< Esajas 11 >

1 Men der skyder en Kvist af Isajs Stub, et Skud gror frem af hans Rod;
Èèkàn kan yóò sọ láti ibi kùkùté Jese, láti ara gbòǹgbò rẹ̀ ni ẹ̀ka kan yóò ti so èso.
2 og HERRENS Aand skal hvile over ham, Visdoms og Forstands Aand, Raads og Styrkes Aand, HERRENS Kundskabs og Frygts Aand.
Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé e, ẹ̀mí ọgbọ́n àti ti òye, ẹ̀mí ìmọ̀ràn àti ti agbára, ẹ̀mí ìmọ̀ àti ti ìbẹ̀rù Olúwa.
3 Hans Hu staar til HERRENS Frygt; han dømmer ej efter, hvad Øjnene ser, skønner ej efter, hvad Ørene hører.
Òun yóò sì ní inú dídùn nínú ìbẹ̀rù Olúwa. Òun kì yóò ṣe ìdájọ́ pẹ̀lú ohun tí ó fi ojú u rẹ̀ rí, tàbí pẹ̀lú ohun tí ó fi etí i rẹ̀ gbọ́,
4 Han dømmer de ringe med Retfærd, fælder redelig Dom over Landets arme. Voldsmanden slaar han med Mundens Ris, gudløse dræber han med Læbernes Aande.
ṣùgbọ́n pẹ̀lú òdodo ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní, pẹ̀lú òtítọ́ ni yóò ṣe ìpinnu fún àwọn aláìní ayé. Òun yóò lu ayé pẹ̀lú ọ̀pá tí ó wà ní ẹnu rẹ̀, pẹ̀lú èémí ẹnu rẹ̀ ni yóò pa àwọn ìkà.
5 Og Retfærd er Bæltet, han har om sin Lænd, Trofasthed Hofternes Bælte.
Òdodo ni yóò jẹ́ ìgbànú rẹ̀ àti òtítọ́ ni yóò ṣe ọ̀já yí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ká.
6 Og Ulven skal gaa hos Lammet, Panteren hvile hos Kiddet, Kalven og Ungløven græsse sammen, dem driver en lille Dreng.
Ìkookò yóò sì máa bá ọmọ àgùntàn gbé, ẹkùn yóò sì sùn ti ewúrẹ́ ọmọ màlúù òun ọmọ kìnnìún àti ọmọ ẹran ó wà papọ̀ ọ̀dọ́mọdé yóò sì máa dà wọ́n.
7 Kvien og Bjørnen bliver Venner, deres Unger ligger Side om Side, og Løven æder Straa som Oksen;
Màlúù àti beari yóò máa jẹun pọ̀, àwọn ọmọ wọn yóò dùbúlẹ̀ pọ̀, kìnnìún yóò sì máa jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù.
8 den spæde skal lege ved Øglens Hul, den afvante række sin Haand til Giftslangens Rede.
Ọ̀dọ́mọdé yóò ṣeré lẹ́bàá ihò ọká, ọmọdé yóò ki ọwọ́ rẹ̀ bọ ìtẹ́ paramọ́lẹ̀.
9 Der gøres ej ondt og voldes ej Men i hele mit hellige Bjergland; thi Landet er fuldt af HERRENS Kundskab, som Vandene dækker Havets Bund.
Wọn kò ní ṣe ni léṣe tàbí pa ni run ní gbogbo òkè mímọ́ mi, nítorí gbogbo ayé yóò kún fún ìmọ̀ Olúwa gẹ́gẹ́ bí omi ti bo Òkun.
10 Paa hin Dag skal Hedningerne søge til Isajs Rodskud, der staar som et Banner for Folkeslagene, og hans Bolig skal være herlig.
Ní ọjọ́ náà, gbòǹgbò Jese yóò dúró gẹ́gẹ́ bí àsíá fún gbogbo ènìyàn, àwọn orílẹ̀-èdè yóò pagbo yí i ká, ibùdó ìsinmi rẹ̀ yóò jẹ́ èyí tí ó lógo.
11 Paa hin Dag skal Herren atter udrække sin Haand for at vinde, hvad der er til Rest af hans Folk, fra Assur og fra Ægypten, fra Patros, Ætiopien og Elam, fra Sinear, Hamat og Havets Strande.
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò na ọwọ́ rẹ̀ jáde nígbà kejì láti tún gba àwọn tí ó ṣẹ́kù àní àwọn tí a ṣẹ́kù nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ láti Asiria wá, láti ìsàlẹ̀ Ejibiti àti òkè Ejibiti, láti Kuṣi, láti Elamu láti Babiloni, láti Hamati àti láti àwọn erékùṣù inú Òkun.
12 For Folkene rejser han Banner, samler Israels bortdrevne Mænd, sanker Judas spredte Kvinder fra Verdens fire Hjørner.
Òun yóò gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì kó àwọn ìgbèkùn Israẹli jọ, yóò kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí a ti fọ́n káàkiri jọ, láti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ ayé.
13 Efraims Skinsyge viger, og Judas Avind svinder; Efraim er ikke skinsygt paa Juda, og Juda bærer ej Avind mod Efraim.
Owú jíjẹ Efraimu yóò pòórá, àwọn ọ̀tá Juda ni a ó ké kúrò, Efraimu kò ní jowú Juda, tàbí Juda kó dojúkọ Efraimu.
14 I Vest slaar de ned paa Filisternes Skulder, sammen plyndrer de Østens Sønner, mod Edom og Moab rækker de Haanden, Ammons Sønner lyder dem.
Wọn yóò fò mọ́ èjìká Filistini sí apá ìwọ̀-oòrùn, wọn yóò pawọ́pọ̀ kọlu àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn. Wọn yóò gbé ọwọ́ wọn lé Edomu àti Moabu, àwọn ará Ammoni yóò sì di ìwẹ̀fà wọn.
15 HERREN udtørrer Ægypterhavets Vig og svinger Haanden mod Floden i sin Aands Vælde; han kløver den i syv Bække, saa man kan gaa over med Sko;
Olúwa yóò sọ di gbígbé àyasí Òkun Ejibiti, pẹ̀lú atẹ́gùn gbígbóná ni yóò na ọwọ́ rẹ̀, kọjá lórí odò Eufurate. Òun yóò sì sọ ọ́ di ọmọdò méje tó fi jẹ́ pé àwọn ènìyàn yóò máa là á kọjá pẹ̀lú bàtà.
16 der bliver en banet Vej for dem af hans Folk, som levnes fra Assyrien, saaledes som der var for Israel, da det drog op fra Ægypten.
Ọ̀nà gidi yóò wà fún àwọn ènìyàn an rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù tí ó kù sílẹ̀ ní Asiria, gẹ́gẹ́ bí ó ti wà fún Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè láti Ejibiti wá.

< Esajas 11 >