láti gún un pa. Nígbà náà ni Jonatani mọ̀ pé baba rẹ̀ mọ̀ ọ́n mọ̀ fẹ́ pa Dafidi ni.
34 Jonathan nochungʼ moa e mesa ka mirima mager omake chiengʼ mar ariyo mar dwe mane ok ochiemo, nikech chunye ne lit kod timbe wuon-gi mag wichkuot mane otimone Daudi.
Bẹ́ẹ̀ ni Jonatani sì fi ìbínú dìde kúrò ni ibi oúnjẹ, kò sì jẹun ni ọjọ́ kejì oṣù náà, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ gidigidi fún Dafidi, nítorí pé baba rẹ̀ dójútì í.
35 Kinyne gokinyi Jonathan nodhi oko e kargi mar romo gi Daudi. Ne en-gi wuowi matin,
Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jonatani jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dafidi ti fi àdéhùn sí, ọmọdékùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.
36 kendo nowachone wuowino niya, “Ringi mondo idwar aserni madirogi.” E sa ma wuowino ne ringo, nodiro asere mokadhe.
Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.
37 Ka wuowino nochopo kama asech Jonathan ne olwarie, Jonathan noluonge gi dwol maduongʼ niya, “Donge asere ni nyimi kanyo?”
Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jonatani ta, Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”
38 Eka nokok kowacho niya, “Reti! Dhi piyo! Kik ichungʼ!” Wuowino nokwanyo asereno mi odok ir ruodhe.
Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jonatani sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.
39 Wuowino ne ok ongʼeyo gimoro amora mane timore, makmana Jonathan gi Daudi kende ema nongʼeyo.
(Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jonatani àti Dafidi ni ó mọ ọ̀ràn náà.)
40 Eka Jonathan nomiyo wuowino gige mag lweny mowachone niya, “Dhiyo idwokgi dala.”
Jonatani sì fi apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú.”
41 Bangʼ ka wuowino nosedhi, Daudi nowuok yo milambo mar dir kidi, mi okulore piny e nyim Jonathan nyadidek ka lend wangʼe mulo piny. Eka ne gimosore ma giywak giduto to Daudi noywak moloyo.
Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dafidi sì dìde láti ibi ìhà gúúsù òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jonatani, wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sọkún, èkínní pẹ̀lú èkejì rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi sọkún púpọ̀ jù.
42 Jonathan nowachone Daudi niya, “Dhi gi kwe nimar wasesingore e nyim Jehova Nyasaye ni osiep man e kindwa kodi ka wakwongʼore niya, Jehova Nyasaye obed janeno e kindi koda kendo e kind nyikwayi kod nyikwaya nyaka chiengʼ” Eka Daudi nowuok to Jonathan bende nodok dala.
Jonatani sì wí fún Dafidi pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí jùmọ̀ búra ni orúkọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrín èmi àti ìwọ, láàrín irú-ọmọ mi àti láàrín irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jonatani sì lọ sí ìlú.

< 1 Samuel 20 >