< 1 Tessalonikerne 4 >
1 Så bede vi eder i øvrigt, Brødre! og formane eder i den Herre Jesus, at som I jo have lært af os, hvorledes I bør vandre og behage Gud, således som I jo også gøre, at I således må gøre end yderligere Fremgang.
Ní ìparí, ará, a sọ fún un yín bí ẹ ti ń gbé láti wu Ọlọ́run, àní gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí ń ṣe. Nísinsin yìí, a béèrè, a sì ń rọ̀ yín nínú Jesu Olúwa láti ṣe bẹ́ẹ̀ àti bẹ́ẹ̀ sí.
2 I vide jo, hvilke Bud vi gave eder ved den Herre Jesus.
Nítorí pé, ẹ̀yin mọ àṣẹ tí a pa fún yín láti ọ̀dọ̀ Olúwa Jesu.
3 Thi dette er Guds Villie, eders Helliggørelse, at I afholde eder fra Utugt;
Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí ẹ jẹ́ mímọ́, kí ẹ sì yàgò kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè,
4 at hver af eder veed at vinde sig sin egen Hustru i Hellighed og Ære,
kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín kọ́ láti ṣàkóso ara rẹ̀ ní ọ̀nà mímọ́ àti pẹ̀lú ọlá,
5 ikke i Begærings Brynde som Hedningerne, der ikke kende Gud;
kì í ṣe ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìkọlà, ẹni tí kò mọ Ọlọ́run;
6 at ingen foruretter og bedrager sin Broder i nogen Sag; thi Herren er en Hævner over alt dette, som vi også før have sagt og vidnet for eder.
àti pé nínú ọ̀rọ̀ yìí, kí ẹnikẹ́ni nínú yín máa ṣe rẹ arákùnrin rẹ̀ jẹ nípa ohunkóhun. Olúwa yóò jẹ àwọn ènìyàn ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn, gẹ́gẹ́ bí a ti ń sọ fún un yín tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.
7 Thi Gud kaldte os ikke til Urenhed, men til Helliggørelse.
Nítorí Ọlọ́run kò pè wá sínú ìwà èérí, bí kò ṣe sínú ìgbé ayé mímọ́.
8 Derfor altså, den, som foragter dette, han foragter ikke et Menneske, men Gud, som også giver sin Helligånd til eder.
Nítorí náà, ẹnikẹ́ni tí ó kọ òfin yìí, kì í ṣe òfin ènìyàn ni ẹni náà kọ̀, bí kò ṣe òfin Ọlọ́run ẹni tí ó fi Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ fún ni.
9 Men om Broderkærligheden have I ikke nødig, at jeg skal skrive eder til; thi I ere selv oplærte af Gud til at elske hverandre;
Ṣùgbọ́n nípa ìfẹ́ ará, a kò ní láti tún kọ̀wé sí i yín, ìdí ni pé, Ọlọ́run pàápàá ń kọ́ yín láti fẹ́ràn ara yín.
10 det gøre I jo også imod alle Brødrene i hele Makedonien; men vi formane eder, Brødre! til yderligere Fremgang
Nítòótọ́, ẹ ní ìfẹ́ fún àwọn arákùnrin tí ó wà káàkiri Makedonia. Síbẹ̀síbẹ̀ àwa ń bẹ̀ yín, ará, pé kí ẹ̀yin kí ó máa tẹ̀síwájú nínú rẹ̀.
11 og til at sætte en Ære i at leve stille og varetage hver sit og arbejde med eders Hænder, således som vi bød eder,
Ẹ jẹ́ kí èyí jẹ́ ìfẹ́ ọkàn yín láti gbé jẹ́ẹ́ àti láti mọ ti ara yín àti kí olúkúlùkù kọjú sí iṣẹ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a ti wí fún yín.
12 for at I kunne vandre sømmeligt over for dem, som ere udenfor, og for ikke at trænge til nogen.
Èyí yóò mú kí àwọn tí kì í ṣe onígbàgbọ́ gbẹ́kẹ̀lé yín àti láti bu ọlá fún yín pẹ̀lú. Bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ kò ní máa wo ojú ẹnikẹ́ni láti fún yín ni owó tí ẹ ó fi san gbèsè.
13 Men vi ville ikke, Brødre! at I skulle være uvidende med Hensyn til dem, som sove hen, for at I ikke skulle sørge som de andre, der ikke have Håb.
Ẹ̀yin ará, àwa kò fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó jẹ́ òpè ní ti àwọn tí ó ti sùn, pé kí ẹ máa banújẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn yòókù tí kò ní ìrètí.
14 Thi når vi tro, at Jesus er død og opstanden, da skal også Gud ligeså ved Jesus føre de hensovede frem med ham.
A gbàgbọ́ pé, Jesu kú, ó sì tún jíǹde, àti pé Ọlọ́run yóò mú gbogbo àwọn tí ó ti sùn nínú rẹ̀ padà wá.
15 Thi dette sige vi eder med Herrens Ord, at vi levende, som blive tilbage til Herrens Tilkommelse, vi skulle ingenlunde komme forud for de hensovede.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, pé àwa tí ó wà láààyè, tí a sì kù lẹ́yìn de à ti wá Olúwa, bí ó ti wù kí ó rí, kì yóò ṣáájú àwọn tí ó sùn láti pàdé rẹ̀.
16 Thi Herren selv skal stige ned fra Himmelen med et Tilråb, med Overengels Røst og med Guds Basun, og de døde i Kristus skulle opstå først;
Nítorí pé, Olúwa fúnra rẹ̀ yóò sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá, pẹ̀lú ariwo àṣẹ ńlá àti ohùn àwọn angẹli ti àwọn angẹli ti àwọn ti ìpè Ọlọ́run, àwọn òkú nínú Kristi yóò sì kọ́kọ́ jíǹde.
17 derefter skulle vi levende, som blive tilbage, bortrykkes tillige med dem i Skyer til at møde Herren i Luften; og så skulle vi altid være sammen med Herren.
Nígbà náà ni a ó gba àwa tí ó sì wà láààyè sókè nínú àwọsánmọ̀ láti ọwọ́ Olúwa. A ó sì wà pẹ̀lú rẹ̀ títí láéláé.
18 Så trøster hverandre med disse Ord!
Nítorí náà, ẹ tu ara yín nínú, kí ẹ sì máa gba ara yín níyànjú pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.