< 1 Mosebog 15 >

1 Nogen Tid efter kom HERRENS Ord til Abram i et Syn saaledes: »Frygt ikke, Abram, jeg er dit Skjold; din Løn skal blive saare stor!«
Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé, “Abramu má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ààbò rẹ, Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”
2 Men Abram svarede: »Herre, HERRE, hvad kan du give mig, naar jeg dog gaar barnløs bort, og en Mand fra Damaskus, Eliezer, skal arve mit Hus.«
Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,”
3 Og Abram sagde: »Du har jo intet Afkom givet mig, og se, min Hustræl kommer til at arve mig!«
Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”
4 Og se, HERRENS Ord kom til ham saaledes: »Han kommer ikke til at arve dig, men den, der udgaar af dit Liv, han skal arve dig.«
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé, “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnra rẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.”
5 Derpaa førte han ham ud i det fri og sagde: »Se op mod Himmelen og prøv, om du kan tælle Stjernerne!« Og han sagde til ham: »Saaledes skal dit Afkom blive!«
Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”
6 Da troede Abram HERREN, og han regnede ham det til Retfærdighed.
Abramu gba Olúwa gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
7 Derpaa sagde han til ham: »Jeg er HERREN, som førte dig bort fra Ur-Kasdim for at give dig dette Land i Eje!«
Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”
8 Men han svarede: »Herre, HERRE, hvorpaa kan jeg kende, at jeg skal faa det i Eje?«
Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”
9 Da sagde han til ham: »Tag mig en treaars Kvie, en treaars Ged og en treaars Væder, en Turteldue og en Smaafugl!«
Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”
10 Saa tog han alle disse Dyr skar dem midt over og lagde Halvdelene over for hinanden; dog skar han ikke Fuglene over.
Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn.
11 Da slog der Rovfugle ned paa de døde Kroppe, men Abram skræmmede dem bort.
Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.
12 Da Solen saa var ved at gaa ned, faldt der Dvale over Abram, og se, Rædsel faldt over ham, et stort Mørke.
Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó.
13 Og han sagde til Abram: »Vide skal du, at dit Afkom skal bo som fremmede i et Land, der ikke er deres eget; de skal trælle for dem og mishandles af dem i 400 Aar.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
14 Dog vil jeg ogsaa dømme det Folk, de kommer til at trælle for, og siden skal de vandre ud med meget Gods.
Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀.
15 Men du skal fare til dine Fædre i Fred og blive jordet i en god Alderdom.
Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin.
16 I fjerde Slægtled skal de vende tilbage hertil; thi endnu er Amoriternes Syndeskyld ikke fuldmoden.«
Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òsùwọ̀n.”
17 Da Solen var gaaet ned og Mørket faldet paa, viste der sig en rygende Ovn med en flammende Ildslue, der skred frem mellem de sønderskaarne Kroppe.
Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà.
18 Paa den Dag sluttede HERREN Pagt med Abram, idet han sagde: »Dit Afkom giver jeg dette Land fra Ægyptens Bæk til den store Flod, Eufratfloden,
Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate:
19 det er Keniterne, Kenizziterne, Kadmoniterne,
ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni,
20 Hetiterne, Perizziterne, Refaiterne,
àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu.
21 Amoriterne, Kana'anæerne, Girgasjiterne, Hivviterne og Jebusiterne.«
Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”

< 1 Mosebog 15 >