< Jeremias 24 >

1 HERREN lod mig skue et Syn, og se, der var to Kurve Figener, som stod foran HERRENS Tempel; det var, efter at Kong Nebukadrezar af Babel havde bortført Jojakims Søn, Kong Jekonja af Juda, og Judas Fyrster, Kunsthaandværkerne og Smedene fra Jerusalem til Babel.
Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
2 Den ene Kurv indeholdt saare gode Figener, saa gode som tidligmodne, den anden saare slette Figener, saa slette, at de ikke kunde spises.
Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
3 Og HERREN sagde til mig: »Hvad ser du, Jeremias?« Jeg svarede: »Figener! De gode er saare gode og de slette saare slette, saa slette, at de ikke kan spises.«
Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
4 Da kom HERRENS Ord til mig saaledes:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
5 Saa siger HERREN, Israels Gud: Som man ser paa disse gode Figener, vil jeg se paa de bortførte Judæere, som jeg drev bort fra dette Sted til Kaldæernes Land.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
6 Jeg vil fæste mine Øjne paa dem med Velbehag og føre dem hjem til dette Land. Jeg vil opbygge og ikke nedbryde dem, plante og ikke oprykke dem.
Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
7 Jeg giver dem Hjerte til at kende mig, at jeg er HERREN; de skal være mit Folk, og jeg vil være deres Gud, naar de omvender sig til mig af hele deres Hjerte.
Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
8 Men som man gør med de slette Figener, for slette til at spises, vil jeg, saa siger HERREN, gøre med Kong Zedekias af Juda og hans Fyrster og Resten af Jerusalem, dem, der er levnet i dette Land, og dem, der bor i Ægypten;
“‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
9 jeg gør dem til Rædsel for alle Jordens Riger, til Spot og Mundheld, til Haan og til et Forbandelsens Tegn paa alle de Steder, hvorhen jeg bortstøder dem;
Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
10 jeg sender Sværd, Hunger og Pest imod dem, indtil de er udryddet af det Land, jeg gav dem og deres Fædre.
Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”

< Jeremias 24 >