< 1 Ruodhi 20 >

1 Koro Ben-Hadad ruodh Aram nochoko jolwenje duto. Koriwore gi ruodhi piero adek gariyo man-gi farese kod geche nodhi molworo Samaria kendo omonje.
Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
2 Nooro joote ei dala ir Ahab ruodh Israel kawacho niya, “Ma e gima Ben-Hadad wacho:
Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
3 ‘Fedha magi gi dhahabu magi gin maga kendo mondi mabeyo kod nyithindi gin maga.’”
‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
4 To ruodh Israel nodwoke niya, “Mana kaka iwacho ruodha jaloch, An kaachiel gi mwanduna duto wan magi.”
Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
5 Jootego noduogo kendo mowacho niya, “Ma e gima Ben-Hadad owacho: ‘Naoro mondo akaw dhahabu magi kod fedha magi kaachiel gi mondi gi nyithindi.
Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
6 To kiny kar sa maka ma, abiro oro jodonga mondo omany odi mar ruoth kaachiel gi ut jodongi. Gibiro kawo gimoro amora mikwano kaka gima berni.’”
Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
7 Ruodh Israel noluongo jodongo duto mag piny mowachonegi niya, “Neuru kaka ngʼatni dwaro chandruok! Kane odwaro dhahabu maga gi fedha maga kaachiel gi monda gi nyithinda ne ok atame.”
Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
8 Jodongo kaachiel gi ji duto nodwoke kawacho niya, “Kik iwinje kata yie kik iyie gik modwaro.”
Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
9 Kamano nodwoko joote mag Ben-Hadad niya, “Nyis ruodha ma jaloch kama, ‘Jatichni biro timo duto mane idwaro mokwongo, to dwaronini ok anyal.’” Negia gitero ni Ben-Hadad dwoko.
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
10 Eka Ben-Hadad nochako ooro ote machielo ni Ahab kowachone niya, “Mad nyiseche timna kata bedi ni en malit machalo nade, ka ok otieko Samaria pep molokore buru.”
Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
11 Ruodh Israel nodwoke niya, “Nyise kama: ‘Ngʼat morwako lepe mag lweny ok onego go siboi ka ngʼat molonyo lepe mag lweny.’”
Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
12 Ben-Hadad nowinjo oteno ka en kaachiel gi ruodhi ne metho e hembegi mi nochiko joge niya, “Ikreuru mondo umonjgi.” Omiyo negiikore mondo gimonj dalano maduongʼ.
Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
13 To e kindeno janabi moro nobiro ir Ahab Ruodh Israel molando niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye wacho, ‘Donge ineno jolweny mangʼenygi? Abiro chiwe e lweti kawuono kendo ibiro ngʼeyo ni An e Jehova Nyasaye.’”
Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
14 To Ahab nopenjo niya, “To en ngʼatno mabiro timo mano?” To janabi nodwoke niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: ‘Rowere ma jolweny mag jotend lweny mar gwenge ema biro timo mani.’” Nopenjo niya, “En ngʼa mabiro chako lweny?” To janabi nodwoke niya, “In ema ibiro timo kamano.”
Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
15 Kamano Ahab nochiko rowere ma jotend lweny mag gwenge maromo ji mia ariyo gi piero adek gariyo. Eka nochoko jo-Israel mamoko maromo ji alufu abiriyo koriwore.
Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
16 Negichako wuoth odiechiengʼ tir ka Ben-Hadad kod ruodhi piero adek gariyo moriwore kode ne nitie e hema metho.
Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
17 Rowere ma jotend lweny mag gwenge nodhi mokwongo. Koro Ben-Hadad nooro jombetre mane odwogone wach kama, “Jomoko biro kowuok Samaria.”
Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
18 Nodwoko kama, “Ka gibiro gi kwe, makgiuru ka gingima; to ka gibiro ni lweny, to bende makgiuru ka gingima.”
Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
19 Rowere ma jotend lweny mag gwenge nowuok e dala ka jolweny luwo bangʼ-gi,
Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
20 kendo moro ma moro nonego jadhape. Gikanyono jo-Aram noringo ka jo-Israel lawogi. To Ben-Hadad ruodh jo-Aram notony koidho farase kod joidh faresene mamoko.
Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
21 Ruodh Israel nolawogi kendo nohinyo jo-farese kod jo-geche mi nonego jo-Aram mangʼeny.
Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
22 Bangʼe janabi nobiro ir ruodh Israel monyise niya, “Koro jiw jolweny magi mondo ine gima onego itim nimar ruodh Aram biro monji kendo e chwiri mabiro.”
Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
23 E kindego jodong ruoth nongʼado rieko ni ruodh Aram nongʼadone rieko kagiwachone niya, “nyisechegi gin nyiseche gode, mano emomiyo ne gin gi teko moloyowa; to ka wakedo kodgi e pewe to adier wabiro bedo matek maloyogi.
Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
24 To tim kama: Gol ruodhi duto e telo ni lweny kendo wilgi gi jotelo mamoko.
Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
25 Bende nyaka ichok jolweny marom gi mago mane wawito farese kar farese mane walalo kod geche kar geche mane walalo eka mondo waked gi Israel e pewe. Eka adier wanabed matek moloyogi.” Noyie kodgi motimo kaka owinjore.
Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
26 E chwiri maluwe Ben-Hadad nochoko jo-Aram modhi Afek mondo oked gi Israel.
Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
27 Kane jo-Israel bende nochoki momigi gige konyruok, ne giwuok mondo girom kodgi. Jo-Israel nogoyo kambi momanyore kodgi machalo gi kweth ariyo mag diek, ka jo-Aram to nokwako pewe.
Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
28 Ngʼat Nyasaye nobiro monyiso ruodh Israel niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye wacho, nikech jo-Aram paro ni Jehova Nyasaye en nyasach gode to ok nyasach holni, abiro chiwo jolweny mangʼenygi e lweti kendo ibiro ngʼeyo ni an Jehova Nyasaye.”
Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
29 Kuom ndalo abiriyo negigoyo kambi ka gimanyore, kendo e odiechiengʼ mar abiriyo lweny norado. Jo-Israel nonego jolwenj Aram ma jotelo maromo alufu mia achiel odiechiengno.
Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
30 Joma nodongʼ kuomgi notony modhi Afek kama ohinga nomukore monego ji alufu piero ariyo gabiriyo. To Ben-Hadad noringo modhi e dala maduongʼ mopondo ei ot maiye.
Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
31 Jodonge nowachone niya, “Ne, wasewinjo ni ruodhi mag jo-Israel ngʼwon. Yie wadhi ir ruodh Israel ka watweyo pien gugru e nungowa kendo ka watweyo tonde e wiwa. Dipo ka okechi.”
Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
32 Negidhi ir ruodh Israel ka girwako lep pien gugru e nungogi kendo gitweyo tonde wigi mi giwachone niya, “Jatichni Ben-Hadad wacho niya, Yie iweya abed mangima.” Eka ruoth nodwoko niya, “Pod ongima? En owadwa.”
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
33 Jogo nokaw wachno kaka ranyisi maber kendo negikawo wachno piyo piyo ma giwacho niya, “Ee, owadu Ben-Hadad!” Ruoth nowachonigi niya, “Dhiuru mondo uome.” Kane Ben-Hadad osewuok oko, Ahab noluongo mondo oidh gache.
Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
34 Ben-Hadad noyie mowachone niya, “Abiro dwoko mier mane wuonwa okawo kuom wuonu.” Inyalo keto chirni magu uwuon Damaski mana kaka wuonwa notimo Samaria. Ahab nodwoke niya, “Kuom winjruok ma wabiro timo abiro weyi mondo idhi.” Kuom mano notimo kode winjruok moweye odhi.
Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
35 Kuom wach Jehova Nyasaye achiel kuom yawuot jonabi nowacho ni wadgi niya, “Goya gi gir lwenji mitingʼo,” to ngʼatno notamore.
Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
36 Kamano janabi nowacho niya, “Nikech ok isewinjo dwond Jehova Nyasaye, mapiyo piyo kiwuok ka, to sibuor biro negi.” Kendo bangʼ ka ngʼatno nosea, sibuor noyude monege.
Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
37 Janabino noyudo ngʼat machielo mowachone niya, “Kiyie to goya.” Kamano ngʼatno nogoye mohinye.
Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
38 Eka janabino nodhi mochungʼ e bath yo korito ruoth. Noumo wangʼe gi kilemba mar wiye mondo kik fweny ni en ngʼa.
Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
39 Kane ruoth kadho kanyo janabi noluonge mowachone niya, “Jatichni nodhi e chuny lweny, kendo ngʼato nobiro ira gi misumba momaki mowachona ni, ‘Rit ngʼatni kolal to ngimani biro chulo ngimane kata ibiro chulo fedha maromo kilo piero adek gangʼwen.’
Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
40 Kane jatijno odich ka gi kacha ngʼatno nolal.” Ruodh Israel nodwoke niya, “Mano e bura mongʼadni nikech isewache iwuon.”
Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
41 Eka janabi nogolo kilemba mane ogengʼogo wangʼe mi ruodh jo-Israel nofwenye kaka achiel kuom jonabi.
Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
42 Nowacho ni ruoth niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye owacho: ‘Iseweyo ngʼat mane awacho ni nyaka tho odhi thuolo. Kuom mano inichul ngimane gi ngimani kendo jogi kuom joge.’”
Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
43 Ruodh Israel nodhi e ode mar ruoth Samaria ka chunye orumo kendo ka iye owangʼ kod mirima.
Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.

< 1 Ruodhi 20 >