< 1 Mosebog 14 >

1 Dengang Amrafel var Konge i Sinear, Arjok i Ellasar, Kedorlaomer i Elam og Tid'al i Gojim,
Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
2 laa de i Krig med Kong Bera af Sodoma, Kong Birsja af Gomorra, Kong Sjin'ab af Adma, Kong Sjem'eber af Zebojim og Kongen i Bela, det et Zoar.
jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
3 Alle disse havde slaaet sig sammen og var rykket frem til Siddims Dal, det er Salthavet.
Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
4 I tolv Aar havde de staaet under Kedorlaomer, men i det trettende faldt de fra;
Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
5 og i det fjortende Aar kom Kedorlaomer og de Konger, som fulgte ham. Først slog de Refaiterne i Asjtarot-Karnajim, Zuziterne i Ham, Emiterne i Sjave-Kirjatajim
Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
6 og Horiterne i Se'irs Bjerge hen ad El-Paran til ved Ørkenens Rand;
àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
7 saa vendte de om og drog til Misjpatkilden, det er Kadesj, og slog Amalekiterne i hele deres Omraade og ligesaa de Amoriter, der boede i Hazazon-Tamar.
Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
8 Da drog Sodomas, Gomorras, Admas, Zebojims og Belas, det er Zoars, Konger ud og indlod sig i Siddims Dal i Kamp
Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
9 med Kong Kedorlaomer af Elam, Kong Tid'al af Gojim, Kong Amrafel af Sinear og Kong Arjok af Ellasar, fire Konger mod fem.
láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
10 Men Siddims Dal var fuld af Jordbeggruber; og da Sodomas og Gomorras Konger blev slaaet paa Flugt, styrtede de i dem, medens de, der blev tilbage, flyede op i Bjergene.
Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
11 Saa tog Fjenden alt Godset i Sodoma og Gomorra og alle Levnedsmidlerne og drog bort;
Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
12 ligeledes tog de, da de drog bort, Abrams Brodersøn Lot og alt hans Gods med sig; thi han boede i Sodoma.
Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
13 Men en Flygtning kom og meldte det til Hebræeren Abram, der boede ved den Lund, som tilhørte Amoriten Mamre, en Broder til Esjkol og Aner, der ligesom han var Abrams Pagtsfæller.
Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
14 Da nu Abram hørte, at hans Frænde var taget til Fange, mønstrede han sine Husfolk, de hjemmefødte Trælle, 318 Mand, og satte efter Fjenden til Dan;
Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
15 der faldt han og hans Trælle over dem om Natten, slog dem paa Flugt og forfulgte dem op til Hoba norden for Damaskus.
Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
16 Derefter bragte han alt Godset tilbage; ogsaa sin Frænde Lot og hans Gods førte han tilbage og ligeledes Kvinderne og Folket.
Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
17 Da han nu kom tilbage fra Sejren over Kedorlaomer og de Konger, der fulgte ham, gik Sodomas Konge ham i Møde i Sjavedalen, det er Kongedalen.
Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
18 Men Salems Konge Melkizedek, Gud den Allerhøjestes Præst, bragte Brød og Vin
Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
19 og velsignede ham med de Ord: »Priset være Abram for Gud den Allerhøjeste, Himmelens og Jordens Skaber,
Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
20 og priset være Gud den Allerhøjeste, der gav dine Fjender i din Haand!« Og Abram gav ham Tiende af alt.
Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
21 Sodomas Konge sagde derpaa til Abram: »Giv mig Menneskene og behold selv Godset!«
Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
22 Men Abram svarede Sodomas Konge: »Til HERREN, Gud den Allerhøjeste, Himmelens og Jordens Skaber, løfter jeg min Haand paa,
Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
23 at jeg ikke vil tage saa meget som en Traad eller en Sandalrem eller overhovedet noget som helst af din Ejendom; du skal ikke sige, at du har gjort Abram rig!
pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
24 Jeg vil intet have — kun hvad de unge Mænd har fortæret, og mine Ledsagere, Aner, Esjkol og Mamres Del, lad dem faa deres Del!«
Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”

< 1 Mosebog 14 >