< 1 Samuel 2 >

1 Eka Hana nolemo kawacho niya, “Chunya oil gi Jehova Nyasaye; Jehova Nyasaye osetingʼa malo ma tekona onenore. Gi dhoga asungora ne wasika, nikech amor gi warruokni.
Hana sì gbàdúrà pé, “Ọkàn mi yọ̀ sí Olúwa; ìwo agbára mi ni a sì gbé sókè sí Olúwa. Ẹnu mi sì gbòòrò lórí àwọn ọ̀tá mi, nítorí ti èmi yọ̀ ni ìgbàlà rẹ̀.
2 “Onge ngʼama ler ka Jehova Nyasaye; kendo onge moro makmana in; onge Lwanda machal gi Nyasachwa.
“Kò sí ẹni tí ó mọ́ bi Olúwa; kò sí ẹlòmíràn bí kò ṣe ìwọ; kò sì sí àpáta bi Ọlọ́run wa.
3 “Weuru siko ka uwuoyo gi sunga ahinya, kata weyo dhogi wuoyo gi ngʼayi, nikech Jehova Nyasaye en Nyasaye mongʼeyo nimar en ema onono timbe.
“Má ṣe halẹ̀; má ṣe jẹ́ kí ìgbéraga ti ẹnu yín jáde nítorí pé Ọlọ́run olùmọ̀ ni Olúwa, láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá ni a ti ń wọn ìwà.
4 “Atunge mag jolweny osetur, to jogo mayom yom osemi teko.
“Ọ̀run àwọn alágbára ti ṣẹ́, àwọn tí ó ṣe aláìlera ni a fi agbára dì ní àmùrè.
5 Jogo mane nigo koro tiyo mondo oyud chiemo, to jogo mane denyo koro kegi orumo. Mano mane migumba osenywolo nyithindo abiriyo to mano mane nigi yawuowi to koro odongʼ nono.
Àwọn tí ó yọ̀ fún oúnjẹ ti fi ara wọn ṣe alágbàṣe, àwọn tí ebi ń pa kò sì ṣe aláìní. Tó bẹ́ẹ̀ tí àgàn fi bí méje. Ẹni tí ó bímọ púpọ̀ sì di aláìlágbára.
6 “Jehova Nyasaye ema kelo tho, kendo chiwo ngima; en ema onego kendo ochiero. (Sheol h7585)
“Olúwa pa ó sì sọ di ààyè; ó mú sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú, ó sì gbé dìde. (Sheol h7585)
7 Jehova Nyasaye ema kelo dhier gi mwandu, josunga odwoko piny, to joma muol otingʼo malo.
Olúwa sọ di tálákà; ó sì sọ di ọlọ́rọ̀; ó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì gbé sókè.
8 Otingʼo jachan malo kogolo e buru kendo otingʼo ngʼama odhier malo kogolo e ipidh yugi; omiyo gibedo kaachiel gi yawuot ruodhi bende omiyo gibedoe kombe moyiedhi. “Nimar mise mag piny gin mag Jehova Nyasaye, kanyo ema oserenjoe piny ngima.
Ó gbé tálákà sókè láti inú erùpẹ̀ wá, ó gbé alágbe sókè láti orí òkìtì eérú wá, láti mú wọn jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé, láti mu wọn jogún ìtẹ́ ògo, “Nítorí pé ọ̀wọ́n ayé ti Olúwa ni, ó sì ti gbé ayé ka orí wọn.
9 Obiro chiko tiende joge maler to joricho to nolal ei mudho. “Ngʼato ok lochi mana nikech teko;
Yóò pa ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́, àwọn ènìyàn búburú ni yóò dákẹ́ ní òkùnkùn. “Nípa agbára kò sí ọkùnrin tí yóò borí.
10 joma piem gi Jehova Nyasaye ibiro tur matindo tindo. Obiro mornegi gie polo; kendo Jehova Nyasaye biro ngʼado bura ne tunge piny. “Obiro miyo ruodhe teko kendo obiro miyo teko mar ngʼate mowir onenre.”
A ó fọ́ àwọn ọ̀tá Olúwa túútúú; láti ọ̀run wá ni yóò sán àrá sí wọn; Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ òpin ayé. “Yóò fi agbára fún ọba rẹ̀, yóò si gbé ìwo ẹni àmì òróró rẹ̀ sókè.”
11 Eka Elkana nodok dalane Rama to wuowino noweyo katiyo e nyim Jehova Nyasaye e bwo Eli jadolo.
Elkana sì lọ sí Rama, sí ilé rẹ̀, ọmọ náà sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Olúwa níwájú Eli àlùfáà.
12 Yawuot Eli ne timbegi mono kendo ne ok gidew Jehova Nyasaye.
Àwọn ọmọ Eli sì jẹ́ ọmọ Beliali; wọn kò mọ Olúwa.
13 Koro ma e tim mane jodolo timo ne ji kane ngʼato angʼata ne chiwo misango, kendo kane pod ringʼo chiek, to jatij jadolo ne biroga gi uma mabor man-gi leke adek e lwete.
Iṣẹ́ àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ènìyàn ni pé nígbà tí ẹnìkan bá ṣe ìrúbọ, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, nígbà tí ẹran náà bá ń hó lórí iná, pẹ̀lú ọ̀pá-ẹran náà oníga mẹ́ta ní ọwọ́ rẹ̀.
14 Nolutoga umano e sufuria, kata aguch ringʼo gi agulni mamoko mag tedo kendo jadolo ne kawo ringʼo moro amora ma uma ochwoyo. Mano e kaka negitimo ni jo-Israel duto mane biro Shilo.
Òun a sì fi gún inú apẹ, tàbí àgé tàbí ọpọ́n, tàbí ìkòkò, gbogbo èyí tí ọ̀pá-ẹran oníga náà bá mú wá sí òkè, àlùfáà á mú un fún ara rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí gbogbo Israẹli tí ó wá sí ibẹ̀ ní Ṣilo.
15 To kata ka boche ne pok owangʼ, jatich jadolo ne biroga ma wach ne ngʼama chiwo misango niya, “Mi jadolo ringʼo moko mondo obul nikech ok obi yie kawo ringʼo mosetedi kuomi makmana manumu.”
Pẹ̀lú, kí wọn tó sun ọ̀rá náà, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, á sì wí fún ọkùnrin tí ó ń ṣe ìrúbọ pé, “Fi ẹran fún mi láti sun fún àlùfáà; nítorí tí kì yóò gba ẹran sísè lọ́wọ́ rẹ, bí kò ṣe tútù.”
16 To ka ngʼatno nowachone niya, “We mondo boche okuong owangʼ mondi eka ikaw gimoro amora midwaro,” to jatijno nedwoko niya, “Ngangʼ miyago sani; ka ok imiyago, to abiro kawe githuon.”
Bí ọkùnrin náà bá sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí wọn ó sun ọ̀rá náà nísinsin yìí, kí o sì mú iyekíye tí ọkàn rẹ̀ bá fẹ́,” nígbà náà ni yóò dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó fi í fún mi nísinsin yìí, bí kó ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó fi agbára gbà á.”
17 Richo mag yawuowigi ne lich ahinya e nyim Jehova Nyasaye nikech ne gichayo gima ochiw ne Jehova Nyasaye.
Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì tóbi gidigidi níwájú Olúwa: nítorí tí àwọn ènìyàn kórìíra ẹbọ Olúwa.
18 Samuel to ne tiyo, e nyim Jehova Nyasaye ka en wuowi matin korwako law mayom mar dolo miluongo ni efod.
Ṣùgbọ́n Samuẹli ń ṣe ìránṣẹ́ níwájú Olúwa, ọmọdé, ti a wọ̀ ní efodu ọ̀gbọ̀.
19 Higa ka higa min ne twangʼone law matin kendo terone e kinde mane ojadhi gi chwore ka gidhi timo misango mar higa ka higa.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, ìyá rẹ̀ máa ń dá aṣọ ìlekè péńpé fún un, a sì máa mú wá fún un lọ́dọọdún, nígbà tí ó bá bá ọkọ rẹ̀ gòkè wá láti ṣe ìrúbọ ọdún.
20 Eli negwedho Elkana gi chiege kowacho niya, “Mad Jehova Nyasaye miyi nyithindo gi dhakoni mondo ochul kar mane olamo kokwayo kendo omiyo Jehova Nyasaye.” Bangʼe negidok dalagi.
Eli súre fún Elkana àti aya rẹ̀ pé, “Kí Olúwa fún ọ ní irú-ọmọ láti ara obìnrin yìí wá, nítorí ẹ̀bùn tí ó béèrè tí ó sì tún fún Olúwa.” Wọ́n sì lọ sí ilé wọn.
21 To Jehova Nyasaye ne mor gi Hana; kendo nomako ich monywolo yawuowi adek gi nyiri ariyo. To Samuel nodongo e nyim Jehova Nyasaye.
Olúwa si bojú wo Hana, ó sì lóyún, ó bí ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì. Samuẹli ọmọ náà sì ń dàgbà níwájú Olúwa.
22 Koro Eli mane oseti ahinya; nowinjo timbe duto mane yawuote timo ne jo-Israel kaka negiterore gi mon mane tiyo e dhoranga Hemb Romo.
Eli sì di arúgbó gidigidi, ó sì gbọ́ gbogbo èyí ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe sí gbogbo Israẹli; àti bi wọ́n ti máa ń bá àwọn obìnrin sùn, tí wọ́n máa ń péjọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
23 Nowachonegi niya, “Angʼo momiyo utimo timbegi? Awinjo kuom ji duto timbeu marichogi.
Ó sì wí fún wọn pé, kí ni ó ti ri “Èétirí tí èmi fi ń gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ sí yín? Nítorí tí èmi ń gbọ́ iṣẹ́ búburú yín láti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn.
24 Ooyo yawuota; ok en huma maber ma awinjo kalandore e kind oganda Jehova Nyasaye.
Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí kì ṣe ìròyìn rere èmi gbọ́; ẹ̀yin mú ènìyàn Olúwa dẹ́ṣẹ̀.
25 Ka ngʼato okethone ngʼat machielo to Nyasaye nyalo thegogi; to ka koro ngʼato oketho ne Jehova Nyasaye, en ngʼa mabiro kwayone?” Kata kamano yawuotego ne ok owinjo siem wuon-gi nikech Jehova Nyasaye ne osechano mondo oneg-gi.
Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì, onídàájọ́ yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀: ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí Olúwa, ta ni yóò bẹ̀bẹ̀ fún un?” Wọn kò sì fi etí sí ohùn baba wọn, nítorí tí Olúwa ń fẹ́ pa wọ́n.
26 To wuowi Samuel nomedo dongo; kendo Jehova Nyasaye kod ji ne mor kode.
Ọmọ náà Samuẹli ń dàgbà, ó sì rí ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa, àti ènìyàn pẹ̀lú.
27 Ngʼat Nyasaye moro nobiro ir Eli mowachone niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye wacho, ‘Donge ne afwenyora ratiro ni od wuonu kane pod gin Misri e bwo loch Farao?
Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ Eli wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí, ‘Èmi fi ara mi hàn ní gbangba fún ilé baba rẹ, nígbà tí wọ́n ń bẹ ní Ejibiti nínú ilé Farao.
28 Nayiero wuonu e kind dhout Israel mondo obed jadolona mondo oidh malo e kendona mar misango, mondo owangʼ ubani, kendo orwak law mayom mar dolo miluongo ni efod e nyima. Ne achako amiyo od wuonu misengini duto ma jo-Israel wangʼo gi mach.
Èmi sì yàn án kúrò láàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti jẹ́ àlùfáà mi, láti rú ẹbọ lórí pẹpẹ mi, láti fi tùràrí jóná, láti wọ efodu níwájú mi, èmi sì fi gbogbo ẹbọ tí ọmọ Israẹli máa ń fi iná sun fún ìdílé baba rẹ̀.
29 Angʼo momiyo ichayo misangona kod chiwo ma asechiwoni kar dakna? Angʼo momiyo imiyo yawuoti duongʼ moloya ka uchiemo kendo ubedo machwe un uwegi kendo ka uyiero kuonde mabeyoe moloyo kuom chiwo ka chiwo ma joga Israel chiwo?’
Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi tàpá sí ẹbọ àti ọrẹ mi, tí mo pàṣẹ ní ibùjókòó mi, ìwọ sì bu ọlá fún àwọn ọmọ rẹ jù mí lọ, tí ẹ sì fi gbogbo àṣàyàn ẹbọ Israẹli àwọn ènìyàn mi mú ara yín sanra.’
30 “Kuom mano Jehova Nyasaye ma Nyasach jo-Israel wacho ni, ‘Ne asingora ni odi kod od wuonu nobed jotichna nyaka chiengʼ.’ To koro Jehova Nyasaye wacho ni, ‘Ma ok anatim! Joma miya duongʼ ema abiro miyo duongʼ, to joma ochaya ok nobed gimoro.
“Nítorí náà Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Èmi ti wí nítòótọ́ pé, ilé rẹ àti ilé baba rẹ, yóò máa rìn níwájú mi títí.’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa wí pé, ‘Kí á má rí i! Àwọn tí ó bú ọlá fún mi ni èmi yóò bu ọlá fún, àti àwọn tí kò kà mí sí ni a ó sì ṣe aláìkàsí.
31 Ndalo biro ma anatiekie tekoni kod teko mar od wuonu, mi ok noyudi ngʼato angʼata moti e dhoodu.
Kíyèsi i, àwọn ọjọ́ ń bọ̀ tí èmi ó gé agbára rẹ kúrò, àti agbára baba rẹ, tí kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ.
32 Kendo inibed gi chandruok e kar dakna kata obedo ni jo-Israel none ber to ei anywolani to onge ngʼat manodag amingʼa mabed moti.
Ìwọ yóò rí wàhálà ti Àgọ́, nínú gbogbo ọlá tí Ọlọ́run yóò fi fún Israẹli; kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ láéláé.
33 Ngʼato ka ngʼato kuomu ma ok agolo e tich mar kendona mar misango anawe mondo omi wengeu opongʼ gi pi wangʼ kendo mondo omi chunyu lit, to ogandani duto to notho kapod gin jomatindo.
Ọkùnrin tí ó jẹ́ tìrẹ, tí èmi kì yóò gé kúrò ní ibi pẹpẹ mi ni a ó dá sí láti sọkún yọ lójú àti láti banújẹ́. Ṣùgbọ́n gbogbo irú-ọmọ ilé rẹ̀ ni a ó fi idà pa ní ààbọ̀ ọjọ́ wọn.
34 “‘To gima timore ne yawuoti ariyo ma gin Hofni gi Finehas nobedni ranyisi kendo gibiro tho odiechiengʼ achiel.
“‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ ọkùnrin rẹ̀ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, yóò jẹ́ àmì fún ọ—àwọn méjèèjì yóò kú ní ọjọ́ kan náà.
35 To abiro chungo Jadolona awuon ma en ngʼat ma ja-adiera, manotim gik moko duto man e chunya kod pacha. Abiro guro ode matek, kendo obiro tiyo ndalo duto e nyim ngʼata ma awiro.
Èmi yóò dìde fún ara mi láti gbé àlùfáà olódodo dìde fún ara mi, ẹni tí yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó wà ní ọkàn mi àti inú mi. Èmi yóò fi ẹsẹ̀ ilé rẹ̀ múlẹ̀ gbọningbọnin òun yóò sì ṣe òjíṣẹ́ níwájú ẹni òróró mi ní ọjọ́ gbogbo.
36 To jogo mane dongʼ e dhoodi nobi ire kakulore e nyime mondo omi fedha gi kuon kendo nokwaye niya, “Yie imiya tich dolo moro mondo ayud kaka dayud chiemo machamo.”’”
Nígbà náà olúkúlùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá kù ní ìdílé yín, yóò jáde wá yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀ nítorí ẹyọ fàdákà àti nítorí èépá àkàrà àti ẹ̀bẹ̀ pé, “Jọ̀wọ́ yàn mí sí ọ̀kan nínú iṣẹ́ àwọn àlùfáà, kí èmi kí ó le máa rí oúnjẹ jẹ.”’”

< 1 Samuel 2 >