< Jeremias 21 >

1 Det Ord, som kom til Jeremias fra HERREN, da Kong Zedekias sendte Pasjhur, Malkijas Søn, og Præsten Zefanja, Ma'asejas Søn, til ham og lod sige:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
2 »Raadspørg HERREN for os, thi Kong Nebukadrezar af Babel angriber os; maaske vil HERREN handle med os efter alle sine Undergerninger, saa Nebukadrezar drager bort fra os.«
“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 Jeremias svarede dem: »Sig til Zedekias:
Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
4 Saa siger HERREN, Israels Gud: Se, Vaabnene i eders Haand, med hvilke I uden for Muren kæmper mod Babels Konge og Kaldæerne, der belejrer eder, dem driver jeg tilbage og samler dem midt i denne By;
‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
5 og jeg vil selv kæmpe mod eder med udrakt Haand og stærk Arm, i Vrede og Harme og stor Fortørnelse;
Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
6 og jeg slaar denne Bys Indbyggere, ja baade Folk og Fæ, med voldsom Pest, saa de dør.
Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
7 Og siden, lyder det fra HERREN, giver jeg Kong Zedekias af Juda og hans Tjenere og Folket, der levnes i denne By af Pesten, Sværdet og Hungeren, i Kong Nebukadrezar af Babels og i deres Fjenders Haand, og i deres Haand, som staar dem efter Livet; de skal hugge dem ned med Sværdet, og jeg vil ikke ynkes over dem eller vise Skaansel eller Barmhjertighed!«
Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 Og sig til dette Folk: »Saa siger HERREN: Se, jeg forelægger eder Livets Vej og Dødens Vej.
“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
9 Den, som bliver i denne By, skal dø ved Sværd, Hunger og Pest; men den, som gaar ud og overgiver sig til Kaldæerne, der belejrer eder, skal leve og vinde sit Liv som Bytte,
Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
10 Thi jeg retter mit Aasyn mod denne By til Ulykke og ikke til Lykke, lyder det fra HERREN; i Babels Konges Haand skal den gives, og han skal opbrænde den med Ild.«
Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 Og sig til Judas Konges Hus: Hør HERRENS Ord,
“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Davids Hus! Saa siger HERREN: Hold aarle retfærdig Dom, fri den, som er plyndret, af Voldsmandens Haand, at ikke min Vrede slaar ud som Ild og brænder, saa ingen kan slukke, for eders onde Gerningers Skyld.
Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Se, jeg kommer over dig, du By i Dalen, du Slettens Klippe, lyder det fra HERREN, I, som siger: »Hvo falder over os, hvo trænger ind i vore Boliger?«
Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Efter eders Gerningers Frugt hjemsøger jeg jer, lyder det fra HERREN; jeg sætter Ild paa dens Skov, den fortærer alt deromkring.
Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”

< Jeremias 21 >