< 1 Ruodhi 19 >

1 Koro Ahab nonyiso Jezebel mago duto mane Elija nosetimo kendo kaka nosenego jonabi gi ligangla,
Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
2 omiyo Jezebel nooro jaote ir Elija mondo owachne niya, “Mad nyiseche timna kata bedi ni en malit machalo nade ka kiny sa ma kama ok atimo ni ngimani machal gi achiel kuom jonabigo.”
Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
3 Elija ne luor kendo noringo nikech ngimane. Kane obiro Bersheba e Juda, noweyo jatichne kanyo,
Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
4 ka en to nodhi e wuodh ndalo achiel e thim. Nochopo e tiend yien ma wiye opedhore mobedo e tiende kendo nolamo ni mad otho. Nowacho niya, “Jehova Nyasaye, aseneno moroma, kaw ngimana, ok aber moloyo kwerena.”
nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
5 Eka nonindo e tiend yien ma nindo otere. Mapiyo piyo nono malaika nomule mowachone niya, “Chungʼ malo mondo ichiem.”
Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
6 Nongʼicho kendo noyudo makati matin maliet motedi gi makaa koketi but wiye kod pi e agulu. Nochiemo mometho eka bangʼe kendo nodok monindo.
Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
7 Malaika mar Jehova Nyasaye noduogo ire mar ariyo kendo nomule mowachone niya, “Chungi mondo ichiem nimar wuoth pod bor.”
Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
8 Kamano nochungʼ mi ochiemo kendo ometho. Kane osechiemo noyudo teko mowuotho ndalo piero angʼwen, odiechiengʼ gotieno nyaka Horeb, got mar Nyasaye.
Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
9 Kanyo nodonjo ei rogo monindo kanyo. Kendo wach Jehova Nyasaye nobirone mawachone niya, “En angʼo mitimo ka, Elija?”
Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
10 Nodwoko niya, “Asebedo katiyo matek ni Jehova Nyasaye Maratego. Jo-Israel osekwedo singruokni, gisemuko kende mag misengini kendo nego jonabigi gi ligangla. An kenda ema adongʼ kendo koro gidwaro nega.”
Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
11 Jehova Nyasaye nowacho niya, “Wuogi mondo idhi ichungi ewi got e nyim Jehova Nyasaye, nimar Jehova Nyasaye chiegni kadho.” Eka yamo maduongʼ makudho matek nobaro got mokeyo kite e nyim Jehova Nyasaye, to Jehova Nyasaye ne onge e yamono. Bangʼ yamono piny noyiengni, to Jehova Nyasaye ne onge e yiengni pinyno.
Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
12 Bangʼ yiengni pinyno mach nobiro, to Jehova Nyasaye ne onge ei majno. To bangʼ majno yamo makudho mos nobiro.
Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
13 Kane Elija owinje noumo wangʼe gi law abola mowuok oko kochungʼ e dho rogo. Eka dwol nowuoyo kode kawacho niya, “En angʼo mitimo ka Elija?”
Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
14 Nodwoko niya, “Asebedo katiyo matek ni Jehova Nyasaye Maratego. Jo-Israel osekwedo singruokni, gisemuko kende mag misengini kendo nego jonabigi gi ligangla. An kenda ema adongʼ kendo koro gidwaro nega.”
Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
15 Jehova Nyasaye nowachone niya, “Dog gi yo mane ibirogo kendo idhi e thim mar Damaski. Ka ichopo kuno, to wir Hazael mondo obed ruodh Aram.
Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
16 Bende wir Jehu wuod Nimshi obed ruodh Israel, kendo iwir Elisha wuod Shafat ma ja-Abel Mehola mondo okaw kari kaka janabi.
Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
17 Jehu biro nego ngʼato angʼata motony e ligangla mar Hazael kendo Elisha biro nego ngʼato angʼata motony e ligangla Jehu.
Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
18 To kata mana sani an gi jodolo alufu abiriyo e piny Israel duto mapok okulore ne Baal, kendo ma pod olame ka nyodhe.”
Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
19 Omiyo Elija nowuok kanyo modhi oyudo Elisha wuod shafat. Nopuro gi rwedhi motwe e jok apar gariyo kendo en owuon ema nochwado rwedhi machien. Elija nodhi machiegni kendo nobolo lawe mar abola kuome.
Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
20 Elisha noweyo rwethe mag pur moringo koluwo bangʼ Elija. Nowachone niya, “Yie iwe ago ne wuonwa kod minwa oriti bangʼe to abiro dhiyo kodi.” Elija nodwoke niya, “Dogi, en angʼo ma asetimo?”
Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
21 Omiyo Elisha noweye modok. Nokawo rwethe mag pur moyangʼogi. Nowangʼo gik mane opurogo mondo ochwakgo ringʼo mi nomiyo ji kendo gichamo. Eka nochako wuoth moluwo bangʼ Elija kendo nobedo jakonyne.
Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.

< 1 Ruodhi 19 >