< 3 Mosebog 17 >

1 HERREN talede til Moses og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Tal til Aron og hans Sønner og alle Israeliterne og sig til dem: Dette har HERREN paabudt:
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli: ‘Ohun tí Olúwa pàṣẹ nìyí,
3 Om nogen af Israels Hus slagter et Stykke Hornkvæg, et Faar eller en Ged i Lejren, eller han slagter dem uden for Lejren,
bí ẹnikẹ́ni nínú ìdílé Israẹli bá pa màlúù tàbí ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí àgbò nínú ibùdó tàbí bí ó bá pa á lẹ́yìn ibùdó
4 uden at bringe dem hen til Aabenbaringsteltets Indgang for at bringe HERREN en Offergave foran HERRENS Bolig, da skal dette tilregnes den Mand som Blodskyld; han har udgydt Blod, og den Mand skal udryddes af sit Folk.
tí kò sì mú un wá sí ibi àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa níwájú àgọ́ ìpàdé, ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni kí ẹ kà sí ẹni náà lọ́rùn: torí pé ó ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹni náà ni a ó sì gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
5 Dette er anordnet, for at Israeliterne skal bringe deres Slagtofre, som de slagter ude paa Marken, til HERREN, til Aabenbaringsteltets Indgang, til Præsten, og ofre dem som Takofre til HERREN.
Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí àwọn ọmọ Israẹli le è máa mú ẹbọ wọn tí wọn ti rú ní ìta gbangba wá sí iwájú Olúwa: wọ́n gbọdọ̀ mú un wá síwájú àlùfáà àní sí Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì rú wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa.
6 Præsten skal da sprænge Blodet paa HERRENS Alter ved Indgangen til Aabenbaringsteltet og bringe Fedtet som Røgoffer, en liflig Duft for HERREN.
Àlùfáà náà yóò sì fi ẹ̀jẹ̀ náà wọ́n ibi pẹpẹ Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, yóò sì sun ọ̀rá rẹ̀ ní òórùn dídùn sí Olúwa.
7 Og de maa ikke mere ofre deres Slagtofre til Bukketroldene, som de boler med. Det skal være en evig gyldig Anordning for dem fra Slægt til Slægt!
Nítorí náà, kí wọn má ṣe rú ẹbọ wọn sí ère ẹranko mọ́, nínú èyí tí wọ́n ti ṣe àgbèrè tọ̀ lọ. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé láti ìran dé ìran wọn tí ń bọ̀.’
8 Og du skal sige til dem: Om nogen af Israels Hus eller de fremmede, der bor iblandt eder, ofrer et Brændoffer eller Slagtoffer
“Kí ó sọ fún wọn pé, ‘Ọkùnrin yówù kí ó jẹ́ ní ìdílé Israẹli tàbí ti àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn tí ó bá rú ẹbọ sísun tàbí ṣe ẹbọ
9 og ikke bringer det hen til Aabenbaringsteltets Indgang for at ofre det til HERREN, da skal den Mand udryddes af sin Slægt.
tí kò sì mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé láti fi rú ẹbọ sí Olúwa irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
10 Om nogen af Israels Hus eller af de fremmede, der bor iblandt dem, nyder noget Blod, saa vender jeg mit Aasyn mod den, der nyder Blodet, og udrydder ham af hans Folk.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀ yálà nínú ìdílé Israẹli tàbí àwọn àlejò tí ń gbé láàrín wọn, Èmi yóò bínú sí irú ẹni náà tí ó jẹ ẹ̀jẹ̀, èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
11 Thi Kødets Sjæl er i Blodet, og jeg har givet eder det til Brug paa Alteret til at skaffe eders Sjæle Soning; thi det er Blodet, som skaffer Soning, fordi det er Sjælen.
Nítorí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí ẹ̀dá wà, èmi sì ti fi fún yín lórí pẹpẹ fún ètùtù ọkàn yín: nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni a fi ń ṣe ètùtù fún ẹ̀mí ènìyàn.
12 Derfor har jeg sagt til Israeliterne: Ingen af eder maa nyde Blod; heller ikke den fremmede, der bor iblandt eder, maa nyde Blod.
Ìdí nìyí tí mo fi sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ọ̀kankan nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àlejò kan tí ń ṣe àtìpó nínú yín kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀.
13 Om nogen af Israeliterne eller af de fremmede, der bor iblandt dem, nedlægger et Stykke Vildt eller en Fugl af den Slags, der maa spises, da skal han lade Blodet løbe ud og dække det med Jord.
“‘Ẹnikẹ́ni yálà nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé láàrín wọn, tí ó bá pa ẹranko tàbí ẹyẹ tí ó yẹ fún jíjẹ gbọdọ̀ ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀ kí ó sì bò ó mọ́lẹ̀.
14 Thi om alt Køds Sjæl gælder det, at dets Blod er dets Sjæl; derfor har jeg sagt til Israeliterne: I maa ikke nyde Blodet af noget som helst Kød, thi alt Køds Sjæl er dets Blod; enhver, der nyder det, skal udryddes.
Torí pé ẹ̀mí gbogbo ẹ̀dá ni ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, torí náà ni mo fi kìlọ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí kankan, torí pé nínú ẹ̀jẹ̀ ohun abẹ̀mí wọ̀nyí ni ẹ̀mí wọn wà, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹ́ ni a ó gé kúrò.
15 Enhver, der spiser selvdøde eller sønderrevne Dyr, det være sig en indfødt eller en fremmed, skal tvætte sine Klæder og bade sig i Vand og være uren til Aften; saa er han ren.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó kú sílẹ̀ fúnra rẹ̀, tàbí èyí tí ẹranko búburú pa kálẹ̀ yálà onílé tàbí àlejò, ó ní láti fọ aṣọ rẹ̀. Kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di àṣálẹ́ lẹ́yìn èyí ni yóò tó di mímọ́.
16 Men hvis han ikke tvætter sine Klæder og bader sig, skal han undgælde for sin Brøde.
Ṣùgbọ́n bí ó bá kọ̀ láti wẹ ara rẹ̀ tí kò sì fọ aṣọ rẹ̀ náà: ẹ̀bi rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.’”

< 3 Mosebog 17 >