< Lukas 6 >
1 Men det skete på den næstførste Sabbat, at han vandrede igennem en Sædemark, og hans Disciple plukkede Aks og gned dem med Hænderne og spiste.
Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, Jesu ń kọjá láàrín oko ọkà; àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń ya ìpẹ́ ọkà, wọ́n sì ń jẹ ẹ́.
2 Men nogle af Farisæerne sagde: "Hvorfor gøre I, hvad det ikke er tilladt at gøre på Sabbaten?"
Àwọn kan nínú àwọn Farisi sì wí fún wọn pé, “Ki lo de tí ẹ̀yin fi ń ṣe èyí tí kò yẹ láti ṣe ní ọjọ́ ìsinmi?”
3 Og Jesus svarede og sagde til dem: "Have I da ikke læst, hvad David gjorde, da han blev hungrig, han og de, som vare med ham?
Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin kò kà nípa ohun tí Dafidi ṣe, nígbà tí ebi ń pa òun tìkára rẹ̀ àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀;
4 hvorledes han gik ind i Guds Hus og tog Skuebrødene og spiste og gav også dem, som vare med ham, skønt det ikke er nogen tilladt at spise dem uden Præsterne alene."
bi ó ti wọ ilé Ọlọ́run lọ, tí ó sì mú àkàrà ìfihàn tí ó sì jẹ ẹ́, tí ó sì fi fún àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú; tí kò yẹ fún un láti jẹ, bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà nìkan ṣoṣo?”
5 Og han sagde til dem: "Menneskesønnen er Herre også over Sabbaten."
Ó sì wí fún wọn pé, “Ọmọ Ènìyàn ni Olúwa Ọjọ́ Ìsinmi.”
6 Men det skete på en anden Sabbat, at han kom ind i Synagogen og lærte. Og der var der en Mand, hvis højre Hånd var vissen.
Ní ọjọ́ ìsinmi mìíràn, ó wọ inú Sinagọgu lọ, ó sì ń kọ́ni, ọkùnrin kan sì ń bẹ níbẹ̀ tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ rọ.
7 Men de skriftkloge og Farisæerne toge Vare på ham, om han vilde helbrede på Sabbaten, for at de kunde finde noget at anklage ham for.
Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi ń ṣọ́ ọ, bóyá yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi; kí wọn lè rí ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kàn án.
8 Men han vidste deres Tanker; og han sagde til Manden, som havde den visne Hånd: "Rejs dig og stå frem her i Midten!" Og han rejste sig og stod frem.
Ṣùgbọ́n ó mọ èrò inú wọn, ó sì wí fún ọkùnrin náà tí ọwọ́ rẹ̀ rọ pé, “Dìde, kí o sì dúró láàrín.” Ó sì dìde dúró.
9 Men Jesus sagde til dem: "Jeg spørger eder, om det er tilladt at gøre godt på Sabbaten eller at gøre ondt, at frelse Liv eller at ødelægge det?"
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Èmi bi yín léèrè, Ó ha tọ́ láti máa ṣe rere ni ọjọ́ ìsinmi, tàbí láti máa ṣe búburú? Láti gba ọkàn là, tàbí láti pa á run?”
10 Og han så omkring på dem alle og sagde til ham: "Ræk din Hånd ud!" Og han gjorde det; da blev hans Hånd sund igen som den anden.
Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká, ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀: ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ̀ sípò gẹ́gẹ́ bí èkejì.
11 Men de bleve fulde af Raseri og talte med hverandre om, hvad de skulde gøre ved Jesus.
Wọ́n sì kún fún ìbínú gbígbóná; wọ́n sì bá ara wọn rò ohun tí àwọn ìbá ṣe sí Jesu.
12 Men det skete i disse Dage, at han gik ud på et Bjerg for at bede; og han tilbragte Natten i Bøn til Gud.
Ni ọ̀kan nínú àwọn ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Jesu lọ sí orí òkè láti gbàdúrà, ó sì fi gbogbo òru náà gbàdúrà sí Ọlọ́run.
13 Og da det blev Dag, hidkaldte han sine Disciple og udvalgte tolv af dem, hvilke han også kaldte Apostle:
Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; nínú wọn ni ó sì yan méjìlá, tí ó sì sọ ní aposteli:
14 Simon, hvem han også kaldte Peter, og Andreas, hans Broder, og Jakob og Johannes og Filip og Bartholomæus
Simoni (ẹni tí a pè ní Peteru) àti Anderu arákùnrin rẹ̀, Jakọbu, Johanu, Filipi, Bartolomeu,
15 og Matthæus og Thomas, Jakob, Alfæus's Søn, og Simon, som kaldes Zelotes,
Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni tí a ń pè ní Sealoti,
16 Judas, Jakobs Søn, og Judas Iskariot, som blev Forræder.
Judea arákùnrin Jakọbu, àti Judasi Iskariotu tí ó di ọ̀dàlẹ̀.
17 Og han gik ned med dem og stod på et jævnt Sted, og der var en Skare af hans Disciple og en stor Mængde af Folket fra hele Judæa og Jerusalem og Kysten ved Tyrus og Sidon,
Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀, ó sì dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn, láti gbogbo Judea, àti Jerusalẹmu, àti agbègbè Tire àti Sidoni, tí wọ́n wá láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìmúláradá kúrò nínú ààrùn wọn;
18 som vare komne for at høre ham og helbredes for deres Sygdomme. Og de plagede bleve helbredte fra urene Ånder;
àti àwọn tí ara wọn kún fún ẹ̀mí àìmọ́ ni ó sì mú láradá.
19 og hele Skaren søgte at røre ved ham; thi en Kraft gik ud fra ham og helbredte alle.
Gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń fẹ́ láti fọwọ́ kàn án, nítorí tí àṣẹ ń jáde lára rẹ̀, ó sì mú gbogbo wọn láradá.
20 Og han opløftede sine Øjne på sine Disciple og sagde: "Salige ere I fattige, thi eders er Guds Rige.
Nígbà tí ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó ní: “Alábùkún fún ni ẹ̀yin òtòṣì, nítorí tiyín ni ìjọba Ọlọ́run.
21 Salige ere I, som nu hungre, thi I skulle mættes. Salige ere I, som nu græde, thi I skulle le.
Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ebi ń pa nísinsin yìí; nítorí tí ẹ ó yóò. Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ń sọkún nísinsin yìí: nítorí tí ẹ̀yin ó rẹ́rìn-ín.
22 Salige er I, når Menneskene hade eder, og når de udstøde eder og håne eder og forkaste eders Navn som ondt for Menneskesønnens Skyld.
Alábùkún fún ni ẹ̀yin, nígbà tí àwọn ènìyàn bá kórìíra yín, tí wọ́n bá yà yín kúrò nínú ẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n bá gàn yín, tí wọ́n bá ta orúkọ yín nù bí ohun búburú, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
23 Glæder eder på den Dag og jubler; thi se, eders Løn er stor i Himmelen. Thi på samme Måde gjorde deres Fædre ved Profeterne.
“Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, kí ẹ sì fò fún ayọ̀, nítorí púpọ̀ ní èrè yín ni ọ̀run. Báyìí ni àwọn baba yín ṣe ṣe sí àwọn wòlíì.
24 Men ve eder, I rige, thi I have allerede fået eders Trøst.
“Ègbé ni fún ẹ̀yin ọlọ́rọ̀ nítorí ẹ ti gba ìtùnú yín.
25 Ve eder, I, som nu ere mætte, thi I skulle hungre. Ve eder, I, som nu le, thi I skulle sørge og græde.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ó yó, nítorí ebi yóò pa yín, Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń rẹ́rìn-ín nísinsin yìí, nítorí tí ẹ̀yin ó ṣọ̀fọ̀, ẹ̀yin ó sì sọkún.
26 Ve eder, når alle Mennesker tale godt om eder; thi på samme Måde gjorde deres Fædre ved de falske Profeter.
Ègbé ni fún yín, nígbà tí gbogbo ènìyàn bá ń sọ̀rọ̀ yín ní rere, nítorí bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn baba wọn ṣe sí àwọn wòlíì èké.
27 Men jeg siger eder, I, som høre: Elsker eders Fjender, gører dem godt, som hade eder;
“Ṣùgbọ́n mo wí fún ẹ̀yin tí ń gbọ́ mi, ẹ fẹ́ àwọn ọ̀tá yín, ṣoore fún àwọn tí ó kórìíra yín.
28 velsigner dem, som forbande eder, og beder for dem, som krænke eder.
Súre fún àwọn tí ń fi yín ré, sì gbàdúrà fún àwọn tí ń kẹ́gàn yín.
29 Den, som slår dig på den ene Kind, byd ham også den anden til; og den, som tager Kappen fra dig, formen ham heller ikke Kjortelen!
Ẹni tí ó bá sì lù ọ́ ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ kan, yí kejì sí i pẹ̀lú; àti ẹni tí ó gba agbádá rẹ, má ṣe dá a dúró láti gba ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ pẹ̀lú.
30 Giv enhver, som beder dig; og af den, som tager, hvad dit er, kræve du det ikke igen!
Sì fi fún gbogbo ẹni tí ó tọrọ lọ́dọ̀ rẹ; lọ́dọ̀ ẹni tí ó sì kó ọ ní ẹrù, má sì ṣe padà béèrè.
31 Og som I ville, at Menneskene skulle gøre imod eder, ligeså skulle også I gøre imod dem!
Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin sì ti fẹ́ kí ènìyàn ṣe sí yín, kí ẹ̀yin sì ṣe bẹ́ẹ̀ sí wọn pẹ̀lú.
32 Og dersom I elske dem, som elske eder, hvad Tak have I derfor? Thi også Syndere elske dem, som dem elske.
“Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin bá fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ yín, ọpẹ́ kí ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ wọn.
33 Og dersom I gøre vel imod dem, der gøre vel imod eder, hvad Tak have I derfor? Thi også Syndere gøre det samme.
Bí ẹ̀yin sì ṣoore fún àwọn tí ó ṣoore fún yín, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
34 Og dersom I låne dem, af hvem I håbe at få igen, hvad Tak have I derfor? Thi også Syndere låne Syndere for at få lige igen.
Bí ẹ̀yin bá fi fún ẹni tí ẹ̀yin ń retí láti rí gbà padà, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń yá ẹlẹ́ṣẹ̀, kí wọn lè gba ìwọ̀n bẹ́ẹ̀ padà.
35 Men elsker eders Fjender, og gører vel, og låner uden at vente noget derfor, så skal eders Løn være stor, og I skulle være den Højestes Børn; thi han er god imod de utaknemmelige og onde.
Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin fẹ́ àwọn ọ̀tá yín kí ẹ sì ṣoore, kí ẹ̀yin sì yá ẹlòmíràn, kí ẹ̀yin má ṣe retí láti rí nǹkan gbà padà; èrè yín yóò sì pọ̀, àwọn ọmọ Ọ̀gá-ògo ni a ó sì máa pè yín: nítorí tí ó ṣe rere fún aláìmoore àti fún ẹni búburú.
36 Vorder barmhjertige, ligesom eders Fader er barmhjertig.
Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin ní àánú, gẹ́gẹ́ bí Baba yín sì ti ní àánú.
37 Og dømmer ikke, så skulle I ikke dømmes; fordømmer ikke, så skulle I ikke fordømmes; forlader, så skal der forlades eder;
“Ẹ má ṣe dá ni lẹ́jọ́, a kì yóò sì dá yín lẹ́jọ́: ẹ má ṣe dá ni lẹ́bi, a kì yóò sì dá yín lẹ́bi: ẹ dáríjì, a ó sì dáríjì yín.
38 giver, så skal der gives eder. Et godt, knuget, rystet, topfuldt Mål skulle de give i eders Skød; thi med hvad Mål I måle, skal der tilmåles eder igen."
Ẹ fi fún ni, a ó sì fi fún yín; òsùwọ̀n dáradára, àkìmọ́lẹ̀, àti àmìpọ̀, àkúnwọ́sílẹ̀, ni a ó wọ́n si àyà yín: nítorí òsùwọ̀n náà tí ẹ̀yin fi wọ́n, òun ni a ó padà fi wọ́n fún yín.”
39 Men han sagde dem også en Lignelse: "Mon en blind kan lede en blind? Ville de ikke begge falde i Graven?
Ó sì pa òwe kan fún wọn wí pé, “Afọ́jú ha lè ṣe amọ̀nà afọ́jú bí? Àwọn méjèèjì kọ́ ni yóò ṣubú sínú ihò bí?
40 En Discipel er ikke over sin Mester; men enhver, som er fuldt færdig, skal være som sin Mester.
Ẹni tí a ń kọ́ kì í ju olùkọ́ rẹ̀ lọ: ṣùgbọ́n olúkúlùkù ẹni tí a bá kọ dáradára, yóò dàbí olùkọ́ rẹ̀.
41 Men hvorfor ser du Skæven, som er i din Broders Øje; men Bjælken, som er i dit eget Øje, bliver du ikke var?
“Èétiṣe tí ìwọ fi ń wo ẹ̀rún igi tí ń bẹ ní ojú arákùnrin rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ ní ojú ara rẹ?
42 Eller hvorledes kan du sige til din Broder: Broder! lad mig drage Skæven ud, som er i dit Øje, du, som ikke ser Bjælken i dit eget Øje? Du Hykler! drag først Bjælken ud af dit Øje, og da kan du se klart til at drage Skæven ud, som er i din Broders Øje.
Tàbí ìwọ ó ti ṣe lè wí fún arákùnrin rẹ pé, ‘Arákùnrin, jẹ́ kí èmi yọ ẹ̀rún igi tí ń bẹ lójú rẹ,’ nígbà tí ìwọ tìkára rẹ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ lójú rẹ? Ìwọ àgàbàgebè, kọ́kọ́ yọ ìtí igi jáde kúrò lójú ara rẹ ná, nígbà náà ni ìwọ ó sì tó ríran gbangba láti yọ èérún igi tí ń bẹ lójú arákùnrin rẹ kúrò.
43 Thi der er intet godt Træ, som bærer rådden Frugt, og intet råddent Træ, som bærer god Frugt
“Nítorí igi rere kì í so èso búburú; bẹ́ẹ̀ ni igi búburú kì í so èso rere.
44 Thi hvert Træ kendes på sin egen Frugt; thi man sanker ikke Figener af Torne, ikke heller plukker man Vindruer af en Tornebusk.
Olúkúlùkù igi ni a ń fi èso rẹ̀ mọ̀ ọn; nítorí lórí ẹ̀gún òṣùṣú, ènìyàn kì í ká èso ọ̀pọ̀tọ́ bẹ́ẹ̀ ni lórí ẹ̀gún ọ̀gàn a kì í ká èso àjàrà.
45 Et godt Menneske fremfører det gode af sit Hjertes gode Forråd, og et ondt Menneske fremfører det onde af sit onde Forråd; thi af Hjertets Overflødighed taler hans Mund.
Ènìyàn rere láti inú yàrá ìṣúra rere ọkàn rẹ̀ ní mú ohun rere jáde wá; àti ènìyàn búburú láti inú ìṣúra búburú ọkàn rẹ̀ ní í mú ohun búburú jáde wá: nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ọkàn ní ẹnu ti máa sọ jáde.
46 Men hvorfor kalde I mig Herre, Herre! og gøre ikke, hvad jeg siger?
“Nítorí náà, èéṣe tí ẹ̀yin ń pè mí ní, ‘Olúwa, Olúwa,’ tí ẹ̀yin kò sì ṣe ohun tí mo wí?
47 Hver den, som kommer til mig og hører mine Ord og gør efter dem, hvem han er lig, skal jeg vise eder.
Ẹnikẹ́ni tí ó tọ̀ mí wá, tí ó sì ń gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó sì ń ṣe é, èmi yóò fi ẹni tí ó jọ hàn yín.
48 Han er lig et Menneske, der byggede et Hus og gravede i Dybden og lagde Grundvolden på Klippen; men da en Oversvømmelse kom, styrtede Floden imod det Hus, og den kunde ikke ryste det; thi det var bygget godt.
Ó jọ ọkùnrin kan, tí ó kọ́ ilé, tí ó sì wa ilẹ̀ jìn, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta, nígbà tí kíkún omi sì dé, ìgbì omi kọlu ilé náà, kò sì lè mì ín nítorí tí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta.
49 Men den, som hører og ikke gør derefter, han er lig et Menneske, der byggede et Hus på Jorden, uden Grundvold; og Floden styrtede imod det, og det faldt straks sammen, og dette Hus's Fald blev stort."
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́, tí kò sì ṣe é, ó dàbí ọkùnrin tí ó kọ́ ilé sí orí ilẹ̀ láìní ìpìlẹ̀; nígbà tí ìgbì omi kọlù ú, lọ́gán, ó sì wó; wíwó ilé náà sì pọ̀ púpọ̀.”