< Salme 29 >
1 En Salme af David. Giver HERREN, I Guds Sønner, giver HERREN Ære og Pris,
Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
2 giver HERREN hans Navns Ære; tilbed HERREN i helligt Skrud!
Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
3 HERRENS Røst er over Vandene, Ærens Gud lader Tordenen rulle, HERREN, over de vældige Vande!
Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
4 HERRENS Røst med Vælde, HERRENS Røst i Højhed,
Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
5 HERRENS Røst, den splintrer Cedre, HERREN splintrer Libanons Cedre,
Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
6 faar Libanon til at springe som en Kalv og Sirjon som den vilde Okse!
Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
7 HERRENS Røst udslynger Luer.
Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
8 HERRENS Røst faar Ørk til at skælve, HERREN faar Kadesj's Ørk til at skælve!
Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
9 HERRENS Røst faar Hind til at føde, og den gør lyst i Skoven. Alt i hans Helligdom raaber: »Ære!«
Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
10 HERREN tog Sæde og sendte Vandfloden, HERREN tog Sæde som Konge for evigt.
Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
11 HERREN give Kraft til sit Folk, HERREN velsigne sit Folk med Fred!
Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.