< Matthæus 5 >
1 Men da han så Skarerne, steg han op på Bjerget; og da han havde sat sig, gik hans Disciple hen til ham,
Nígbà tí ó rí ọ̀pọ̀ ènìyàn, ó gun orí òkè lọ ó sì jókòó. Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ si tọ̀ ọ́ wá.
2 og han oplod sin Mund, lærte dem og sagde:
Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ wọn. Ó wí pé,
3 "Salige ere de fattige i Ånden, thi Himmeriges Rige er deres.
“Alábùkún fún ni àwọn òtòṣì ní ẹ̀mí, nítorí tiwọn ni ìjọba ọ̀run.
4 Salige ere de, som sørge, thi de skulle husvales.
Alábùkún fún ni àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀, nítorí a ó tù wọ́n nínú.
5 Salige ere de sagtmodige, thi de skulle arve Jorden.
Alábùkún fún ni àwọn ọlọ́kàn tútù, nítorí wọn yóò jogún ayé.
6 Salige ere de, som hungre og tørste efter Retfærdigheden, thi de skulle mættes.
Alábùkún fún ni àwọn tí ebi ń pa tí òǹgbẹ ń gbẹ́ nítorí òdodo, nítorí wọn yóò yó.
7 Salige ere de barmhjertige, thi dem skal vises Barmhjertighed.
Alábùkún fún ni àwọn aláàánú, nítorí wọn yóò rí àánú gbà.
8 Salige ere de rene af Hjertet, thi de skulle se Gud.
Alábùkún fún ni àwọn ọlọ́kàn mímọ́, nítorí wọn yóò rí Ọlọ́run.
9 Salige ere de, som stifte Fred, thi de skulle kaldes Guds Børn.
Alábùkún fún ni àwọn onílàjà, nítorí ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè wọ́n.
10 Salige ere de, som ere forfulgte for Retfærdigheds Skyld, thi Himmeriges Rige er deres.
Alábùkún fún ni àwọn ẹni tí a ṣe inúnibíni sí, nítorí tí wọ́n jẹ́ olódodo nítorí tiwọn ní ìjọba ọ̀run.
11 Salige ere I, når man håner og forfølger eder og lyver eder alle Hånde ondt på for min Skyld.
“Alábùkún fún ni ẹ̀yin nígbà tí àwọn ènìyàn bá fi àbùkù kàn yín tí wọn bá ṣe inúnibíni sí yín, tiwọn fi ètè èké sọ̀rọ̀ búburú gbogbo sí yín nítorí mi.
12 Glæder og fryder eder, thi eders Løn skal være stor i Himlene; thi således have de forfulgt Profeterne, som vare før eder.
Ẹ yọ̀, kí ẹ̀yin sì fò fún ayọ̀, nítorí ńlá ni èrè yín ní ọ̀run, nítorí bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ṣe inúnibíni sí àwọn wòlíì tí ń bẹ ṣáájú yín.
13 I ere Jordens Salt; men dersom Saltet mister sin Kraft, hvormed skal det da saltes? Det duer ikke til andet end at kastes ud og nedtrædes af Menneskene.
“Ẹ̀yin ni iyọ̀ ayé. Ṣùgbọ́n bí iyọ̀ bá di òbu kí ni a ó fi mú un dùn? Kò tún wúlò fún ohunkóhun mọ́, bí kò ṣe pé kí a dàánù, kí ó sì di ohun tí ènìyàn ń fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
14 I ere Verdens Lys; en Stad, som ligger på et Bjerg, kan ikke skjules.
“Ẹyin ni ìmọ́lẹ̀ ayé. Ìlú tí a tẹ̀dó sórí òkè kò lè fi ara sin.
15 Man tænder heller ikke et Lys og sætter det under Skæppen, men på Lysestagen; så skinner det for alle dem, som ere i Huset.
Bẹ́ẹ̀ ni a kì í tan fìtílà tán, kí a sì gbé e sí abẹ́ òsùwọ̀n; bí kò ṣe sí orí ọ̀pá fìtílà, a sì tan ìmọ́lẹ̀ fún gbogbo ẹni tí ń bẹ nínú ilé.
16 Lader således eders Lys skinne for Menneskene, at de må se eders gode Gerninger og ære eders Fader, som er i Himlene.
Bákan náà, ẹ jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ yín kí ó mọ́lẹ̀ níwájú ènìyàn, kí wọ́n lè máa rí iṣẹ́ rere yín, kí wọn lè máa yin baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run lógo.
17 Mener ikke, at jeg er kommen for at nedbryde Loven eller Profeterne; jeg er ikke kommen for at nedbryde, men for at fuldkomme.
“Ẹ má ṣe rò pé, èmí wá láti pa òfin àwọn wòlíì run, èmi kò wá láti pa wọn rẹ́, bí kò ṣe láti mú wọn ṣẹ.
18 Thi sandelig, siger jeg eder, indtil Himmelen og Jorden forgår, skal end ikke det mindste Bogstav eller en Tøddel forgå af Loven, indtil det er sket alt sammen.
Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, títí ọ̀run òun ayé yóò fi kọjá, àmì kínkínní tí a fi gègé ṣe kan kì yóò parẹ́ kúrò nínú gbogbo òfin tó wà nínú ìwé òfin títí gbogbo rẹ̀ yóò fi wá sí ìmúṣẹ.
19 Derfor, den, som bryder et at de mindste af disse Bud og lærer Menneskene således, han skal kaldes den mindste i Himmeriges Rige; men den, som gør dem og lærer dem, han skal kaldes stor i Himmeriges Rige.
Ẹnikẹ́ni ti ó bá rú òfin tí ó tilẹ̀ kéré jùlọ, tí ó sì kọ́ ẹlòmíràn láti ṣe bẹ́ẹ̀, òun ni yóò kéré jùlọ ní ìjọba ọ̀run, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń ṣe wọ́n, tí ó sì ń kọ́ wọn, ni yóò jẹ́ ẹni ńlá ní ìjọba ọ̀run.
20 Thi jeg siger eder: Uden eders Retfærdighed overgår de skriftkloges og Farisæernes, komme I ingenlunde ind i Himmeriges Rige.
Nítorí náà ni mo ti wí fún yín pé àfi bí òdodo yín bá ju ti àwọn Farisi àti ti àwọn olùkọ́ òfin lọ, dájúdájú ẹ̀yin kì yóò le wọ ìjọba ọ̀run.
21 I have hørt, at der er sagt til de gamle: Du må ikke slå ihjel, men den, som slår ihjel, skal være skyldig for Dommen.
“Ẹ̀yin ti gbọ́ bí a ti wí fún àwọn ará ìgbàanì pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn, ẹnikẹ́ni tí ó bá pànìyàn yóò wà nínú ewu ìdájọ́.’
22 Men jeg siger eder, at hver den, som bliver vred på sin Broder uden Årsag, skal være skyldig for Dommen; og den, som siger til sin Broder: Raka! skal være skyldig for Rådet; og den, som siger: Du Dåre! skal være skyldig til Helvedes Ild. (Geenna )
Ṣùgbọ́n èmi wí fún un yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bínú sí arákùnrin rẹ̀ yóò wà nínú ewu ìdájọ́. Ẹnikẹ́ni ti ó ba wí fun arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ráákà,’ yóò fi ara hàn níwájú ìgbìmọ̀ àwọn àgbà Júù; ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá wí pé, ‘Ìwọ wèrè!’ yóò wà nínú ewu iná ọ̀run àpáàdì. (Geenna )
23 Derfor, når du ofrer din Gave på Alteret og der kommer i Hu, at din Broder har noget imod dig,
“Nítorí náà, nígbà tí ìwọ bá ń mú ẹ̀bùn rẹ wá síwájú pẹpẹ, bí ìwọ bá sì rántí níbẹ̀ pé arákùnrin rẹ̀ ni ohùn kan nínú sí ọ.
24 så lad din Gave blive der foran Alteret, og gå hen, forlig dig først med din Broder, og kom da og offer din Gave!
Fi ẹ̀bùn rẹ sílẹ̀ níwájú pẹpẹ. Ìwọ kọ́kọ́ lọ ṣe ìlàjà láàrín ìwọ àti arákùnrin rẹ̀ na. Lẹ́yìn náà, wá kí ó sì fi ẹ̀bùn rẹ sílẹ̀.
25 Vær velvillig mod din Modpart uden Tøven, medens du er med ham på Vejen, for at Modparten ikke skal overgive dig til Dommeren, og Dommeren til Tjeneren, og du skal kastes i Fængsel.
“Bá ọ̀tá rẹ làjà kánkán, ẹni tí ó ń gbé ọ lọ sílé ẹjọ́. Ṣe é nígbà ti ó wà ní ọ̀nà pẹ̀lú rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò fà ọ́ lé onídàájọ́ lọ́wọ́, onídàájọ́ yóò sí fá ọ lé àwọn ẹ̀ṣọ́ lọ́wọ́, wọ́n a sì sọ ọ́ sínú túbú.
26 Sandelig, siger jeg dig, du skal ingenlunde komme ud derfra, førend du får betalt den sidste Hvid.
Lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, ìwọ kì yóò jáde kúrò níbẹ̀ títí tí ìwọ yóò fi san ẹyọ owó kan tí ó kù.
27 I have hørt, at der er sagt: Du må ikke bedrive Hor.
“Ẹ̀yin ti gbọ́ bí òfin ti wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.’
28 Men jeg siger eder, at hver den, som ser på en Kvinde for at begære hende, har allerede bedrevet Hor med hende i sit Hjerte.
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá wo obìnrin kan ní ìwòkuwò, ti bà ṣe panṣágà nínú ọkàn rẹ̀.
29 Men dersom dit højre Øje forarger dig, så riv det ud, og kast det fra dig; thi det er bedre for dig, at eet af dine Lemmer fordærves, end at hele dit Legeme bliver kastet i Helvede. (Geenna )
Bí ojú ọ̀tún rẹ bá mú ọ kọsẹ̀, yọ ọ́ jáde, kí ó sì sọ ọ́ nù. Ó sá à ní èrè fún ọ kí ẹ̀yà ara rẹ kan ṣègbé, ju kí a gbé gbogbo ara rẹ jù sí iná ọ̀run àpáàdì. (Geenna )
30 Og om din højre Hånd forarger dig, så hug den af og kast den fra dig; thi det er bedre for dig, at eet af dine Lemmer fordærves, end at hele dit Legeme kommer i Helvede. (Geenna )
Bí ọwọ́ ọ̀tún rẹ bá mú ọ kọsẹ̀, gé e kúrò, kí ó sì sọ ọ́ nù. Ó sá à ní èrè kí ẹ̀yà ara rẹ kan ṣègbé ju kí a gbé gbogbo ara rẹ jù sí iná ọ̀run àpáàdì. (Geenna )
31 Og der er sagt: Den, som skiller sig fra sin Hustru, skal give hende et Skilsmissebrev.
“A ti wí pẹ̀lú pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, jẹ́ kí ó fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ lé e lọ́wọ́.’
32 Men jeg siger eder, at enhver, som skiller sig fra sin Hustru, uden for Hors Skyld, gør, at hun bedriver Hor, og den, som tager en fraskilt Kvinde til Ægte, bedriver Hor.
Ṣùgbọ́n èmi sọ èyí fún yín pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, láìṣe pé nítorí àgbèrè, ó mú un ṣe àgbèrè, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbé ẹni tí a kọ̀ ní ìyàwó, ó ṣe panṣágà.
33 I have fremdeles hørt, at der er sagt til de gamle: Du må ikke gøre nogen falsk Ed, men du skal holde Herren dine Eder.
“Ẹ̀yin ti gbọ́ bí a ti wí fún àwọn ará ìgbàanì pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ búra èké bí kò ṣe pé kí ìwọ kí ó mú ìbúra rẹ̀ fún Olúwa ṣẹ.’
34 Men jeg siger eder, at I må aldeles ikke sværge, hverken ved Himmelen, thi den er Guds Trone,
Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín, ẹ má ṣe búra rárá: ìbá à ṣe fífi ọ̀run búra, nítorí ìtẹ́ Ọlọ́run ni.
35 ej heller ved Jorden, thi den er hans Fodskammel, ej heller ved Jerusalem, thi det er den store Konges Stad.
Tàbí fi ayé búra, nítorí àpótí ìtìsẹ̀ Ọlọ́run ni; tàbí Jerusalẹmu, nítorí olórí ìlú ọba ńlá ni.
36 Du må heller ikke sværge ved dit Hoved, thi du kan ikke gøre et eneste Hår hvidt eller sort.
Má ṣe fi orí rẹ búra, nítorí ìwọ kò lè sọ irun ẹyọ kan di funfun tàbí di dúdú.
37 Men eders Tale skal være ja, ja, nej, nej; hvad der er ud over dette, er af det onde.
Ẹ jẹ́ kí bẹ́ẹ̀ ni yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àti bẹ́ẹ̀ kọ́ yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ kọ́, ohunkóhun tí ó ba ju ìwọ̀nyí lọ, wá láti ọ̀dọ̀ ẹni ibi.
38 I have hørt, at der er sagt: Øje for Øje, og Tand for Tand.
“Ẹ̀yin tí gbọ́ bí òfin tí wí pé, ‘Ojú fún ojú àti eyín fún eyín.’
39 Men jeg siger eder, at I må ikke sætte eder imod det onde; men dersom nogen giver dig et Slag på din højre Kind, da vend ham også den anden til!
Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín pé, ẹ má ṣe tako ẹni ibi. Bí ẹnìkan bá gbá ọ lẹ́rẹ̀kẹ́ ọ̀tún, yí ẹ̀rẹ̀kẹ́ òsì sí olúwa rẹ̀ pẹ̀lú.
40 Og dersom nogen vil gå i Rette med dig og tage din Kjortel, lad ham da også få Kappen!
Bí ẹnìkan bá fẹ́ gbé ọ lọ sílé ẹjọ́, tí ó sì fẹ́ gba ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀, jọ̀wọ́ agbádá rẹ fún un pẹ̀lú.
41 Og dersom nogen tvinger dig til at gå een Mil, da gå to med ham!
Bí ẹni kan bá fẹ́ fi agbára mú ọ rìn ibùsọ̀ kan, bá a lọ ní ibùsọ̀ méjì.
42 Giv den, som beder dig, og vend dig ikke fra den, som vil låne af dig.
Fi fún ẹni tí ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ń fẹ́ wín lọ́wọ́ rẹ, má ṣe mú ojú kúrò.
43 I have hørt, at der er sagt: Du skal elske din Næste og hade din Fjende.
“Ẹ̀yin ti gbọ́ bí òfin ti wí pé, ‘Ìwọ fẹ́ ọmọnìkejì rẹ, kí ìwọ sì kórìíra ọ̀tá rẹ̀.’
44 Men jeg siger eder: Elsker eders Fjender, velsigner dem, som forbande eder, gører dem godt, som hade eder, og beder for dem, som krænke eder og forfølge eder,
Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín pé, ẹ fẹ́ràn àwọn ọ̀tá yín kí ẹ sì gbàdúrà fún àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí yín.
45 for at I må vorde eders Faders Børn, han, som er i Himlene; thi han lader sin Sol opgå over onde og gode og lader det regne over retfærdige og uretfærdige.
Kí ẹ̀yin lè jẹ́ ọmọ Baba yín ti ń bẹ ní ọ̀run. Ó mú kí oòrùn rẹ̀ ràn sára ènìyàn búburú àti ènìyàn rere, ó rọ̀jò fún àwọn olódodo àti fún àwọn aláìṣòdodo.
46 Thi dersom I elske dem, som elske eder, hvad Løn have I da? Gøre ikke også Tolderne det samme?
Bí ẹ̀yin bá fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn yín nìkan, èrè kí ni ẹ̀yin ní? Àwọn agbowó òde kò ha ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́?
47 Og dersom I hilse eders Brødre alene, hvad stort gøre I da? Gøre ikke også Hedningerne det samme?
Àti bí ó bá sì jẹ́ pé kìkì àwọn arákùnrin yín nìkan ni ẹ̀yin ń kí, kín ni ẹ̀yin ń ṣe ju àwọn mìíràn lọ? Àwọn kèfèrí kò ha ń ṣe bẹ́ẹ̀ bí?
48 Værer da I fuldkomne, ligesom eders himmelske Fader er fuldkommen.
Nítorí náà, ẹ jẹ́ pípé, gẹ́gẹ́ bí Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run ṣe jẹ́ pípé.