< Ezekiel 25 >

1 HERRENS Ord kom til mig saaledes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Menneskesøn, vend dit Ansigt imod Ammoniterne, profeter imod dem
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
3 og sig til dem: Hør den Herre HERRENS Ord: Saa siger den Herre HERREN: Fordi du raabte »Ha, ha!« over min Helligdom, da den vanhelligedes, og over Israels Land, da det lagdes øde, og over Judas Hus, da de vandrede i Landflygtighed,
Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
4 se, derfor giver jeg dig i Eje til Østens Sønner; de skal opslaa deres Teltlejre og indrette deres Boliger i dig; de skal spise din Frugt og drikke din Mælk.
kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
5 Jeg gør Rabba til Græsgang for Kameler og Ammons Byer til Lejrsted for Smaakvæg; og I skal kende, at jeg er HERREN.
Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 Thi saa siger den Herre HERREN: Fordi du klappede i Hænderne og stampede med Fødderne og med dyb Ringeagt godtede dig af Hjertet over Israels Land,
Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
7 se, derfor udrækker jeg Haanden imod dig og gør dig til Rov for Folkene; jeg udrydder dig af Folkeslagene, udsletter dig af Landene og tilintetgør dig; og du skal kende, at jeg er HERREN.
nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
8 Saa siger den Herre HERREN: Fordi Moab siger: »Se, det er med Judas Hus som med alle de andre Folk!«
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
9 se, derfor lægger jeg Moabs Skrænter aabne, saa Byerne gaar tabt fra dets ene Ende til den anden, Landets Pryd, Bet-Jesjimot, Ba'al-Meon og Kirjatajim.
nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
10 Østens Sønner giver jeg det i Eje, for at det ikke mere skal ihukommes blandt Folkene.
Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
11 Jeg holder Dom over Moab; og de skal kende, at jeg er HERREN.
Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
12 Saa siger den Herre HERREN: Fordi Edom optraadte hævngerrigt mod Judas Hus og paadrog sig svar Skyld ved at hævne sig paa dem,
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
13 derfor, saa siger den Herre HERREN: Jeg udrækker Haanden mod Edom og udrydder Folk og Fæ deraf og gør det øde; fra Teman til Dedan skal de falde for Sværdet.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
14 Jeg fuldbyrder min Hævn paa Edom ved mit Folk Israels Haand, og de skal handle med Edom efter min Vrede og Harme, og Edom skal kende min Hævn, lyder det fra den Herre HERREN.
Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Saa siger den Herre HERREN: Fordi Filisterne optraadte hævngerrigt og med Foragt i Hjertet tog Hævn og hærgede i endeløst Had,
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
16 derfor, saa siger den Herre HERREN: Se, jeg udrækker Haanden mod Filisterne og udrydder Kreterne, og jeg tilintetgør, hvad der er levnet ved Havets Strand.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
17 Jeg tager vældig Hævn over dem og revser dem i Vrede; og de skal kende, at jeg er HERREN, naar jeg fuldbyrder min Hævn paa dem.
Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”

< Ezekiel 25 >