< Jeremias 44 >

1 Det Ord, som kom til Jeremias om alle de Judæere, der boede i Ægypten, i Migdol, Takpankes, Nof og Patros:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
2 Saa siger Hærskarers HERRE, Israels Gud: I saa selv al den Ulykke, jeg bragte over Jerusalem og alle Judas Byer; se, de ligger nu øde hen, og ingen bor i dem;
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
3 det er Straf for det onde, de gjorde, idet de krænkede mig ved at gaa hen og tænde Offerild for og dyrke andre Guder, som hverken de eller deres Fædre før kendte til.
Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
4 Jeg sendte aarle og silde alle mine Tjenere Profeterne til dem, for at de skulde sige: »Gør dog ikke disse vederstyggelige Ting, som jeg hader!«
Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
5 Men de hørte ikke og bøjede ikke deres Øre dertil, saa de omvendte sig fra deres Ondskab og hørte op med at tænde Offerild for andre Guder.
Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
6 Derfor udgød min Vrede og Harme sig og luede op i Judas Byer og Jerusalems Gader, saa de blev til Ødemark og Ørk, som de er den Dag i Dag.
Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
7 Og nu, saa siger HERREN, Hærskarers Gud, Israels Gud: Hvorfor nedkalder I stor Ulykke over eder selv og udrydder Mænd og Kvinder, Børn og diende af Juda, saa I ikke levner eder nogen Rest,
“Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
8 idet I krænker mig med eders Hænders Værker og tænder Offerild for andre Guder i Ægypten, hvor I kom hen for at bo som fremmede? Følgen bliver, at I udrydder eder selv og bliver et Forbandelsens og Spottens Tegn blandt alle Jordens Folk.
Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
9 Har I glemt de onde Gerninger, eders Fædre og Judas Konger og Fyrster og eders Kvinder gjorde i Judas Land og paa Jerusalems Gader?
Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
10 Hidtil har de ikke ydmyget sig; de frygter ikke og vandrer ikke efter min Lov og mine Bud, som jeg forelagde eder og eders Fædre.
Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
11 Derfor, saa siger Hærskarers HERRE, Israels Gud: Se, jeg har ondt i Sinde imod eder; jeg vil udrydde hele Juda.
“Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
12 Og jeg tager Judas Rest, dem, som fik i Sinde at drage til Ægypten og bo der som fremmede; de skal alle omkomme i Ægypten; de skal falde for Sværd og Hunger og omkomme, store og smaa; for Sværd og Hunger skal de dø og blive et Edens, Rædselens, Forbandelsens og Spottens Tegn.
Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
13 Og jeg hjemsøger dem, der bor i Ægypten, som jeg hjemsøgte Jerusalem, med Sværd, Hunger og Pest.
Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
14 Og af Judas Rest, dem, der kom til Ægypten for at bo der som fremmede, skal ingen reddes eller undslippe, saa han kan vende hjem til Judas Land, hvor de længes efter at bo igen; nej, ingen skal vende hjem undtagen enkelte, som reddes.
Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
15 Men alle Mændene, der vel vidste, at deres Kvinder tændte Offerild for andre Guder, og alle Kvinderne, som stod der i en stor Klynge, og alt Folket, som boede i Ægypten, i Patros, svarede Jeremias:
Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
16 »Det Ord, du har talt til os i HERRENS Navn, vil vi ikke høre;
“Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
17 nej, vi vil opfylde hvert Løfte; som er udgaaet af vor Mund, og tænde Offerild for Himmelens Dronning og udgyde Drikofre for hende, som vi og vore Fædre, vore Konger og Fyrster gjorde det i Judas Byer og paa Jerusalems Gader. Dengang havde vi Brød nok og var lykkelige og kendte ikke til Ulykke;
Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
18 men fra den Stund vi hørte op med at tænde Offerild for Himmelens Dronning og udgyde Drikofre for hende, led vi Mangel paa alt og omkom ved Sværd og Hunger.
Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
19 Og naar vi tænder Offerild for Himmelens Dronning og udgyder Drikofre for hende, mon det saa er uden vore Mænds Vidende, at vi bager hende Offerkager, som afbilder hende, og udgyder Drikofre for hende?«
Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
20 Jeremias sagde til alt Folket, Mændene, Kvinderne og alt Folket, som havde svaret ham saaledes:
Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
21 »Mon ikke den Offerild, som I, eders Fædre, eders Konger og Fyrster og Landets Befolkning tændte i Judas Byer og paa Jerusalems Gader, randt HERREN i Hu og kom ham i Tanke?
“Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
22 HERREN kunde ikke mere holde det ud for eders onde Gerninger og de vederstyggelige Ting, I gjorde; derfor blev eders Land til Ørk, til et Rædselens og Forbandelsens Tegn, som det er den Dag i Dag.
Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
23 Fordi I tændte Offerild og syndede mod HERREN og ikke adlød HERRENS Røst eller fulgte hans Lov, Vedtægter og Vidnesbyrd, derfor ramtes I af denne Ulykke, som varer ved den Dag i Dag.«
Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
24 Og Jeremias sagde til alt Folket og alle Kvinderne: »Hør HERRENS Ord, hele Juda i Ægypten!
Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
25 Saa siger Hærskarers HERRE, Israels Gud: I og eders Kvinder lover med eders Mund og opfylder det med eders Hænder! I siger: Vi vil opfylde de Løfter, vi har aflagt, og tænde Offerild for Himmelens Dronning og udgyde Drikofre for hende. Saa hold da eders Løfter og indfri dem!
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
26 Men hør da ogsaa HERRENS Ord, alle I Judæere, som bor i Ægypten: Se, jeg sværger ved mit store Navn, siger HERREN: Ikke skal mere nogensteds i Ægypten mit Navn nævnes i nogen judæisk Mands Mund, saa han siger: Saa sandt den Herre HERREN lever!
Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
27 Se, jeg er aarvaagen over dem til Ulykke og ikke til Lykke, og hver judæisk Mand i Ægypten skal omkomme ved Sværd og Hunger, indtil de er udryddet.
Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
28 Kun de, der undslipper Sværdet, skal vende hjem fra Ægypten til Judas Land, et ringe Tal; og hele Judas Rest, der er kommet til Ægypten for at bo der som fremmede, skal kende, hvis Ord der staar fast, mit eller deres.
Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
29 Og dette, lyder det fra HERREN, skal være eder et Tegn paa, at jeg hjemsøger eder paa dette Sted, for at I skal kende, at mine Ord opfyldes paa eder til eders Ulykke:
“‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
30 Saa siger HERREN: Se, jeg giver Ægypterkongen Farao Hofra i hans Fjenders Haand og i deres Haand, som staar ham efter Livet, ligesom jeg gav Kong Zedekias af Juda i hans Fjende, Kong Nebukadrezar af Babels Haand, som stod ham efter Livet.«
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”

< Jeremias 44 >