< 1 Ruodhi 22 >

1 Kuom higni adek ne onge lweny e kind Israel gi Aram
Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli.
2 To e higa mar adek Jehoshafat ruodh Juda nodhi neno ruodh Israel.
Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli.
3 Ruodh Israel nosenyiso jodonge niya, “Donge ungʼeyo ni Ramoth Gilead en marwa to onge gima watimo mondo wakawe kuom ruodh Aram?”
Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
4 Omiyo nopenjo Jehoshafat, “Ibiro dhi konya kedo gi jo-Ramoth Gilead?” Jehoshafat nodwoko ruodh Israel niya, “Wan joka ngʼato achiel, joga gin jogi, faresena gin fareseni.”
Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?” Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
5 To Jehoshafat bende nowachone ruodh Israel niya, “Mokwongo penj ane Jehova Nyasaye wachni.”
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
6 Omiyo ruodh Israel nochoko jonabi kanyakla maromo ji mia angʼwen, mopenjogi niya, “Bende anyalo dhi kedo gi jo-Ramoth Gilead, koso kik adhi?” Negidwoke niya “Dhiyo nikech Jehova Nyasaye nochiwe e lwet ruoth.”
Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irinwó ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
7 To Jehoshafat nopenjo niya, “Donge nitie janabi mar Jehova Nyasaye ka ma dwapenj wach?”
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
8 Ruodh Israel nodwoko Jehoshafat niya, “Pod nitie ngʼato achiel manyalo penjonwa Jehova Nyasaye wach, to ok adware nikech ok okor gimoro amora maber kuoma, to kinde duto mana gik maricho. Nyinge en Mikaya wuod Imla.” Jehoshafat nodwoko niya, “Ruoth ok onego iwach kamano.”
Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.” Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
9 Omiyo ruodh Israel noluongo achiel kuom jodonge mowachone niya, “Dhi piyo iom Mikaya wuod Imla.”
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
10 Ruodh Israel kod Jehoshafat ruodh Juda noyudo orwako lepgi mag ruoth ka moro ka moro kuomgi obet e kom duongʼne e kar dino cham mantie e dhoranga Samaria, kendo ne gin kod jonabi duto mane koro e nyimgi.
Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
11 Koro Zedekia wuod Kenana noloso tunge mag nyinyo kolando niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye owacho, ‘Gi chumbegi ibiro chwowo jo-Aram nyaka itiekgi chuth.’”
Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’”
12 Jonabi mamoko duto bende ne koro wach mana machal kamano. Negiwacho niya, “Monj jo-Ramoth Gilead kendo ilogi nikech Jehova Nyasaye enokete e lwet ruoth.”
Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “Nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
13 Jaote mane odhi luongo Mikaya nowachone niya “Jonabi duto osekoro wach achiel machalre, kagiwacho ni gima ber biro timore ni ruoth. In bende yie ikor wach maber kaka gisekorono.”
Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
14 To Mikaya nowacho niya, “Akwongʼora gi nying Jehova Nyasaye mangima ni, anyalo mana nyise gima Jehova Nyasaye owachona.”
Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
15 Kane Mikaya ochopo, ruoth nopenje niya, “Bende wanyalo dhi mondo waked gi jo-Ramoth Gilead, koso kik wadhi?” Nodwoke niya, “Ked kodgi kendo iyud loch nimar Jehova Nyasaye osechiwe e lwet ruoth.”
Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?” Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
16 Ruoth nowachone niya, “Nyaka karangʼo ma anaketi mondo ikwongʼrina gi nying Jehova Nyasaye ni iwacho adiera ma ok miriambo?”
Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
17 Eka Mikaya nodwoke niya, “Ne aneno jo-Israel duto koke ewi gode mana kaka rombe maonge jakwath, kendo Jehova Nyasaye nowacho ni, ‘Jogi onge gi ruoth. Yie iwe ngʼato ka ngʼato odhi e dalane gi kwe.’”
Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
18 Ruodh Israel nowachone Jehoshafat niya, “Donge nawachoni ni ok okorna gik mabeyo, to okoro mana gik maricho?”
Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
19 Mikaya nodhi nyime kawacho niya, “Kuom mano winj wach Jehova Nyasaye: Naneno Jehova Nyasaye kobet e kom duongʼne gi jopolo duto kochungʼ molwore, e bade korachwich kendo e bade koracham.
Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀.
20 Kendo Jehova Nyasaye nowacho ni, ‘En ngʼa mabiro hoyo Ahab mondo oked gi jo-Ramoth Gilead kendo onege kuno?’ “To ngʼato ka ngʼato nochiwo pache.
Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’ “Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn.
21 Mogik, roho marach nobiro mochungʼ e nyim Jehova Nyasaye mowacho ni, ‘Abiro hoye.’
Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
22 “Jehova Nyasaye nopenje niya, ‘Ere kaka ibiro hoye?’ “Nodwoke niya, ‘Abiro dhi mondo abed roho mar miriambo e dho jonabi mage duto.’ “Jehova Nyasaye nodwoke niya, ‘Dhiyo kendo itim kamano nikech in ema ibiro hoye mi iloye.’
“Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’ “Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’ “Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
23 “Omiyo koro sani Jehova Nyasaye oseketo roho mar miriambo e dho jonabigi duto. Jehova Nyasaye osengʼadoni buch masira.”
“Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
24 Eka Zedekia wuod Kenana noa malo mopamo lemb Mikaya. Nopenje niya, “En yo mane ma Roho mar Jehova Nyasaye noluwo kobiro wuoyo kodi?”
Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
25 Mikaya nodwoke niya, “Ibiro fwenyo chiengʼ ma iniring kidhi pondo e ot maiye.”
Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
26 Ruodh Israel nogolo chik niya, “Kawuru Mikaya kendo utere ir Amon jatend dala maduongʼ kendo ir Joash wuod ruoth,
Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba
27 kendo uwachne ni, ‘Gima ruoth wacho ema: Ket ngʼatni e od twech kendo kik imiye gimoro amora makmana makati kod pi nyaka aduogi kangima.’”
kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’”
28 Mikaya nowachone niya, “Kidwogo kingima, to kara ok asewuoyo gi dho Jehova Nyasaye.” Bangʼe nomedo wacho niya, “Winjuru wechena, un ji duto!”
Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
29 Omiyo ruodh Israel gi Jehoshafat ruodh Juda nodhi Ramoth Gilead.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi.
30 Ruodh Israel nowachone Jehoshafat niya, “Abiro rwako lewni moko ka wadhi e lweny mondo kik gifwenya, in to rwak arwaka lepi mag ruoth.” Omiyo ruodh Israel norwako lewni ma ok nyal fwenyego kendo nodhi e lweny.
Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
31 Ruodh jo-Aram nogolo chik ne jotende piero adek gariyo mariembo geche niya, “Kik uked gi ngʼato angʼata bed ni otin kata oduongʼ makmana ruodh Israel.”
Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.”
32 Kane jotelo mariembo geche lweny noneno Jehoshafat negiwacho e chunygi niya, “Adier ma en ruodh Israel.” Omiyo negilokore mondo giked kode, to kane Jehoshafat oywak,
Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè,
33 jotelo mariembo geche lweny noneno ni ok en ruodh Israel mi negiweyo lawe.
àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
34 To ngʼat moro noywayo atungʼ mare modiro asere ma nochwowo ruodh Israel e kind law lweny mane orwako. Ruoth nonyiso jariemb gache niya, “Lok garini mondo igola ka, nimar ahinyora marach.”
Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”
35 Odiechiengʼno duto lweny nomedo bedo mager kendo noten ruoth e gache komanyore gi jo-Aram. Remo mane chwer kawuok kama nohinyore nopongʼo i gari, kendo godhiambo notho.
Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.
36 Kane ochopo podho chiengʼ ywak nowinjore e kind jolweny niya, ngʼato ka ngʼato odog e gwengʼ-gi kendo ngʼato ka ngʼato odog e pinygi.
A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
37 Kamano ruoth notho kendo nokele Samaria moike kanyo.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria.
38 Ne gilwoko garino e yawo moro Samaria (kama ochode lwokoree), kendo guogi nonangʼo rembe, mana kaka wach Jehova Nyasaye nosewacho.
Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
39 Timbe mamoko mag loch Ahab kaachiel gi gik moko duto mane otimo, gi dala ruoth maduongʼ mane ogero mobawo gi lak liech kod mier mane ochielo gi ohinga, donge ondikgi e kitap rapar mar ruodhi Israel?
Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
40 Ahab noyweyo gi kwerene, kendo Ahazia wuode nokawo lochne kaka ruoth.
Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
41 Jehoshafat wuod Asa nodoko ruodh Juda e higa mar angʼwen mar Ahab ruodh Israel.
Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli.
42 Jehoshafat ne ja-higni piero adek gabich kane obedo ruoth kendo norito piny kodak Jerusalem kuom higni piero adek gabich. Min mare ne nyinge Azuba nyar Shilhi.
Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
43 E gik moko duto noluwo yore Asa wuon mare kendo ne ok oweyogi, nimar notimo gima kare e nyim Jehova Nyasaye. To kata kamano kuonde motingʼore gi malo mag lemo ne ok omuki kendo ji nodhi nyime mana gi chiwo misengini kendo wangʼo ubani.
Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
44 Jehoshafat bende ne nigi kwe gi ruodh Israel.
Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
45 Gik mamoko manotimore ndalo loch Jehoshafat gi gik mane otimo kaachiel gi humbe lwenjene, donge ondikgi e kitepe rapar mar ruodhi Juda?
Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
46 Noriembo jochode machwo mane ni kuonde motingʼore mag lemo mane otony e ndalo mag loch wuon-gi Asa.
Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
47 E kindeno ne onge ruoth e piny Edom, jalupne ema ne ni e loch.
Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
48 Koro Jehoshafat nohondho yiedhi mag ohala mondo odhi Ofir oom dhahabu to kata kamano ne ok gikwangʼ nikech ne gikethore kama iluongo ni Ezion Geber.
Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ, nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi.
49 E kindeno Ahazia wuod Ahab nowacho ni Jehoshafat niya, “Yie iwe joga okwangʼ gi jogi, to Jehoshafat nodagi.”
Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
50 Jehoshafat notho kaka kwerene kendo noyike but kwerene e dala maduongʼ mar Daudi wuon-gi. Kendo Jehoram wuode nobedo ruoth kare.
Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
51 Ahazia wuod Ahab nobedo ruodh Israel e Samaria e higa mar apar gabiriyo mar loch Jehoshafat ruodh Juda, kendo nobedo ruodh Israel higni ariyo.
Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtàdínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli.
52 Notimo richo e nyim Jehova Nyasaye nikech nowuotho e yore mag wuon-gi gi min-gi kendo e yore mag Jeroboam wuod Nebat mane omiyo Israel otimo richo.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀.
53 Notiyo ni Baal kendo nolame mi nomiyo Jehova Nyasaye, Nyasach Israel, obedo gi mirima mana kaka wuon-gi nosetimo.
Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.

< 1 Ruodhi 22 >