< Salme 107 >
1 Halleluja! Lov Herren, thi han er god, thi hans Miskundhed varer evindelig!
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
2 Så skal HERRENs genløste sige, de, han løste af Fjendens Hånd
Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
3 og samlede ind fra Landene, fra Øst og Vest, fra Nord og fra Havet.
àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
4 I den øde Ørk for de vild, fandt ikke Vej til beboet By,
Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
5 de led både Sult og Tørst, deres Sjæl var ved at vansmægte;
Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
6 men de råbte til HERREN i Nøden, han frelste dem at deres Trængsler
Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
7 og førte dem ad rette Vej, så de kom til beboet By.
Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
8 Lad dem takke HERREN for hans Miskundhed, for hans Underværker mod Menneskens Børn.
Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
9 Thi han mættede den vansmægtende Sjæl og fyldte den sultne med godt.
nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
10 De sad i Mulm og Mørke, bundne i pine og Jern,
Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
11 fordi de havde stået Guds Ord imod og ringeagtet den Højestes Råd.
nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
12 Deres Hjerte var knuget af Kummer, de faldt, der var ingen, som hjalp;
Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
13 men de råbte til HERREN i Nøden, han frelste dem af deres Trængsler,
Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
14 førte dem ud af Mørket og Mulmet og sønderrev deres Bånd.
Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
15 Lad dem takke HERREN for hans Miskundhed, for hans Underværker mod Menneskens Børn.
Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
16 Thi han sprængte Døre af Kobber og sønderslog Slåer af Jern.
Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
17 De sygnede hen for Synd og led for Brødes Skyld,
Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
18 de væmmedes ved al Slags Mad, de kom Dødens Porte nær
Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
19 men de råbte til Herren i Nøden, han frelste dem af deres Trængsler,
Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
20 sendte sit Ord og lægede dem og frelste deres Liv fra Graven.
Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
21 Lad dem takke HERREN for hans Miskundhed, for hans Underværker mod Menneskens Børn
Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
22 og ofre Lovprisningsofre og med Jubel forkynnde hans Gerninger.
Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
23 De for ud på Havet i Skibe, drev Handel på vældige Vande,
Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
24 blev Vidne til HERRENs Gerninger, hans Underværker i Dybet;
Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
25 han bød, og et Stormvejr rejste sig, Bølgerne tårnedes op;
Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
26 mod Himlen steg de, i Dybet sank de, i Ulykken svandt deres Mod;
Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
27 de tumled og raved som drukne, borte var al deres Visdom;
Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
28 men de råbte til HERREN i Nøden, han frelste dem af deres Trængsler,
Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
29 skiftede Stormen til Stille, så Havets Bølger tav;
Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
30 og glade blev de, fordi det stilned; han førte dem til Havnen, de søgte.
Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
31 Lad dem takke HERREN for hans Miskundhed, for hans Underværker mod Menneskens Børn,
Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
32 ophøje ham i Folkets Forsamling og prise ham i de Ældstes Kreds!
Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
33 Floder gør han til Ørken og Kilder til øde Land,
Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
34 til Saltsteppe frugtbart Land for Ondskabens Skyld hos dem, som - bor der.
Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
35 Ørken gør han til Vanddrag, det tørre Land til Kilder;
O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
36 der lader han sultne bo, så de grunder en By at bo i,
níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
37 tilsår Marker og planter Vin og høster Afgrødens Frugt.
Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
38 Han velsigner dem, de bliver mange, han lader det ikke skorte på Kvæg.
Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
39 De bliver få og segner under Modgangs og Kummers Tryk,
Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
40 han udøser Hån over Fyrster og lader dem rave i vejløst Øde.
ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
41 Men han løfter den fattige op af hans Nød og gør deres Slægter som Hjorde;
Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
42 de oprigtige ser det og glædes, men al Ondskab lukker sin Mund.
Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
43 Hvo som er viis, han mærke sig det og lægge sig HERRENs Nåde på Sinde!
Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.