< Salme 11 >
1 Til Sangmesteren. Af David. Jeg tager min Tilflugt til HERREN! Hvor kan I sige til min Sjæl: »Fly som en Fugl til Bjergene!
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa. Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé, “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
2 Thi se, de gudløse spænder Buen, lægger Pilen til Rette paa Strengen for i Mørke at ramme de oprigtige af Hjertet.
Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀; wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn láti tafà níbi òjìji sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
3 Naar selv Grundpillerne styrter, hvad gør den retfærdige da?«
Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́ kí ni olódodo yóò ṣe?”
4 HERREN er i sin hellige Hal, i Himlen er HERRENS Trone; paa Jorderig skuer hans Øjne ned, hans Blik ransager Menneskens Børn;
Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn; ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
5 retfærdige og gudløse ransager HERREN; dem, der elsker Uret, hader hans Sjæl;
Olúwa ń yẹ olódodo wò, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
6 over gudløse sender han Regn af Gløder og Svovl, et Stormvejr er deres tilmaalte Bæger.
Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó; àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
7 Thi retfærdig er HERREN, han elsker at øve Retfærd, de oprigtige skuer hans Aasyn!
Nítorí, olódodo ní Olúwa, o fẹ́ràn òdodo; ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.