< Josua 2 >

1 Josua, Nuns Søn, udsendte hemmeligt fra Sjittim to Mænd som Spejdere med den Befaling: »Gaa hen og undersøg Landet, særlig Jeriko!« De gav sig da paa Vej og kom ind i et Hus til en Skøge ved Navn Rahab, og der lagde de sig til Hvile.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 Da blev der meldt Kongen af Jeriko: »Se, der er kommet nogle israelitiske Mænd hertil i Nat for at udspejde Landet!«
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 Og Kongen af Jeriko sendte Bud til Rahab og lod sige: »Udlever de Mænd, som er kommet til dig; thi de er kommet for at udspejde hele Landet!«
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 Men Kvinden tog og skjulte de to Mænd og sagde: »Ja, Mændene kom ganske vist til mig, men jeg vidste ikke, hvor de var fra;
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 og da Porten skulde lukkes i Mørkningen, gik Mændene bort. Jeg ved ikke, hvor de gik hen! Sæt hurtigt efter dem, saa kan I indhente dem!«
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 Men hun havde ført dem op paa Taget og skjult dem under Hørstænglerne, som hun havde bredt ud paa Taget.
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 Mændene satte saa efter dem ad Vejen til Jordan hen til Vadestederne, og Porten blev lukket, saa snart Forfølgerne var udenfor.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 Før de to Mænd endnu havde lagt sig, kom hun op paa Taget til dem;
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 og hun sagde til dem: »Jeg ved, at HERREN har givet eder Landet, thi vi er grebet af Rædsel for eder, og alle Landets Indbyggere er skrækslagne over eder.
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 Thi vi har hørt, hvorledes HERREN lod Vandet i det røde Hav tørre bort foran eder, da I drog ud af Ægypten, og hvad I gjorde ved de to Amoriterkonger hinsides Jordan, Sihon og Og, paa hvem I lagde Band.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Da vi hørte det, blev vi slaget af Rædsel og tabte alle Modet over for eder; thi HERREN eders Gud er Gud oppe i Himmelen og nede paa Jorden.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 Men tilsværg mig nu ved HERREN, at I vil vise Godhed mod mit Fædrene Hus, ligesom jeg har vist Godhed mod eder, og giv mig et sikkert Tegn paa,
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
13 at I vil lade min Fader og Moder, mine Brødre og Søstre og alt, hvad deres er, blive i Live og redde os fra Døden!«
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 Da sagde Mændene til hende: »Vi indestaar med vort Liv for eder, hvis du ikke røber vort Forehavende; og naar HERREN giver os Landet, vil vi vise dig Godhed og Trofasthed!«
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 Derpaa hejsede hun dem med et Reb ned gennem Vinduet, thi hendes Hus laa ved Bymuren, og hun boede ved Muren;
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 og hun sagde til dem: »Gaa ud i Bjergene, for at eders Forfølgere ikke skal træffe eder, og hold eder skjult der i tre Dage, indtil eders Forfølgere er vendt tilbage; efter den Tid kan I gaa eders Vej!«
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 Mændene sagde til hende: »Paa denne Maade vil vi bære os ad med at holde den Ed, du har ladet os sværge:
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 Naar vi kommer ind i Landet, skal du binde denne røde Snor fast i det Vindue, du har hejst os ned igennem, og saa skal du samle din Fader og din Moder, dine Brødre og hele dit Fædrenehus hos dig i Huset.
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 Enhver, som saa gaar uden for din Husdør, maa selv tage Ansvaret for sit Liv, uden at der falder Skyld paa os; men hvis der lægges Haand paa nogen af dem, som bliver i Huset hos dig, hviler Ansvaret paa os.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 Hvis du derimod røber vort Forehavende, er vi løst fra den Ed, du lod os sværge!«
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 Da sagde hun: »Lad det være, som I siger!« Saa lod hun dem drage bort; og hun bandt den røde Snor fast i Vinduet.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 Men de begav sig ud i Bjergene og blev der i tre Dage, indtil deres Forfølgere var vendt tilbage. Og Forfølgerne ledte overalt paa Vejen uden at finde dem.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 Derpaa begav de to Mænd sig paa Tilbagevejen, og efter at være steget ned fra Bjergene gik de over Floden; og de kom til Josua, Nuns Søn, og fortalte ham alt, hvad der var hændet dem.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 Og de sagde til Josua: »HERREN har givet hele Landet i vor Magt, og alle Landets Indbyggere er skrækslagne over os!«
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”

< Josua 2 >