< 2 Mosebog 23 >

1 Du maa ikke udsprede falske Rygter. Gør ikke fælles Sag med den, der har Uret, ved at optræde som uretfærdigt Vidne.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀. Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.
2 Du maa ikke følge Mængden i, hvad der er ondt, eller i dit Vidnesbyrd for Retten tage Hensyn til Mængden, saa du bøjer Retten.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn.
3 Du maa ikke tage Parti for den ringe i hans Retssag.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.
4 Naar du træffer din Fjendes Okse eller Æsel løbende løse, skal du bringe dem tilbage til ham.
“Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.
5 Naar du ser din Uvens Æsel segne under sin Byrde, maa du ikke lade ham i Stikken, men du skal hjælpe ham med at læsse Byrden af.
Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.
6 Du maa ikke bøje din fattige Landsmands Ret i hans Retssag.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.
7 Hold dig fra en uretfærdig Sag; og den, som er uskyldig og har Ret, maa du ikke berøve Livet; nej, du maa ikke skaffe den Ret, som har Uret.
Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.
8 Tag ikke mod Bestikkelse, thi Bestikkelse gør den seende blind og fordrejer Sagen for dem, der har Ret.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
9 Undertryk ikke den fremmede; I ved jo, hvorledes den fremmede er til Mode, thi I var selv fremmede i Ægypten.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.
10 Seks Aar igennem skal du tilsaa dit Land og indsamle dets Afgrøde;
“Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀.
11 men i det syvende skal du lade det hvile og ligge urørt, saa at de fattige i dit Folk kan gøre sig til gode dermed, og Markens vilde Dyr kan æde, hvad de levner; ligesaa skal du gøre med din Vingaard og dine Oliventræer.
Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.
12 I seks Dage skal du gøre dit Arbejde, men paa den syvende skal du hvile, for at dine Okser og Æsler kan faa Hvile og din Trælkvindes Søn og den fremmede hvile ud.
“Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.
13 Hold eder alt, hvad jeg siger eder, efterrettelig; du maa ikke nævne andre Guders Navn, det maa ikke høres i din Mund.
“Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.
14 Tre Gange om Aaret skal du holde Højtid for mig.
“Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.
15 Du skal fejre de usyrede Brøds Højtid; i syv Dage skal du spise usyret Brød, som jeg har paalagt dig, paa den fastsatte Tid i Abib Maaned, thi i den Maaned vandrede du ud af Ægypten, Man maa ikke stedes for mit Aasyn med tomme Hænder.
“Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.
16 Fremdeles skal du fejre Højtiden for Høsten, Førstegrøden af dit Arbejde, af hvad du saar i din Mark, og Højtiden for Frugthøsten ved Aarets Udgang, naar du har bjærget Udbyttet af dit Arbejde hjem fra Marken.
“Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ. “Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.
17 Tre Gange om Aaret skal alle dine Mænd stedes for den Herre HERRENS Aasyn.
“Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.
18 Du maa ikke ofre Blodet af mit Slagtoffer sammen med syret Brød. Fedtet fra min Højtid maa ikke gemmes til næste Morgen.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà. “Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.
19 Du skal bringe det første, Førstegrøden af din Jord, til HERREN din Guds Hus. Du maa ikke koge et Kid i dets Moders Mælk.
“Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.
20 Se, jeg sender en Engel foran dig for at vogte dig undervejs og føre dig til det Sted, jeg har beredt.
“Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún.
21 Tag dig vel i Vare for ham og adlyd ham; vær ikke genstridig imod ham, thi han skal ikke tilgive eders Overtrædelser, efterdi mit Navn er i ham.
Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀.
22 Naar du adlyder ham og gør alt, hvad jeg siger, vil jeg være dine Fjenders Fjende og dine Modstanderes Modstander,
Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín.
23 Ja, min Engel skal drage foran dig og føre dig til Amoriterne, Hetiterne, Perizziterne, Kana'anæerne, Hivviterne og Jebusiterne, og jeg vil udrydde dem.
Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò.
24 Du maa ikke tilbede eller dyrke deres Guder eller følge deres Skikke; men du skal nedbryde dem og sønderslaa deres Stenstøtter.
Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú.
25 I skal dyrke HERREN eders Gud, saa vil jeg velsigne dit Brød og dit Vand og holde Sygdomme borte fra dig.
Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ.
26 Utidige Fødsler eller Ufrugtbarhed skal ikke forekomme i dit Land, og dine Dages Maal vil jeg gøre fuldt.
Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.
27 Jeg vil sende min Rædsel foran dig og bringe Bestyrtelse over alle de Folk, du kommer til, og jeg vil drive alle dine Fjender paa Flugt for dig.
“Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ.
28 Jeg vil sende Gedehamse foran dig, og de skal drive Hivviterne, Kana'anæerne og Hetiterne bort foran dig.
Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ.
29 Men jeg vil ikke drive dem bort foran dig i et og samme Aar, for at Landet ikke skal lægges øde, og for at Markens vilde Dyr ikke skal tage Overhaand for dig;
Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ.
30 lidt efter lidt vil jeg drive dem bort foran dig, indtil du bliver saa talrig, at du kan tage Landet i Besiddelse.
Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.
31 Jeg vil lade dine Landemærker naa fra det røde Hav til Filisternes Hav, fra Ørkenen til Floden, thi jeg giver Landets Indbyggere i eders Haand, saa du kan drive dem bort foran dig.
“Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun Pupa títí dé òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate, Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ.
32 Du maa ikke slutte Pagt med dem eller deres Guder.
Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn.
33 De maa ikke blive boende i dit Land, for at de ikke skal forlede dig til Synd imod mig, til at dyrke deres Guder, saa det bliver dig til en Snare!
Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”

< 2 Mosebog 23 >