< Ezekiel 35 >
1 HERRENS Ord kom til mig saaledes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Menneskesøn, vend dit Ansigt mod Se'irs Bjergland og profeter imod det
“Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
3 og sig til det: Saa siger den Herre HERREN: Se, jeg kommer over dig, Se'irs Bjergland, og løfter min Haand imod dig; jeg gør dig til Ørk og Ødemark,
kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
4 dine Byer lægger jeg i Grus. Du selv skal blive til Ørk og kende, at jeg er HERREN.
Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
5 Fordi du nærede evigt Had og i Nødens Stund overgav Israeliterne til Sværdet, da deres Misgerning var fuldmoden,
“‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
6 derfor, saa sandt jeg lever, lyder det fra den Herre HERREN: Jeg gør dig til Blod, og Blod skal forfølge dig; sandelig, du forbrød dig ved Blod, og Blod skal forfølge dig.
nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
7 Jeg gør Se'irs Bjergland til Ørk og Ødemark og udrydder deraf enhver, som kommer og gaar;
Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
8 jeg fylder dets Bjerge med dræbte; paa dine Høje og i dine Dale og Kløfter skal de sværdslagne falde.
Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
9 Jeg gør dig til Ørk for evigt, dine Byer skal ikke bebos; og du skal kende, at jeg er HERREN.
Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
10 Fordi du sagde: »De tvende Folk og de tvende Lande skal tilhøre mig, jeg vil tage dem i Eje!« skønt HERREN var der,
“‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
11 derfor, saa sandt jeg lever, lyder det fra den Herre HERREN: Jeg vil gøre med dig efter den Vrede og det Nid, du hadefuldt udviste imod dem, og jeg vil give mig til Hende for dig, naar jeg dømmer dig;
nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
12 og du skal kende, at jeg er HERREN. Jeg har hørt al den Spot, du udslyngede mod Israels Bjerge: »De er ødelagt, os er de givet til Føde!«
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
13 Du gjorde dig stor imod mig med din Mund og overfusede mig med Ord; jeg hørte det.
Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
14 Saa siger den Herre HERREN: Som det var din Glæde, at mit Land blev Ørk, saaledes vil jeg gøre med dig;
Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
15 som det var din Glæde, at Israels Hus's Arvelod blev Ørk, saaledes vil jeg gøre med dig. Ørk skal du blive, Se'irs Bjergland og hele Edom med; og de skal kende, at jeg er HERREN.
Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”