< Lukas 24 >
1 Men paa den første Dag i Ugen meget aarle kom de til Graven og bragte de vellugtende Urter, som de havde beredt.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ ọ̀sẹ̀, àwọn obìnrin wá sí ibojì, wọ́n sì mú ìkunra olóòórùn dídùn ti wọ́n tí pèsè sílẹ̀ wá.
2 Og de fandt Stenen bortvæltet fra Graven.
Òkúta ti yí kúrò ní ẹnu ibojì.
3 Men da de gik derind, fandt de ikke den Herres Jesu Legeme.
Nígbà tí wọ́n sì wọ inú rẹ̀, wọn kò rí òkú Jesu Olúwa.
4 Og det skete, da de vare tvivlraadige om dette, se, da stode to Mænd for dem i straalende Klædebon.
Bí wọ́n ti dààmú kiri níhà ibẹ̀, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì aláṣọ dídán dúró tì wọ́n.
5 Men da de bleve forfærdede og bøjede deres Ansigter imod Jorden, sagde de til dem: „Hvorfor lede I efter den levende iblandt de døde?
Nígbà tí ẹ̀rù ń bà wọ́n, tí wọ́n sì dojúbolẹ̀, àwọn angẹli náà bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá alààyè láàrín àwọn òkú?
6 Han er ikke her, men han er opstanden; kommer i Hu, hvorledes han talte til eder, medens han endnu var i Galilæa, og sagde,
Kò sí níhìn-ín yìí, ṣùgbọ́n ó jíǹde; ẹ rántí bí ó ti wí fún yín nígbà tí ó wà ní Galili.
7 at Menneskesønnen burde overgives i syndige Menneskers Hænder og korsfæstes og opstaa paa den tredje Dag.”
Pé, ‘A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́, a ó sì kàn án mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.’”
8 Og de kom hans Ord i Hu.
Wọ́n sì rántí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
9 Og de vendte tilbage fra Graven og kundgjorde alle disse Ting for de elleve og for alle de andre.
Wọ́n sì padà ti ibojì wá, wọ́n sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún àwọn mọ́kànlá, àti fún gbogbo àwọn ìyókù.
10 Men det var Maria Magdalene og Johanna og Maria, Jakobs Moder, og de øvrige Kvinder med dem; de sagde Apostlene disse Ting.
Maria Magdalene, àti Joanna, àti Maria ìyá Jakọbu, àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn sì ni àwọn tí ó ròyìn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn aposteli.
11 Og disse Ord kom dem for som løs Tale; og de troede dem ikke.
Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sì dàbí ìsọkúsọ lójú wọn, wọn kò sì gbà wọ́n gbọ́.
12 Men Peter stod op og løb til Graven; og da han kiggede derind, ser han Linklæderne alene liggende der, og han gik hjem i Undren over det, som var sket.
Nígbà náà ni Peteru dìde, ó súré lọ sí ibojì; nígbà tí ó sì bẹ̀rẹ̀, ó rí aṣọ àlà lọ́tọ̀ fúnra wọn, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀, ẹnu yà á sí ohun tí ó ṣe.
13 Og se, to af dem vandrede paa den samme Dag til en Landsby, som laa tresindstyve Stadier fra Jerusalem, dens Navn var Emmaus.
Sì kíyèsi i, àwọn méjì nínú wọn ń lọ ní ọjọ́ náà sí ìletò kan tí a ń pè ní Emmausi, tí ó jìnnà sí Jerusalẹmu níwọ̀n ọgọ́ta ibùsọ̀.
14 Og de talte med hinanden om alle disse Ting, som vare skete.
Wọ́n ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣẹlẹ̀.
15 Og det skete, medens de samtalede og spurgte hinanden indbyrdes, da kom Jesus selv nær og vandrede med dem.
Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń bá ara wọn sọ̀rọ̀, tí wọ́n sì ń bá ara wọn jíròrò, Jesu tìkára rẹ̀ súnmọ́ wọn, ó sì ń bá wọn rìn lọ.
16 Men deres Øjne holdtes til, saa de ikke kendte ham.
Ṣùgbọ́n a rú wọn lójú, kí wọn má le mọ̀ ọ́n.
17 Men han sagde til dem: „Hvad er dette for Ord, som I skifte med hinanden paa Vejen?” Og de standsede bedrøvede.
Ó sì bi wọ́n pé, “Ọ̀rọ̀ kín ni ẹ̀yin ń bá ara yín sọ, bí ẹ̀yin ti ń rìn?” Wọ́n sì dúró jẹ́, wọ́n fajúro.
18 Men en af dem, som hed Kleofas, svarede og sagde til ham: „Er du alene fremmed i Jerusalem og ved ikke, hvad der er sket der i disse Dage?”
Ọ̀kan nínú wọn, tí a ń pè ní Kileopa, sì dáhùn wí fún un pé, “Àlejò sá à ni ìwọ ní Jerusalẹmu, tí ìwọ kò sì mọ ohun tí ó ṣẹ̀ níbẹ̀ ní ọjọ́ wọ̀nyí?”
19 Og han sagde til dem: „Hvilket?” Men de sagde til ham: „Det med Jesus af Nazareth, som var en Profet, mægtig i Gerning og Ord for Gud og alt Folket;
Ó sì bi wọ́n pé, “Kín ni?” Wọ́n sì wí fún un pé, “Ní ti Jesu ti Nasareti, ẹni tí ó jẹ́ wòlíì, tí ó pọ̀ ní ìṣe àti ní ọrọ̀ níwájú Ọlọ́run àti gbogbo ènìyàn,
20 og hvorledes Ypperstepræsterne og vore Raadsherrer have overgivet ham til Dødsdom og korsfæstet ham.
àti bí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà wa ti fi òun lé wọn lọ́wọ́ láti dá a lẹ́bi ikú, àti bí wọ́n ti kàn án mọ́ àgbélébùú.
21 Men vi haabede, at han var den, som skulde forløse Israel. Men med alt dette er det i Dag den tredje Dag, siden dette skete.
Bẹ́ẹ̀ ni òun ni àwa ti ní ìrètí pé, òun ni ìbá dá Israẹli ní ìdè. Àti pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, òní ni ó di ọjọ́ kẹta tí nǹkan wọ̀nyí ti ṣẹlẹ̀.
22 Men ogsaa nogle af vore Kvinder have forfærdet os, idet de kom aarle til Graven,
Àwọn obìnrin kan pẹ̀lú nínú ẹgbẹ́ wa, tí wọ́n lọ si ibojì ní kùtùkùtù, sì wá yà wá lẹ́nu,
23 og da de ikke fandt hans Legeme, kom de og sagde, at de havde ogsaa set et Syn af Engle, der sagde, at han lever.
nígbà tí wọn kò sì rí òkú rẹ̀, wọ́n wá wí pé, àwọn rí ìran àwọn angẹli tí wọ́n wí pé, ó wà láààyè.
24 Og nogle af vore gik hen til Graven, og de fandt det saaledes, som Kvinderne havde sagt; men ham saa de ikke.”
Àti àwọn kan tí wọ́n wà pẹ̀lú wa lọ sí ibojì, wọ́n sì rí i gẹ́gẹ́ bí àwọn obìnrin náà ti wí, ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ ni wọn kò rí.”
25 Og han sagde til dem: „O I uforstandige og senhjertede til at tro paa alt det, som Profeterne have talt!
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tí òye kò yé, tí ẹ sì yigbì ní àyà láti gba gbogbo èyí tí àwọn wòlíì ti wí gbọ́,
26 Burde ikke Kristus lide dette og indgaa til sin Herlighed?”
kò ha yẹ kí Kristi ó jìyà nǹkan wọ̀nyí kí ó sì wọ inú ògo rẹ̀ lọ.”
27 Og han begyndte fra Moses og fra alle Profeterne og udlagde dem i alle Skrifterne det, som handlede om ham.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti Mose àti gbogbo àwọn wòlíì wá, ó sì túmọ̀ nǹkan fún wọn nínú ìwé mímọ́ gbogbo nípa ti ara rẹ̀.
28 Og de nærmede sig til Landsbyen, som de gik til; og han lod, som han vilde gaa videre.
Wọ́n sì súnmọ́ ìletò tí wọ́n ń lọ, ó sì ṣe bí ẹni pé yóò lọ sí iwájú.
29 Og de nødte ham meget og sagde: „Bliv hos os; thi det er mod Aften, og Dagen hælder.” Og han gik ind for at blive hos dem.
Wọ́n sì rọ̀ ọ́, pé, “Bá wa dúró: nítorí ó di ọjọ́ alẹ́, ọjọ́ sì kọjá tán.” Ó sì wọlé lọ, ó bá wọn dúró.
30 Og det skete, da han havde sat sig med dem til Bords, tog han Brødet, velsignede og brød det og gav dem det.
Ó sì ṣe, bí ó ti bá wọn jókòó ti oúnjẹ, ó mú àkàrà, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún wọn.
31 Da bleve deres Øjne aabnede, og de kendte ham; og han blev usynlig for dem.
Ojú wọn sì là, wọ́n sì mọ̀ ọ́n, ó sì nù mọ́ wọn ní ojú.
32 Og de sagde til hinanden: „Brændte ikke vort Hjerte i os, medens han talte til os paa Vejen og oplod os Skrifterne?”
Wọ́n sì bá ara wọn sọ pé, “Ọkàn wa kò ha gbiná nínú wa, nígbà tí ó ń bá wa sọ̀rọ̀ tí ó sì ń túmọ̀ ìwé mímọ́ fún wa!”
33 Og de stode op i den samme Time og vendte tilbage til Jerusalem og fandt forsamlede de elleve og dem, som vare med dem, hvilke sagde:
Wọ́n sì dìde ní wákàtí kan náà, wọ́n padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì bá àwọn mọ́kànlá péjọ, àti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ wọn.
34 „Herren er virkelig opstanden og set af Simon.”
Wọn si wí pé, “Olúwa jíǹde nítòótọ́, ó sì ti fi ara hàn fún Simoni!”
35 Og de fortalte, hvad der var sket paa Vejen, og hvorledes han blev kendt af dem, idet han brød Brødet.
Àwọn náà sì ròyìn nǹkan tí ó ṣe ní ọ̀nà, àti bí ó ti di mí mọ̀ fún wọn ní bíbu àkàrà.
36 Men medens de talte dette, stod han selv midt iblandt dem; og han siger til dem: „Fred være med eder!”
Bí wọ́n sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí Jesu tìkára rẹ̀ dúró láàrín wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
37 Da forskrækkedes de og betoges af Frygt og mente, at de saa en Aand.
Ṣùgbọ́n àyà fò wọ́n, wọ́n sì wárìrì, wọ́n ṣe bí àwọn rí ẹ̀mí kan.
38 Og han sagde til dem: „Hvorfor ere I forfærdede? og hvorfor opstiger der Tvivl i eders Hjerter?
Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ara yín kò lélẹ̀? Èé sì ti ṣe tí èròkerò fi ń sọ nínú ọkàn yín?
39 Ser mine Hænder og mine Fødder, at det er mig selv; føler paa mig og ser; thi en Aand har ikke Kød og Ben, som I se, at jeg har.”
Ẹ wo ọwọ́ mi àti ẹsẹ̀ mi, pé èmi tìkára mi ni! Ẹ dì mímú kí ẹ wò ó nítorí tí iwin kò ní ẹran àti egungun lára, bí ẹ̀yin ti rí tí èmi ní.”
40 Og da han havde sagt dette, viste han dem sine Hænder og sine Fødder.
Nígbà tí ó sì wí bẹ́ẹ̀ tan, ó fi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ hàn wọ́n.
41 Men da de af Glæde herover endnu ikke kunde tro og undrede sig, sagde han til dem: „Have I her noget at spise?”
Nígbà tí wọn kò sì tí ì gbàgbọ́ fún ayọ̀, àti fún ìyanu, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ní ohunkóhun jíjẹ níhìn-ín yìí?”
42 Og de gave ham et Stykke af en stegt Fisk.
Wọ́n sì fún un ní ẹja tí a fi oyin sè.
43 Og han tog det og spiste det for deres Øjne.
Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.
44 Men han sagde til dem: „Dette er mine Ord, som jeg talte til eder, medens jeg endnu var hos eder, at de Ting bør alle sammen opfyldes, som ere skrevne om mig i Mose Lov og Profeterne og Psalmerne.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé, a ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mose, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Saamu, nípasẹ̀ mi.”
45 Da oplod han deres Forstand til at forstaa Skrifterne.
Nígbà náà ni ó ṣí wọn ní iyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn.
46 Og han sagde til dem: „Saaledes er der skrevet, at Kristus skulde lide og opstaa fra de døde paa den tredje Dag,
Ó sì wí fún wọn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni a ti kọ̀wé rẹ̀, pé: kí Kristi jìyà, àti kí ó sì jíǹde ní ọjọ́ kẹta kúrò nínú òkú,
47 og at der i hans Navn skal prædikes Omvendelse og Syndernes Forladelse for alle Folkeslagene og begyndes fra Jerusalem.
àti pé kí a wàásù ìrònúpìwàdà àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ lórúkọ rẹ̀, ní orílẹ̀-èdè gbogbo, bẹ̀rẹ̀ láti Jerusalẹmu lọ.
48 I ere Vidner om disse Ting.
Ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí.
49 Og se, jeg sender min Faders Forjættelse over eder; men I skulle blive i Staden, indtil I blive iførte Kraft fra det høje.”
Èmi yóò rán ohun tí Baba mi ṣe ìlérí sí yín, ṣùgbọ́n ẹ jókòó ní ìlú Jerusalẹmu, títí a ó fífi agbára wọ̀ yín, láti òkè ọ̀run wá.”
50 Men han førte dem ud til hen imod Bethania, og han opløftede sine Hænder og velsignede dem.
Ó sì mú wọn jáde lọ títí wọ́n fẹ́rẹ̀ dé Betani, nígbà tí ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó súre fún wọn.
51 Og det skete, idet han velsignede dem, skiltes han fra dem og opløftedes til Himmelen.
Ó sì ṣe, bí ó ti ń súre fún wọn, ó yà kúrò lọ́dọ̀ wọn, a sì gbé e lọ sí ọ̀run.
52 Og efter at have tilbedet ham vendte de tilbage til Jerusalem med stor Glæde.
Wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì padà lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ayọ̀ púpọ̀.
53 Og de vare stedse i Helligdommen og priste Gud.
Wọ́n sì wà ní tẹmpili nígbà gbogbo, wọ́n ń fi ìyìn, àti ìbùkún fún Ọlọ́run.