< 3 Mosebog 3 >

1 Men er hans Offergave et Takoffer, saa skal det, hvis han bringer det af Hornkvæget, være et lydefrit Han eller Hundyr, han bringer HERREN.
“‘Bí ọrẹ ẹnìkan bá jẹ́ ọrẹ àlàáfíà, tí ó sì mú ẹran wá láti inú agbo màlúù yálà akọ tàbí abo, kí ó mú èyí tí kò ní àbùkù wá síwájú Olúwa.
2 Han skal lægge sin Haand paa sin Offergaves Hoved og slagte Dyret ved Indgangen til Aabenbaringsteltet; og Arons Sønner, Præsterne, skal sprænge Blodet rundt om paa Alteret.
Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
3 Saa skal han af Takofferet som Ildoffer for HERREN frembære Fedtet, der dækker Indvoldene, og alt Fedtet paa Indvoldene,
Láti ara ọrẹ àlàáfíà ni kí ẹni náà ti mú ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa, gbogbo ọ̀nà tí ó bo nǹkan inú ẹran náà àti gbogbo ọ̀rá tí ó so mọ́ wọn.
4 begge Nyrerne med det Fedt, som sidder paa dem ved Lændemusklerne, og Leverlappen, som han skal skille fra ved Nyrerne.
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá ara rẹ̀ tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀, àti gbogbo ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
5 Og Arons Sønner skal bringe det som Røgoffer paa Alteret oven paa Brændofferet paa Brændet, der ligger paa Ilden, et Ildoffer til en liflig Duft for HERREN.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun tí a fi iná sun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
6 Men hvis hans Offergave, der bringes som Takoffer til HERREN, tages af Smaakvæget, skal det være et lydefrit Han eller Hundyr, han bringer.
“‘Bí ó bá ṣe inú agbo ewúrẹ́ àti àgùntàn ni ó ti mú ọrẹ àlàáfíà wá fún Olúwa kí ó mú akọ tàbí abo tí kò ní àbùkù.
7 Er den Offergave, han vil bringe, et Lam, skal han bringe det hen for HERRENS Aasyn
Bí ó bá ṣe pé ọ̀dọ́-àgùntàn ni ó mú, kí ó mú un wá síwájú Olúwa.
8 og lægge sin Haand paa sin Offergaves Hoved og slagte Dyret foran Aabenbaringsteltet, og Arons Sønner skal sprænge Blodet deraf rundt om paa Alteret.
Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú àgọ́ ìpàdé, kí àwọn ọmọ Aaroni wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
9 Saa skal han af Takofferet som Ildoffer for HERREN frembære Fedtet, hele Fedthalen, skilt fra Rygraden, Fedtet, som dækker Indvoldene, og alt Fedtet paa Indvoldene,
Kí o sì mú wá nínú ẹbọ àlàáfíà náà, fún ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa; ọ̀rá rẹ̀ àti gbogbo ìrù rẹ̀ tí ó ní ọ̀rá, òun ni kí o mú kúrò súnmọ́ egungun ẹ̀yìn àti ọ̀rá tí ó bo ìfun lórí; àti gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ lára ìfun.
10 begge Nyrerne med det Fedt, som sidder paa dem ved Lændemusklerne, og Leverlappen, som han skal skille fra ved Nyrerne.
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí o yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
11 Og Præsten skal bringe det som Røgoffer paa Alteret, Ildofferspise for HERREN.
Kí àlùfáà sun ún lórí pẹpẹ bí oúnjẹ ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.
12 Men hvis hans Offergave er en Ged, skal han bringe den hen for HERRENS Aasyn
“‘Bí ó bá ṣe pé ewúrẹ́ ni ó mú, kí ó mú un wá síwájú Olúwa.
13 og lægge sin Haand paa dens Hoved og slagte den foran Aabenbaringsteltet, og Arons Sønner skal sprænge Blodet rundt om paa Alteret.
Kí ó gbé ọwọ́ lé e lórí. Kí ó sì pa á ní iwájú àgọ́ ìpàdé. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Aaroni yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ ẹran náà yí pẹpẹ ká.
14 Saa skal han deraf frembære som sin Offergave, som et Ildoffer for HERREN, Fedtet, det dækker Indvoldene, og alt Fedtet paa Indvoldene,
Lára ọrẹ tó mú wá, kí ó mú ẹbọ sísun fún Olúwa, gbogbo ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú rẹ̀ àti ohun gbogbo tó so mọ́ ọn.
15 begge Nyrerne med det Fedt, som sidder paa dem ved Lændemusklerne, og Leverlappen, som han skal skille fra ved Nyrerne.
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá ara rẹ̀ tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ jáde pẹ̀lú kíndìnrín.
16 Og Præsten skal bringe det som Røgoffer paa Alteret, Ildofferspise til en liflig Duft. Alt Fedt skal være HERRENS.
Kí àlùfáà sun ún lórí pẹpẹ bí oúnjẹ, ọrẹ tí a fi iná sun, ní òórùn dídùn. Gbogbo ọ̀rá rẹ̀ jẹ́ ti Olúwa.
17 En evig Anordning skal det være for eder fra Slægt til Slægt, hvor I end bor: Intet Fedt og intet Blod maa I nyde!
“‘Èyí jẹ́ ìlànà láéláé fún àwọn ìran tó ń bọ̀, ní gbogbo ibi tí ẹ bá ń gbé, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ọ̀rá tàbí ẹ̀jẹ̀.’”

< 3 Mosebog 3 >