< 1 Samuel 17 >

1 Koro jo-Filistia nochoko jolweny mag-gi mondo gikedi kendo negichokore kama iluongo ni Soko e piny Juda. Negijot Efes-Damin man e kind Soko gi Azeka.
Filistini kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ fún ogun ní Soko ti Juda. Wọ́n pàgọ́ sí Efesi-Damimu, láàrín Soko àti Aseka,
2 Saulo gi jo-Israel to nochokore mine gibworo e Holo mar Ela kendo negichanore mondo girad gi jo-Filistia.
Saulu àti àwọn ọmọ Israẹli wọ́n kò ara wọ́n jọ pọ̀, wọ́n sì pàgọ́ ní àfonífojì Ela, wọ́n sì gbé ogun wọn sókè ní ọ̀nà láti pàdé àwọn Filistini.
3 Jo-Filistia ne ni ewi got moro to jo-Israel bende ne ni e got machielo to holo ne ni e kindgi.
Àwọn Filistini sì wà ní orí òkè kan àwọn ọmọ Israẹli sì wà ní orí òkè mìíràn, àfonífojì sì wà láàrín wọn.
4 Thuon ma nyinge Goliath, ma ja-Gath nowuok koa e kambi mar jo-Filistia. Borne ne en fut ochiko.
Ọ̀gágun tí a ń pè ní Goliati, tí ó jẹ́ ará Gati, ó wá láti ibùdó Filistini. Ó ga ní ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà àti ìnà ìka kan ní ìbú.
5 Nosidho ogut mula e wiye kendo norwako koti mar lweny mar mula ma pekne oromo kilo piero abich gi abiriyo,
Ó ní àṣíborí idẹ ní orí rẹ̀, ó sì wọ ẹ̀wù tí a fi idẹ pẹlẹbẹ ṣe, ìwọ̀n ẹ̀wù náà sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ṣékélì idẹ.
6 ogwendene to norwakoe mula mothedhi, kendo noliero tongʼ mar mula e ngʼeye.
Òun sì wọ ìhámọ́ra idẹ sí ẹsẹ̀ rẹ̀ àti àpáta idẹ kan láàrín ẹ̀yìn rẹ̀.
7 Bond tongʼe ne chalo gi lodi, lew tonge to pekne ne romo kilo abiriyo. Jatingʼne okumba notelo nyime.
Ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ rí bí apásá ìhunṣọ, orí ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì wọn ẹgbẹ̀ta kilogiramu méje irin, ẹni tí ó ru asà ogun rẹ̀ lọ ṣáájú u rẹ̀.
8 Goliath nochungʼ mokok ne jolweny mag Israel niya, “Angʼo momiyo ubiro kendo uriedo ne lweny? Donge an ja-Filistia, to un, donge un jotich Saulo? Yieruru ngʼato mondo olor obi kama antieni.
Goliati dìde, ó sì kígbe sí ogun Israẹli pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi jáde wá, tí ẹ ṣe tò fún ogun? Ṣé èmi kì í ṣe Filistini ni, àbí ẹ̀yin kì í ṣe ìránṣẹ́ Saulu? Yan ọkùnrin kan kí o sì jẹ́ kí ó sọ̀kalẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
9 To konyalo kedo koda monega, to wabiro bedo jotiju, to ka ahinge mi anege, to ubiro bedo jotijwa ma tiyonwa.”
Tí òhun bá sì le jà tí ó sì pa mí, àwa yóò di ẹrú u yín, ṣùgbọ́n tí èmi bá lè ṣẹ́gun rẹ̀ tí mo sì pa á, ẹ̀yin yóò di ẹrú u wa, ẹ̀yin yóò sì máa sìn wá.”
10 Eka ja-Filistiano nowacho niya, “Kawuononi athiano ne jolweny mag Israel! Miyauru ngʼato mondo wakedgo.”
Nígbà náà Filistini náà wí pé, “Èmi fi ìjà lọ ogun Israẹli ní òní! Ẹ mú ọkùnrin kan wá kí ẹ sì jẹ́ kí a bá ara wa jà.”
11 Kane Saulo gi jo-Israel owinjo weche ja-Filistia, kibaji nogoyogi mi luoro nomakogi.
Nígbà tí Saulu àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Filistini, ìdààmú bá wọn.
12 Daudi ne en wuod ja-Efrath miluongo ni Jesse mane oa Bethlehem e piny Juda. Jesse ne nigi yawuowi aboro to e ndalo Saulo ne en ngʼat moti ma hike ngʼeny.
Nísinsin yìí Dafidi jẹ́ ọmọ ará Efrata kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jese, tí ó wá láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda, Jese ní ọmọ mẹ́jọ, ní àsìkò Saulu ó ti darúgbó ẹni ọdún púpọ̀.
13 Yawuot Jesse adek madongo noluwo Saulo e lweny. Wuowi maduongʼ ne en Eliab, mar ariyo ne Abinadab, to mar adek ne en Shama.
Àwọn ọmọ Jese mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ti dàgbà bá Saulu lọ sí ojú ogun, èyí àkọ́bí ni Eliabu, èyí èkejì ni Abinadabu, èyí ẹ̀kẹta sì ní Ṣamma.
14 Daudi ema ne wuowi matin kuomgi. Yawuowi adek madongo noluwo bangʼ Saulo,
Dafidi ni ó kéré jù nínú wọn. Àwọn àgbà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì tẹ̀lé Saulu,
15 to Daudi ne jadok kinde ka kinde koa ir Saulo mondo odhi okwa romb wuon-gi Bethlehem.
ṣùgbọ́n Dafidi padà lẹ́yìn Saulu, láti máa tọ́jú àgùntàn baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu.
16 Kuom ndalo piero angʼwen ja-Filistiano ne wuok okinyi godhiambo konyisore.
Fún ogójì ọjọ́, Filistini wá síwájú ní àràárọ̀ àti ní ìrọ̀lẹ́ wọ́n sì fi ara wọn hàn.
17 Koro Jesse nowachone Daudi wuode niya, “Kaw atonga mopongʼ gi bando mobul kod makati apar mondo ireti iterne oweteni e kambigi.
Nísinsin yìí Jese wí fún ọmọ rẹ̀ Dafidi pé, “Mú ìwọ̀n efa àti àgbàdo yíyan àti ìṣù àkàrà mẹ́wàá lọ fún àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ kí o sì súré lọ sí ibùdó o wọn.
18 Kaw bende chak mopoto mongʼin apar mondo itergi ne jatendgi. Nenane kaka oweteni dhi mondo iduogna wach maber moa kuomgi.
Kí o sì mú wàrà mẹ́wàá yìí lọ́wọ́ fún adarí ogun tiwọn. Wo bí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ ṣe wà kí o sì padà wá fún mi ní àmì ìdánilójú láti ọ̀dọ̀ wọn.
19 Gin gi Saulo gi jo-Israel duto e holo mar Ela, ka gikedo gi jo-Filistia.”
Wọ́n wà pẹ̀lú Saulu àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli ní àfonífojì Ela, wọ́n bá àwọn Filistini jà.”
20 Okinyi mangʼich Daudi noweyo rombe gi jokwath, notweyo misike mowuok odhi kaka Jesse nonyise. Nochopo e kambi ka jolweny wuok dhi e paw lweny, ka gigoyo koko kendo gigiyo sigich lweny.
Ní àárọ̀ kùtùkùtù Dafidi fi agbo ẹran rẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn olùtọ́jú, ó di ẹrù, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n gẹ́gẹ́ bí Jese ti sọ fún un. Ó dé ibùdó bí àwọn ọmọ-ogun ti ń lọ láti dúró ní ipò wọn ní ojú ogun, wọ́n hó ìhó ogun.
21 Jo-Israel kod jo-Filistia nochanore koni gi kocha ka gimanyore.
Israẹli àti Filistini lọ sí ojú ìjà wọ́n da ojú ìjà kọ ara wọn.
22 Daudi noweyo gigege gi jarit gik moko moringo odhi ir jolweny mi omoso owetene.
Dafidi sì kó ẹrù rẹ̀ ti àwọn olùtọ́jú ohun èlò, ó sì sálọ sí ojú ogun ó sì kí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
23 Kane pod owuoyo kodgi, Goliath mathuon jo-Filistia ma ja-Gath nowuok kuom jolweny kakok kawacho wechege mag ajara mapile kendo Daudi nowinje.
Bí ó ṣe ń bá wọn sọ̀rọ̀, Goliati akíkanjú Filistini tí ó wá láti Gati bọ́ sí iwájú ní ojú ogun, ó sì kígbe fún ìpèníjà, Dafidi sì gbọ́.
24 Kane jo-Israel oneno ngʼatno, to giduto ne giringe ka giluor ahinya.
Nígbà tí àwọn Israẹli rí ọkùnrin náà, gbogbo wọn sì sá fún un ní ìbẹ̀rù bojo.
25 Koro noyudo ka jo-Israel osebedo kawacho niya, “Donge uneno kaka ngʼatni osiko wuok? Owuok, mana mar jaro, Israel. Ruoth biro chiwo mwandu mathoth ne ngʼat monege. Bende obiro miye nyare mondo okendi, joodgi bende ok nogol osuru e Israel.”
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli wí pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò rí i bí ọkùnrin yìí ṣe ń jáde wá? Ó jáde wá láti pe Israẹli níjà. Ọba yóò fún ọkùnrin tí ó bá pa á ní ọrọ̀ púpọ̀. Yóò tún fi ọmọ rẹ̀ obìnrin fún un ní ìyàwó, yóò sì sọ ilé e baba rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú sísan owó orí ní Israẹli.”
26 Daudi nopenjo joma nochungʼ machiegni kode niya, “Ibiro tim angʼo ne ngʼat monego ja-Filistiani magol wichkuodni e Israel? Ja-Filistia ma ok oter nyangu to en ngʼa manyalo jaro jolweny mag Nyasaye mangima?”
Dafidi béèrè lọ́wọ́ ọkùnrin tí ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Kí ni a yóò ṣe fún ọkùnrin náà tí ó bá pa Filistini yìí, tí ó sì mú ẹ̀gàn kúrò lára Israẹli? Ta ni aláìkọlà Filistini tí ó jẹ́ wí pé yóò máa gan ogun Ọlọ́run alààyè?”
27 Neginwoyone weche mane oyudo giwacho mi giwachone niya, “Ma e gima ibiro timo ne ngʼat manonege.”
Wọ́n tún sọ fún un ohun tí wọ́n ti ń sọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí wọn yóò ṣe fún ọkùnrin tí ó bá pa á.”
28 Kane Eliab mowadgi Daudi maduongʼ, owinje ka owuoyo gi ji, mirima nomake kode mopenje niya, “Ibiro ka nangʼo? To rombe manok ka to iweyo gi ngʼa e thim? Angʼeyo ni in jangʼayi bende pachi richo, isebiro mana ni mondo ine kaka lweny dhi.”
Nígbà tí Eliabu ẹ̀gbọ́n Dafidi gbọ́ nígbà tí ó ń bá ọkùnrin yìí sọ̀rọ̀, ó bínú sí i, ó sì wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi sọ̀kalẹ̀ wá síbí? Àti pé ta ni ìwọ fi àwọn àgùntàn kékeré tókù ṣọ́ ní aginjù? Èmi mọ ìgbéraga rẹ, àti búburú ọkàn rẹ: ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá nìkan láti wòran ogun.”
29 Daudi nowacho niya, “Koro sani to atimo angʼo? Ok anyal kata wuoyoe?”
Dafidi wí pé, “Kí ni mo ṣe nísinsin yìí? Ǹjẹ́ mo lè sọ̀rọ̀ bí?”
30 Eka nolokore mochako wuoyo gi ngʼama chielo konono mana wachno kendo ji nodwoke mana wach machalre gi manosewinjo.
Ó sì yípadà sí ẹlòmíràn, ó sì ń sọ̀rọ̀ kan náà, ọkùnrin náà sì dáhùn bí ti ẹni ìṣáájú.
31 Gima Daudi nowacho nolandore mochopo ne Saulo eka Saulo noluonge.
Àwọn ènìyàn gbọ́ ohun tí Dafidi sọ wọ́n sọ fún Saulu, Saulu sì ránṣẹ́ sí i.
32 Daudi nowachone Saulo niya, “Kik chuny ji nyosre nikech ja-Filistiani; jatichni biro dhi mondo oked kode.”
Dafidi sọ fún Saulu pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí Filistini yìí, ìránṣẹ́ rẹ yóò lọ láti bá a jà.”
33 Saulo nodwoko niya, “In ok inyal dhi kedo gi ja-Filistia nikech in mana rawera, to en to osebedo kokedo chakre tin-ne.”
Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò tó láti jáde lọ pàdé ogun Filistini yìí àti láti bá a jà; ọmọdé ni ìwọ, òun sì ti ń jagun láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.”
34 To Daudi nowacho ni Saulo niya, “Jatichni osebedo kakwayo romb wuon-gi. Ka sibuor kata ondiek omako achiel kuom rombwa,
Ṣùgbọ́n Dafidi sọ fún Saulu pé, “Ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ti ń tọ́jú agbo àgùntàn baba rẹ̀. Nígbà tí kìnnìún tàbí àmọ̀tẹ́kùn bá wá láti wá gbé àgùntàn láti inú igbó.
35 to ne alawe kendo agoye mi amaye rombo kagolo e dhoge. Kane ochikore ira, ne amake gi yie dende mi agoye kendo anege.
Mo sá tẹ̀lé e, mo lù ú, mo sì gba àgùntàn náà kúrò lẹ́nu rẹ̀. Nígbà tí ó kọjú sí mi, mo fi irun rẹ̀ gbá a mú, mo sì lù ú mo sì pa á.
36 Jatichni osenego sibuor gi ondiek; ja-Filistia ma ok oter nyanguni, biro bedo achiel kuomgi nikech osejaro jolwenj Nyasaye mangima.
Ìránṣẹ́ rẹ ti pa kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn, aláìkọlà Filistini yìí yóò jẹ́ ọ̀kan lára wọn, nítorí ó ti pe ogun Ọlọ́run alààyè ní ìjà.
37 Jehova Nyasaye mane oresa e kok sibuor gi kok ondiek biro resa e lwet ja-Filistiani.” Saulo nowachone Daudi niya, “Dhi kendo Jehova Nyasaye obed kodi.”
Olúwa tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìhàlẹ̀ kìnnìún àti ti ìhàlẹ̀ àmọ̀tẹ́kùn yóò gbà mí kúrò lọ́wọ́ Filistini yìí.” Saulu wí fún Dafidi pé, “Lọ kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
38 Eka Saulo norwako Daudi gi lawe owuon. Norwakone koti mar lweny kendo nosidhone ogudu mar mula e wiye.
Saulu fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ wọ Dafidi, ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ìhámọ́ra ogun, ó sì fi ìbòrí idẹ kan bò ó ní orí.
39 Daudi notweyo liganglane ewi law mi notemo wuothogo nikech ne ok ongʼiyo gi gigo. Nowachone Saulo niya, “Ok anyal dhi gi gigi nikech ok angʼiyo kodgi.” Omiyo nogonyogi oko.
Dafidi si di idà rẹ̀ mọ́ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rìn káàkiri nítorí wí pé kò mọ́ ọ lára. Ó sọ fún Saulu pé, “Èmi kò le wọ èyí lọ, kò mọ́ mi lára.” Ó sì bọ́ wọn kúrò.
40 Eka nokawo ludhe mi oyiero kite mapoth abich ei aora kendo noketogi e ofukune mar kwath mi otingʼo orujre e lwete kendo osudo machiegni gi ja-Filistiano.
Nígbà náà, ó sì mú ọ̀pá rẹ̀ lọ́wọ́, ó ṣá òkúta dídán márùn-ún létí odò, ó kó wọn sí àpò olùṣọ́-àgùntàn tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kànnàkànnà, ó sì súnmọ́ Filistini náà.
41 E kindeno, ja-Filistiano gi jatingʼ kuode, ne sudo machiegni gi Daudi.
Lákòókò yìí, Filistini pẹ̀lú ẹni tí ń gbé ìhámọ́ra ààbò wà níwájú rẹ̀, ó ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ Dafidi.
42 Eka norango Daudi konone moneno ni en mana rawera ma silwal, ma jaber, mine obuone.
Nígbà tí Filistini náà sì wo Dafidi láti òkè délẹ̀, ó sì rí i wí pé ọmọ kékeré kùnrin ni, ó pọ́n ó sì lẹ́wà lójú, ó sì kẹ́gàn an rẹ̀.
43 Nowachone Daudi niya, “An guok mibirona kitongʼona kete?” Ja-Filistia nokwongʼo Daudi gi nying nyisechene.
Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ṣé ajá ni mí ni? Tí o fi tọ̀ mí wá pẹ̀lú ọ̀pá?” Filistini sì fi Dafidi bú pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
44 Nowachone niya, “Bi ka abiro miyo winy ma e kor yamo ringi gi le man e thim.”
Filistini náà sì wí Dafidi pé, “Wá níbí, èmi yóò fi ẹran-ara rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ àti fún àwọn ẹranko tí ó wà nínú igbó!”
45 Daudi nowachone ja-Filistiano niya, “Ibirona gi ligangla kod tongʼ gi bidhi, anto abironi e nying Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach jolweny Israel ma iseyanyo.
Dafidi sì wí fún Filistini pé, “Ìwọ dojú ìjà kọ mí pẹ̀lú idà, ọ̀kọ̀ àti ọfà, ṣùgbọ́n èmi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ pẹ̀lú orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí ìwọ tí gàn.
46 Kawuononi Jehova Nyasaye biro keti e lweta, abiro goyi piny mi angʼad ngʼuti. Kawuono abiro miyo winy mae kor polo gi le man e thim ringre jolweny mag jo-Filistia, kendo piny mangima biro ngʼeyo ni nitie Nyasaye ei Israel.
Lónìí yìí ni Olúwa yóò fi ọ́ lé mi lọ́wọ́, èmi yóò sì pa ọ́, èmi yóò sì gé orí rẹ. Lónìí èmi yóò fi òkú ogun Filistini fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko igbó, gbogbo ayé yóò sì mọ̀ pé Ọlọ́run wà ní Israẹli.
47 Ji duto mochokore ka biro ngʼeyo ni Jehova Nyasaye ok res joge gi ligangla gi tongʼ nimar lweny en mar Jehova Nyasaye, kendo obiro chiwou uduto e lwetwa.”
Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ọ̀kọ̀ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
48 Kane ja-Filistiano osudo machiegni mondo oked kode, Daudi ne oringo mapiyo piyo kochiko kar kedo mondo orom kode.
Bí Filistini ṣe súnmọ́ iwájú láti pàdé e rẹ̀. Dafidi yára sáré sí òun náà láti pàdé e rẹ̀.
49 Nosoyo lwete ei mifukune mogolo kidi; eka noketo kidino e orujre mine odiro mogoyogo lend wangʼ ja-Filistiano. Kidi nodonjo e lend wangʼe mine opodho piny auma.
Dafidi ti ọwọ́ sí àpò rẹ̀, ó sì mú òkúta jáde wá ó sì fì í, ó sì jù ú sí ọ̀kọ́kán iwájú orí Filistini. Òkúta náà sì wọ̀ ọ́ níwájú orí, ó sì ṣubú ó sì dojúbolẹ̀ ní orí ilẹ̀.
50 Omiyo Daudi noloyo ja-Filistiano gi orujre kod kidi; ka oonge gi ligangla e lwete nogoyo ja-Filistiano piny monege.
Dafidi yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistini pẹ̀lú kànnàkànnà àti òkúta, láìsí idà ní ọwọ́ rẹ̀, ó lu Filistini, ó sì pa á.
51 Daudi noringo mochungʼ kuome. Nokawo ligangla ja-Filistia mowuodho e olalone kane osenege, nongʼado wiye gi ligangla. Kane jo-Filistia oneno ni thuon-gi osetho negilokore mi gichako ngʼwech.
Dafidi sì sáré ó sì dúró lórí rẹ̀. Ó sì mú idà Filistini, ó sì fà á yọ nínú àkọ̀ ọ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa á tan, ó sì gé orí rẹ̀ pẹ̀lú idà. Nígbà tí àwọn ará Filistini rí i wí pé akọni wọn ti kú, wọ́n yípadà wọ́n sì sálọ.
52 Eka jo-Israel gi jo-Juda nosudo machiegni negigiyo sigich lweny mi gilawo jo-Filistia nyaka gichopi kama idonjogo Gath nyaka rangeye mag Ekron. Ringre jogi motho nokeyore e yo madhi Sharaim nyaka Gath gi Ekron.
Nígbà náà, àwọn ọkùnrin Israẹli àti ti Juda súnmọ́ iwájú pẹ̀lú ariwo, wọ́n sì lépa àwọn ará Filistini dé ẹnu ibodè Gati àti títí dé ẹnu ibodè Ekroni. Àwọn tí ó kú wà káàkiri ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà Ṣaaraimu àti títí dé ọ̀nà Gati àti Ekroni.
53 Kane jo-Israel odwogo koa lawo jo-Filistia, ne giyako kargi mar bworo.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli sì padà láti máa lé àwọn ará Filistini, wọ́n sì ba ibùdó wọn jẹ́.
54 Daudi nokawo wi ja-Filistia mokelo Jerusalem, to gige lweny mag ja-Filistia notero e hembe owuon.
Dafidi gé orí Filistini ó sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn ohun ìjà Filistini sínú àgọ́ tirẹ̀.
55 Kane Saulo orango Daudi e sa mane odhi rado gi ja-Filistia, nopenjo Abner mane jatend jolweny niya, “Abner wuowini en wuod ngʼa?” Abner nodwoko niya “Yaye ruoth, akwongʼora e nyimi ni ok angʼeye.”
Bí Saulu sì ti wo Dafidi bí ó ṣe ń jáde lọ pàdé Filistini, ó wí fún Abneri, olórí àwọn ológun rẹ̀ pé, “Abneri, ọmọ ta ni ọmọdékùnrin yìí?” Abneri dáhùn pe, “Bí ọkàn rẹ̀ ti ń bẹ ní ààyè, ọba èmi kò mọ̀.”
56 Ruoth nowachone niya, “Non ane ni wuowini en wuod ngʼa?”
Ọba sì wí pé, “Wádìí ọmọ ẹni tí ọmọdékùnrin náà ń ṣe.”
57 Mapiyo piyo kane Daudi odwogo koa nego ja-Filistia, Abner nokawe motere e nyim Saulo, kapod Daudi otingʼo wi ja-Filistia.
Kété tí ó dé láti ibi tí ó ti lọ pa Filistini, Abneri sì mú u wá síwájú Saulu, orí Filistini sì wà ní ọwọ́ Dafidi.
58 Saulo nopenje niya, “Wuowi matin in wuod ngʼa?” Daudi nodwoko niya, “An wuod Jesse ma ja-Bethlehem ma jatichni.”
Saulu béèrè pé, “Ọmọdékùnrin, ọmọ ta ni ọ́?” Dafidi dáhùn pé, “Èmi ni ọmọ ìránṣẹ́ rẹ Jese ti Bẹtilẹhẹmu.”

< 1 Samuel 17 >