< 4 Mosebog 9 >
1 HERREN talede således til Moses i Sinaj Ørken i den første Måned af det andet År efter deres Udvandring fra Ægypten:
Olúwa sọ fún Mose nínú aginjù Sinai ní oṣù kìn-ín-ní ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wí pé,
2 Israeliterne skal fejre Påsken til den fastsatte Tid,
“Mú kí àwọn ọmọ Israẹli máa pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní àsìkò rẹ̀.
3 på den fjortende Dag i denne Måned ved Aftenstid skal I fejre den til den fastsatte Tid; overensstemmende med alle Anordningerne og Lovbudene om den skal I fejre den!
Ẹ ṣe é ní àsìkò rẹ̀ gan an ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí ní ìbámu pẹ̀lú àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀.”
4 Da sagde Moses til Israeliterne, at de skulde fejre Påsken;
Mose sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa pa àjọ ìrékọjá mọ́.
5 og de fejrede Påsken i Sinaj Ørken den fjortende Dag i den første Måned ved Aftenstid; nøjagtigt som HERREN havde pålagt Moses, således gjorde Israeliterne.
Wọ́n sì ṣe àjọ ìrékọjá ní aginjù Sinai ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní. Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo nǹkan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
6 Men der var nogle Mænd, som var blevet urene ved et Lig og derfor ikke kunde fejre Påske den Dag. Disse Mænd trådte nu den Dag frem for Moses og Aron
Àwọn díẹ̀ nínú wọn kò lè ṣe àjọ ìrékọjá lọ́jọ́ náà nítorí pé wọ́n di aláìmọ́ nítorí òkú ènìyàn. Nítorí èyí wọ́n wá sọ́dọ̀ Mose àti Aaroni lọ́jọ́ náà.
7 og sagde til ham: "Vi er blevet urene ved et Lig; hvorfor skal det da være os forment at frembære HERRENs Offergave til den fastsatte Tid sammen med de andre Israelitter?"
Wọ́n sọ fún Mose pé, “A di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ló dé tí a kò fi ní í le è fi ọrẹ wa fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ará Israẹli yòókù ní àsìkò tí a ti yàn.”
8 Moses svarede dem: "Vent, til jeg får at høre, hvad HERREN påbyder angående eder!"
Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ dúró kí n ba lè mọ ohun tí Olúwa yóò pàṣẹ nípa yín.”
9 Da talede HERREN til Moses og sagde:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
10 Tal til Israeliterne og sig: Når nogen af eder eller eders Efterkommere er blevet uren ved et Lig eller er ude på en lang Rejse, skal han alligevel holde Påske for HERREN;
“Sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘Bí ẹnìkan nínú yín tàbí nínú ìran yín bá di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn tàbí bí ó bá lọ sí ìrìnàjò síbẹ̀ yóò pa àjọ ìrékọjá Olúwa mọ́.
11 den fjortende Dag i den anden Måned ved Aftenstid skal de holde den; med usyret Brød og bitre Urter skal de spise Påskelammet.
Wọn yóò ṣe tiwọn ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì. Wọn yóò jẹ ẹran náà, pẹ̀lú àkàrà aláìwú àti ewúro.
12 De må intet levne deraf til næste Morgen, og de må ikke sønderbryde noget af dets Ben. De skal fejre Påsken i Overensstemmelse med alle de Anordninger, som gælder for den.
Wọn kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀, wọn kò sì gbọdọ̀ ṣẹ́ eegun rẹ̀. Wọ́n gbọdọ̀ tẹ̀lé gbogbo ìlànà fún ṣíṣe àjọ ìrékọjá.
13 Men den, som undlader at fejre Påsken, skønt han er ren og ikke på Rejse, det Menneske skal udryddes af sin Slægt, fordi han ikke har frembåret HERRENs Offergave til den fastsatte Tid. Den Mand skal undgælde for sin Synd.
Ṣùgbọ́n bí ẹnìkan tó wà ní mímọ́ tí kò sì lọ sí ìrìnàjò bá kọ̀ láti pa àjọ ìrékọjá mọ́, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí pé kò mú ọrẹ Olúwa wá ní àsìkò tí ó yẹ. Ẹni náà yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
14 Og når en fremmed, der bor hos eder, vil bolde Påske for HERREN, skal han holde den efter de Anordninger og Lovbud, som gælder for Påsken. En og samme Lov skal gælde for eder, for den fremmede og for den indfødte.
“‘Bí àlejò tí ń gbé láàrín yín bá fẹ́ ṣe àjọ ìrékọjá Olúwa, ó gbọdọ̀ pa á mọ́ ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà àti òfin rẹ̀. Ìlànà kan náà ni kí ẹ ní fún àlejò àti àwọn ọmọ bíbí ilẹ̀ yín.’”
15 Den Dag Boligen blev rejst, dækkede Skyen Boligen, Vidnesbyrdets Telt; men om Aftenen var der som et Ildskær over Boligen, og det holdt sig til om Morgenen.
Ní ọjọ́ tí wọ́n gbé àgọ́ ró, èyí tí í ṣe àgọ́ ẹ̀rí, dúró, ìkùùkuu àwọsánmọ̀ bò ó mọ́lẹ̀. Ìkùùkuu náà sì dàbí iná ní orí àgọ́ láti ìrọ̀lẹ́ títí di òwúrọ̀.
16 Således var det til Stadighed: Om dagen dækkede Skyen den, om Natten Ildskæret.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí nígbà gbogbo; ìkùùkuu bò ó, àti pé ní alẹ́ ìrísí rẹ̀ sì dàbí iná.
17 Hver Gang Skyen løftede sig fra Teltet, brød Israeliterne op, og der, hvor Skyen stod stille, slog Israeliterne Lejr.
Nígbàkígbà tí ìkùùkuu yìí bá ká sókè kúrò lórí àgọ́ ni àwọn ọmọ Israẹli yóò dìde láti máa lọ; ibikíbi tí ìkùùkuu náà bá dúró sí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò pa ibùdó wọn sí.
18 På HERRENs Bud brød Israeliterne op, og på HERRENs Bud gik de i Lejr, og så længe Skyen hvilede over Boligen, blev de liggende i Lejr;
Nípa àṣẹ Olúwa ni àwọn ọmọ Israẹli ń jáde lọ, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń pa ibùdó wọn. Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́, àwọn náà yóò dúró sí ibùdó.
19 når Skyen blev over Boligen i længere Tid, rettede Israeliterne sig efter, hvad HERREN havde foreskrevet dem, og brød ikke op.
Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́ fún ìgbà pípẹ́, síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa wọn kò sì ní gbéra láti lọ.
20 Det hændte, at Skyen kun blev nogle få Dage over Boligen; da gik de i Lejr på HERRENs Bud og brød op på HERRENs Bud.
Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè wà lórí àgọ́ fún ọjọ́ díẹ̀; síbẹ̀ ní àṣẹ Olúwa, wọn yóò dúró ní ibùdó, bí ó sì tún yá, ní àṣẹ rẹ̀ náà ni wọn yóò gbéra.
21 Og det hændte, at Skyen kun blev der fra Aften til Morgen; når Skyen da løftede sig om Morgenen, brød de op. Eller den blev der en Dag og en Nat; når Skyen da løftede sig, brød de op.
Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè dúró láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀, nígbà tó bá ṣí kúrò ní àárọ̀, wọn ó gbéra. Ìbá à ṣe ní ọ̀sán tàbí òru, ìgbàkígbà tí ìkùùkuu bá tó kúrò náà ni wọn ó tó gbéra.
22 Eller den blev der et Par Dage eller en Måned eller længere endnu, idet Skyen i længere Tid hvilede over Boligen; så blev Israeliterne liggende i Lejr og brød ikke op, men når den løftede sig, brød de op.
Ìbá à ṣe fún ọjọ́ méjì, oṣù kan tàbí ọdún kan ni ìkùùkuu fi dúró sórí àgọ́, àwọn ọmọ Israẹli yóò dúró ní ibùdó wọn, wọn kò ní gbéra; ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá lọ sókè ni wọn ó tó o gbéra.
23 På HERRENs Bud gik de i Lejr, og på HERRENs Bud brød de op; de rettede sig efter, hvad HERREN havde foreskrevet dem, efter HERRENs Bud ved Moses.
Nípa àṣẹ Olúwa ni wọ́n ń pa ibùdó wọn, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń gbéra. Wọ́n gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa ní ìbámu pẹ̀lú àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.