< 1 Ruodhi 17 >

1 Koro Elija ja-Tishbi moa Tishbe e piny Gilead nonyiso Ahab niya, “Mana kaka Jehova Nyasaye mangima, ma Nyasach Israel matiyone nitie, tho kata koth ok nobedi kuom higni manok nyaka chop achak awach kendo.”
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 Eka wach Jehova Nyasaye nobiro ne Elija mowachone niya,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 “Aa ka, dhi yo wuok chiengʼ kendo ipondi e holo mar Kerith man yo wuok chiengʼ mar Jordan.
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 Ibiro modho pi mowuok e soko kendo asechiko winyo mag agak mondo omiyi chiemo kanyo.”
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 Kamano notimo gima Jehova Nyasaye nochike. Nodhi e holo mar Kerith yo ka wuok chiengʼ mar aora Jordan kendo nobedo kuno.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 Winyo mag agakgo nokelone kuon gi ringʼo okinyi godhiambo to nomodho e sokono.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Bangʼ kinde moko sokono notwo nikech koth ne pok ochuwe e piny.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 Eka wach Jehova Nyasaye nobirone mowachone niya,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 “Dhiyo piyo piyo nyaka Zarefath e piny Sidon kendo ibed kanyo. Asechiko dhako ma chwore otho moro kanyo mondo omiyi chiemo.”
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 Kamano nodhi Zarefath. Kane ochopo e dhoranga dalano, dhako ma chwore otho moro ne ni kanyo ka choko yien. Noluonge mopenje niya, “Bende inyalo kelonae pi matin e agwata agulu mondo amodhi?”
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 Kane odhi kelo pi, Elija noluonge mowachone niya, “Kendo kiyie, to kelna kuon matin.”
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 Eka nodwoko Elija niya, “Mana kaka Jehova Nyasaye ma Nyasachi ngima aonge gi kuon moro amora makmana mogo matin e agulu kod mo matin e puga. Amodo yien matin mondo ater dala kendo alosgo chiemba kod mar wuoda mondo wacham bangʼe watho.”
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Elija nowachone niya, “Kik ibed maluor dhi dala kendo tim kaka isewacho. To mokwongo losna kuon matin kuom gima in-go mondo ikelna eka ilos gimoro ni in kaachiel gi wuodi
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Nimar ma e gima Jehova Nyasaye Nyasach Israel wacho, ‘Agulu mar mogo ok nodongʼ nono kendo puga mar mo ok notwo nyaka chop chiengʼ ma Jehova Nyasaye nokelie koth, e piny.’”
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 Nodhi motimo kaka Elija nowachone. Kamano ne nitie chiemo pile ka pile ne Elija gi dhakono kod joode.
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Nimar agulu mar mogono ne ok odongʼ nono kendo puga mar mo-no ne ok otwo kaluwore gi wach Jehova Nyasaye mane Elija owacho.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 Bangʼ kinde moko wuod dhakoni ma wuon odno ne tuo, nomedo bedo marach ahinya to bangʼe notho.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Dhakono nopenjo Elija niya, “En rach mane ma in-go koda, ngʼat Nyasaye? Ne ibiro mondo iparna richona kendo mondo ineg wuoda?”
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 Elija nodwoke niya, “Miya wuodi.” Nokawe koa e lwete motingʼe nyaka ei ot mamalo mane odakie mopiele e kitandane.
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 Eka noywak ne Jehova Nyasaye niya, “Yaye Jehova Nyasaye ma Nyasacha isekelo chandruok bende ni dhako ma chwore otho madakgo ni kimiyo wuode tho?”
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 Eka noriere kuom wuowino nyadidek moywak ni Jehova Nyasaye niya, “Jehova Nyasaye ma Nyasacha yie ngima wuowini oduogne!”
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 Jehova Nyasaye nowinjo ywak Elija mi ngima wuowino noduogone mi nobedo mangima.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Elija nochungo nyathino motingʼe kogole oko ewi tado motere e ot. Nomiye min-gi mowachone niya ne wuodi ngima!
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 Eka dhakono nowacho ni Elija niya, “Koro angʼeyo adiera ni in ngʼat Nyasaye kendo ni wach Jehova Nyasaye mawuok e dhogi en adiera.”
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”

< 1 Ruodhi 17 >