< 1 Ruodhi 15 >

1 E higa mar apar gaboro mar loch Jeroboam wuod Nebat, Abija nobedo ruodh Juda,
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu ọmọ Nebati, Abijah jẹ ọba lórí Juda,
2 kendo norito piny kuom higni adek kodak Jerusalem. Min mare ne nyinge Maaka nyar Abishalom.
ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́ta ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
3 Notimo richo duto mane wuon otimo kendo chunye ne ok ochiwore chuth ni Jehova Nyasaye ma Nyasache, kaka chuny Daudi kwargi ne en.
Ó sì rìn nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí baba rẹ̀ ti dá ṣáájú rẹ̀; ọkàn rẹ̀ kò sì pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
4 To kata kamano nikech Daudi, Jehova Nyasaye ma Nyasache nomiye taya Jerusalem koyiero wuode mondo okaw lochne kendo oket Jerusalem obed motegno.
Ṣùgbọ́n, nítorí i Dafidi Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fún un ní ìmọ́lẹ̀ kan ní Jerusalẹmu nípa gbígbé ọmọ rẹ̀ ró láti jẹ ọba ní ipò rẹ̀ àti láti fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀.
5 Nikech Daudi notimo gima kare e nyim Jehova Nyasaye kendo ne ok oweyo ma ok omako chik Jehova Nyasaye moro amora e ndalo ngimane duto makmana e wach Uria ja-Hiti.
Nítorí tí Dafidi ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pàṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Uriah ará Hiti.
6 Lweny ne nitie e kind Rehoboam gi Jeroboam e kinde duto mar ngima Abija.
Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní gbogbo ọjọ́ ayé Abijah.
7 To timbe mamoko mag loch Abija kaachiel gi gik moko duto mane otimo, donge ondikgi e kitepe mag weche mag ndalo mar ruodhi mag Juda? Ne nitie lweny e kind Abija kod Jeroboam.
Ní ti ìyókù ìṣe Abijah, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ogun sì wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
8 Kendo Abija notho kaka kwerene kendo noyike e Dala Maduongʼ mar Daudi. Asa wuode nobedo ruoth kare.
Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
9 E higa mar piero ariyo mar loch Jeroboam ruodh Israel, Asa nobedo ruodh Juda,
Ní ogún ọdún Jeroboamu ọba Israẹli, Asa jẹ ọba lórí Juda,
10 kendo nobedo ruoth Jerusalem kuom higni piero angʼwen gachiel. Dagi niluongo ni Maaka nyar Abishalom.
Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ńlá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
11 Asa notimo gima kare e nyim Jehova Nyasaye mana kaka Daudi wuon mare notimo.
Asa sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
12 Noriembo chwo ma jochode mag kuonde lemo modarogi e pinye kendo noketho nyiseche manono mane kweregi oloso.
Ó sì mú àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà kúrò ní ilẹ̀ náà, ó sì kó gbogbo ère tí àwọn baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
13 Bende nogolo dagi ma Maaka e kome mane entie kaka min ruoth nikech noloso sirni milamo mar Ashera. Asa nongʼado yien-no mowangʼe e holo mar Kidron.
Ó sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
14 Kata obedo ni Asa ne ok oketho kuonde motingʼore malo mag lemo, chunye nochiwore chutho ni Jehova Nyasaye ndalo duto mag ngimane.
Ṣùgbọ́n kò mú àwọn ibi gíga kúrò, síbẹ̀ ọkàn Asa pé pẹ̀lú Olúwa ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo.
15 Nokelo gige dhahabu gi fedha kod mula e hekalu mar Jehova Nyasaye ma en owuon gi wuon mare nosepwodho.
Ó sì mú wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò tí òun àti baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wọ ilé Olúwa.
16 Ne nitie lweny e kind Asa kod Baasha ruodh Israel ndalo duto mag lochgi.
Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn.
17 Baasha ruodh Israel nodhi kedo kod Juda kendo nochielo Rama motegno mondo ogengʼ ni ngʼato angʼata kik wuogi kata donji e piny Asa ruodh Juda.
Baaṣa, ọba Israẹli sì gòkè lọ sí Juda, ó sì kọ́ Rama láti má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba lọ.
18 Eka Asa nokawo fedha gi dhahabu duto mane odongʼ e ute keno mag hekalu mar Jehova Nyasaye gi mago mag ode. Nomiyogi jodonge mi oorogi ir Ben-Hadad wuod Tabrimon ma wuod Hezion ruodh Aram manodak Damaski.
Nígbà náà ni Asa mú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ó kù nínú ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ilé ọba. Ó sì fi lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Beni-Hadadi ọmọ Tabrimoni, ọmọ Hesioni ọba Siria tí ó ń gbé ní Damasku.
19 Nowachone niya, “Winjruok mondo obedie kindi koda, mana kaka nobedo e kind wuonwa gi wuonu. Aoroni mich mag fedha gi dhahabu, koro keth winjruok mantie e kindi gi Baasha ruodh Israel mondo mi owe kedo koda.”
Ó sì wí pé, “Jẹ́ kí májẹ̀mú kí ó wà láàrín èmi àti ìwọ, bí ó sì ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Wò ó, Èmi rán ọrẹ fàdákà àti wúrà sí ọ. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, da májẹ̀mú rẹ pẹ̀lú Baaṣa, ọba Israẹli, kí ó lè lọ kúrò lọ́dọ̀ mi.”
20 Ben-Hadad noyie gi ruoth Asa kendo nooro jotende mag lweny mondo omonj mier matindo mag Israel. Noloyo Ijon gi Dan gi Abel Beth Maaka kod Kinereth duto kaachiel gi Naftali.
Beni-Hadadi gba ti Asa ọba, ó sì rán àwọn alágbára olórí ogun rẹ̀ sí àwọn ìlú Israẹli. Ó sì ṣẹ́gun Ijoni, Dani àti Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo Kinnereti pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali.
21 Kane Baasha owinjo mano, nochungo gero Rama modok Tirza.
Nígbà tí Baaṣa sì gbọ́ èyí, ó sì ṣíwọ́ kíkọ́ Rama, ó sì lọ kúrò sí Tirsa.
22 Eka ruoth Asa nochiwo chik ni Juda duto maonge ngʼato angʼata mane owe oko, negikawo kite duto kod yiende mane Baasha osebedo katiyogo Rama kendo notiyo kodgi kanyo. Asa notiyo kodgi kuom gero Geba e piny Benjamin kod Mizpa bende.
Nígbà náà ni Asa ọba kéde ká gbogbo Juda, kò dá ẹnìkan sí, wọ́n sì kó òkúta Rama kúrò àti igi rẹ̀, tí Baaṣa fi kọ́lé. Asa ọba sì fi wọ́n kọ́ Geba ti Benjamini àti Mispa.
23 Weche mamoko duto mag loch Asa, gi lochne, gi gigo duto mane otimo gi mier duto mane ogero donge ondikgi e kitepe mag ruodhi mag Juda? Kata kamano ka hike noseniangʼ tiende nobedo gituo.
Ní ti ìyókù gbogbo ìṣe Asa, àti gbogbo agbára rẹ̀, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti àwọn ìlú tí ó kọ́, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ṣùgbọ́n, ní ìgbà ogbó rẹ̀, ààrùn ṣe é ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
24 Eka Asa noyweyo gi kwerene kendo noyike kodgi e dala Daudi wuon mare. Kendo Jehoshafat wuode nobedo ruoth kare.
Asa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
25 Nadab wuod Jeroboam nobedo ruoth mar Israel e higa mar ariyo mar loch Asa ruodh Juda, kendo nobedo ruodh Israel kuom higni ariyo.
Nadabu ọmọ Jeroboamu sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún kejì Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjì.
26 Notimo richo e nyim Jehova Nyasaye, kowuotho e yor wuon mare kod richone mane omiyo Israel otimo.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Israẹli dá.
27 Baasha wuod Ahija ja-dhood Isakar nomonje mi nogoye monege e Gibethon e dala jo-Filistia ka Nadab kod jo-Israel duto ne dwaro monjo dalano.
Baaṣa ọmọ Ahijah ti ilé Isakari sì dìtẹ̀ sí i, Baaṣa sì kọlù ú ní Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini, nígbà tí Nadabu àti gbogbo Israẹli dó ti Gibetoni.
28 Baasha nonego Nadab e higa mar adek mar loch Asa ruodh Juda, kendo nokaw lochne kaka ruoth.
Baaṣa sì pa Nadabu ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
29 Mapiyo piyo kochako locho, nonego jood Jeroboam duto. Ne ok oweyo ni Jeroboam kata ngʼato achiel mayweyo to notiekogi kaluwore gi wach Jehova Nyasaye mane omiyo jatichne Ahija ja-Shilo;
Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ó pa gbogbo ilé Jeroboamu, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jeroboamu, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
30 nikech richo mane Jeroboam otimo kendo mane omiyo Israel otimo, kendo nikech nomiyo Jehova Nyasaye Nyasach Israel obedo gi mirima.
Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú.
31 To kuom mamoko mag loch Nadab kaachiel gi timbene duto donge ondiki e kitepe mag ruodhi mag Israel?
Ní ti ìyókù ìṣe Nadabu àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
32 Ne nitie lweny e kind Asa kod Baasha ruodh Israel ndalo duto mag lochgi.
Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ wọn.
33 E higa mar adek mar loch Asa ruodh Juda, Baasha wuod Ahija nodoko ruoth kuom Israel duto e Tirza kendo nobedo ruoth kuom higni piero ariyo gangʼwen.
Ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, Baaṣa ọmọ Ahijah sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli ní Tirsa, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́rìnlélógún.
34 Notimo richo e nyim Jehova Nyasaye, kowuotho e yore mag Jeroboam kod richone mane omiyo Israel otimo.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.

< 1 Ruodhi 15 >