< Ezra 9 >

1 Men da alt dette var gjort, kom Øversterne til mig og sagde: »Folket, Israel og Præsterne og Leviterne, har ikke skilt sig ud fra Hedningerne eller fra deres Vederstyggeligheder, Kana'anæerne, Hetiterne, Perizziterne, Jebusiterne, Ammoniterne, Moabiterne, Ægypterne og Amoriterne;
Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tán, àwọn olórí tọ̀ mí wá, wọ́n sì wí pé, “Àwọn ènìyàn Israẹli, tí ó fi mọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, kò tì í ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn agbègbè tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra bí i ti àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Jebusi, àwọn ará Ammoni, àwọn ará Moabu, àwọn ará Ejibiti àti ti àwọn ará Amori.
2 thi af deres Døtre har de taget sig selv og deres Sønner Hustruer, saa at den hellige Sæd har blandet sig med Hedningerne; og Øversterne og Forstanderne var de første til at øve denne Troløshed!«
Wọ́n ti fẹ́ lára àwọn ọmọbìnrin wọn fún ara wọn àti fún àwọn ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí aya, wọ́n ti da irú-ọmọ ìran mímọ́ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn ti ó wà ní àyíká wọn. Àwọn olórí àti àwọn ìjòyè ta àwọn ènìyàn tókù yọ nínú híhu ìwà àìṣòótọ́.”
3 Da jeg hørte den Tale, sønderrev jeg min Kjortel og min Kappe, rev Haar af mit Hoved og Skæg og satte mig hen i stum Smerte.
Nígbà tí mo gbọ́ èyí, mo fa àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi ya, mo tu irun orí àti irùngbọ̀n mi, mo sì jókòó ní ìjayà.
4 Da samlede sig omkring mig alle de, der bævede for Israels Guds Ord mod Troløsheden hos dem, der havde været i Landflygtighed; og jeg sad i stum Smerte til Aftenafgrødeofferets Tid.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn tí ó wárìrì sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Israẹli kó ara wọn jọ yí mi ká nítorí àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn yìí. Èmi sì jókòó níbẹ̀ ní ìjayà títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́.
5 Men ved Aftenafgrødeofferets Tid rejste jeg mig af min Selvydmygelse, og idet jeg sønderrev min Kjortel og min Kappe, kastede jeg mig paa Knæ og udbredte Hænderne til, HERREN min Gud
Ní ìgbà tí ó di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, mo dìde kúrò nínú ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn mi, pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi yíya ní ọrùn mi, mo kúnlẹ̀ lórí eékún mi méjèèjì, mo sì tẹ́ ọwọ́ mi méjèèjì sí Olúwa Ọlọ́run mi.
6 og sagde: »Min Gud, jeg skammer mig og blues ved at løfte mit Ansigt til dig, min Gud, thi vore Misgerninger er vokset os over Hovedet, og vor Skyld er saa stor, at den rækker til Himmelen!
Mo sì gbàdúrà: “Ojú tì mí gidigidi, tí n kò fi lè gbé ojú mi sókè sí ọ̀dọ̀ rẹ, Ọlọ́run mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá di púpọ̀ ní orí wa, ẹ̀bi wa sì ga kan àwọn ọ̀run.
7 Fra vore Fædres Tid indtil denne Dag har vor Skyld været stor, og for vore Misgerninger blev vi, vore Konger og Præster givet til Pris for Landenes Konger, for Sværd, Fangenskab, Udplyndring og Vanære, saaledes som det er den Dag i Dag.
Láti ọjọ́ àwọn baba wá ni ẹ̀bi wa ti pọ̀ jọjọ títí di ìsinsin yìí. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, àwa àti àwọn ọba wa àti àwọn àlùfáà wa ni a ti sọ di ẹni idà, ẹni ìgbèkùn, ìkógun àti ẹni ẹ̀sín lọ́wọ́ àwọn àjèjì ọba, bí ó ti rí lónìí.
8 Og nu er der en føje Stund blevet os Naade til Del fra HERREN vor Gud, idet han har ladet os beholde en undsluppet Rest og givet os at slaa vor Teltpæl paa sit hellige Sted, for at vor Gud kan lade vore Øjne lyse og give os en Smule Livskraft i vor Trældom;
“Ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí, fún ìgbà díẹ̀, ni a ti fi oore-ọ̀fẹ́ fún wa láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa wá láti sálà, àti láti fi èèkàn fún wa ni ibi mímọ́ rẹ̀, nítorí kí Ọlọ́run kí ó lè mú ojú wa mọ́lẹ̀, kí ó sì tún wa gbé dìde díẹ̀ kúrò nínú ìgbèkùn wa.
9 thi er vi end Trælle, har vor Gud dog ikke forladt os i vor Trældom, men vundet os Naade for Perserkongernes Aasyn, saa at han har givet os Livskraft til at rejse vor Guds Hus og opbygge dets Grushobe og givet os et Gærde i Juda og Jerusalem.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwa jẹ́ ẹrú, Ọlọ́run wa kò fi wa sílẹ̀ nínú ìgbèkùn wa. Ó ti fi àánú hàn fún wa ni iwájú àwọn ọba Persia: Ó ti fún wa ní ìgbé ayé tuntun láti tún odi ilé Ọlọ́run wa mọ, kí a sì tún àwókù rẹ̀ ṣe, ó sì fi odi ààbò fún wa ní Juda àti ní Jerusalẹmu.
10 Men hvad skal vi nu sige, vor Gud, efter alt dette? Vi har jo forladt dine Bud,
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, kí ni àwa yóò wí lẹ́yìn èyí? Nítorí tí àwa kọ àṣẹ rẹ sílẹ̀
11 som du gav os ved dine Tjenere Profeterne, da du sagde: Det Land, I drager ind i og tager i Besiddelse, er et urent Land paa Grund af Hedningernes Urenhed, paa Grund af de Vederstyggeligheder, de i deres Urenhed har fyldt det med fra Ende til anden;
èyí tí ìwọ ti pa fún wa láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, nígbà ti ìwọ wí pé, ‘Ilẹ̀ náà ti ẹ̀yin ń wọ̀ lọ láti gbà n nì jẹ́ ilẹ̀ aláìmọ́ tó kún fún ẹ̀gbin àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, nípa ṣíṣe ohun ìríra àti híhu ìwà èérí ti kún ún láti ìkángun kan dé èkejì.
12 derfor maa I ikke give deres Sønner eders Døtre eller tage deres Døtre til Hustruer for eders Sønner og ingen Sinde søge deres Velfærd og Lykke, at I kan blive stærke og nyde Landets Goder og sikre eders Sønner Besiddelsen deraf for evigt!
Nítorí náà, ẹ má ṣe fi àwọn ọmọbìnrin yín fún àwọn ọmọkùnrin wọn ní ìyàwó tàbí kí ẹ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó. Ẹ má ṣe dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn nígbàkígbà kí ẹ̀yin kí ó sì le lágbára, kí ẹ sì le máa jẹ ire ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le fi í sílẹ̀ fún àwọn ọmọ yín gẹ́gẹ́ bí ogún ayérayé.’
13 Efter alt, hvad der er vederfaret os paa Grund af vore onde Gerninger og vor svare Skyld — og endda har du vor Gud ikke i fuldt Maal tilregnet os vore Synder, men skænket os en saadan Flok undslupne —
“Ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa jẹ́ àyọríṣí iṣẹ́ búburú wa àti ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá wa, síbẹ̀, Ọlọ́run wa, ìjìyà ti ìwọ fún wa kéré si ìjìyà tí ó yẹ fún ẹ̀ṣẹ̀ ti a dá, ìwọ sì fún wa ní àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù bí èyí.
14 skal vi da paa ny krænke dine Bud ved at besvogre os med Folk, der øver slige Vederstyggeligheder? Vil du da ikke vredes saaledes paa os, at du ødelægger os aldeles, saa der ikke levnes nogen Rest, og ingen undslipper?
Ǹjẹ́ ó yẹ kí àwa tún yẹ̀ kúrò nínú àṣẹ rẹ, kí a sì máa ṣe ìgbéyàwó papọ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọn ti ṣe onírúurú ohun ìríra báyìí? Ṣe ìwọ kò ní bínú sí wa láti pa wá run tí kì yóò sẹ́ ku ẹnikẹ́ni tí yóò là?
15 HERRE, Israels Gud! Du er retfærdig, derfor er vi nu en Rest tilbage, som er undsluppet; se, vi staar for dig i vor Syndeskyld; thi det er umuligt at bestaa for dit Aasyn, naar sligt kan ske!«
Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ìwọ jẹ́ olódodo! Àwa ìgbèkùn tí ó ṣẹ́kù bí ó ti rí lónìí. Àwa dúró níwájú rẹ nínú ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nítorí èyí ẹnikẹ́ni nínú wa kò lè dúró níwájú rẹ”.

< Ezra 9 >