< 5 Mosebog 31 >

1 Da Moses var færdig med at tale disse Ord til hele Israel,
Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
2 sagde han til dem: »Jeg er nu 120 Aar gammel og kan ikke mere færdes som før; og HERREN har sagt til mig: Du skal ikke komme over Jordan der!
“Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
3 Men HERREN din Gud vil selv drage over i Spidsen for dig, han vil udrydde disse Folkeslag for dig, saa du kan tage deres Land i Besiddelse. Og Josua skal drage over i Spidsen for dig, som HERREN har sagt.
Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
4 Og HERREN skal handle med dem, som han handlede med Amoriterkongerne Sihon og Og og med deres Land, som han ødelagde;
Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
5 og HERREN skal give dem i eders Magt, og I skal handle med dem i Overensstemmelse med alle de Bud, jeg gav eder.
Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
6 Vær frimodige og stærke, frygt ikke og forfærdes ikke for dem; thi HERREN din Gud vil selv drage med dig; han vil ikke slippe og ikke forlade dig!«
Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
7 Derpaa lod Moses Josua kalde og sagde til ham i hele Israels Nærværelse: »Vær frimodig og stærk; thi du skal føre dette Folk ind i det Land, HERREN svor at ville give deres Fædre, og give dem det i Eje.
Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
8 HERREN selv vil gaa foran dig, han vil være med dig og ikke slippe eller forlade dig; frygt derfor ikke og vær ikke bange!«
Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
9 Derpaa nedskrev Moses denne Lov og overgav den til Præsterne, Levis Sønner, der bar HERRENS Pagts Ark, og til alle Israels Ældste.
Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
10 Og Moses bød dem: »Hvergang der er gaaet syv Aar, i Friaaret, paa Løvhyttefesten,
Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
11 naar hele Israel kommer for at stedes for HERREN din Guds Aasyn paa det Sted, han udvælger, skal du læse denne Lov højt for hele Israel.
Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
12 Kald da Folket sammen, Mænd, Kvinder og Børn og de fremmede, som bor inden dine Porte, for at de kan høre og lære at frygte HERREN eders Gud og omhyggeligt handle efter alle denne Lovs Ord;
Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
13 og deres Børn, som endnu ikke har lært den at kende, skal høre den og lære at frygte HERREN eders Gud, alle de Dage I lever i det Land, som I skal ind og tage i Besiddelse efter at være gaaet over Jordan!«
Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
14 Derpaa sagde HERREN til Moses: »Nu nærmer Tiden sig, da du skal dø. Kald derfor Josua hid og stil eder i Aabenbaringsteltet, for at jeg kan give ham mine Befalinger!« Og Moses og Josua gik hen og stillede sig i Aabenbaringsteltet.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
15 Da aabenbarede HERREN sig i Teltet i en Skystøtte, og Skystøtten stillede sig ved Teltets Indgang.
Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
16 Derpaa sagde HERREN til Moses: »Naar du har lagt dig til Hvile hos dine Fædre, vil dette Folk give sig til at bole med fremmede Guder, det Lands Guder, det kommer til, og det vil forlade mig og bryde min Pagt, som jeg har sluttet med det.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
17 Men til den Tid skal min Vrede blusse op imod det, og jeg vil forlade dem og skjule mit Aasyn for dem; det skal ædes op, og mange Ulykker og Trængsler skal ramme det. Til den Tid skal det sige: Mon det ikke er, fordi min Gud ikke er i min Midte, at disse Ulykker har ramt mig?
Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
18 Og jeg vil til den Tid helt skjule mit Aasyn for det for alt det ondes Skyld, det øvede, da det vendte sig til fremmede Guder.
Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
19 Saa skriv nu denne Sang op, lær Israeliterne den og læg den i deres Mund, for at denne Sang kan være mit Vidne mod Israeliterne.
“Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
20 Thi jeg vil føre dem ind i det Land, jeg tilsvor deres Fædre, et Land, der flyder med Mælk og Honning; men naar det har spist sig mæt og mæsket sig, vil det vende sig til fremmede Guder og dyrke dem, og det vil ringeagte mig og bryde min Pagt.
Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
21 Naar da Ulykker og Trængsler i Mængde rammer det, skal denne Sang være det et Vidne; thi aldrig maa den dø paa dets Afkoms Læber. Jeg ved jo, hvad de pønser paa allerede nu, før jeg har ført dem ind i det Land, jeg tilsvor deres Fædre.«
Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
22 Da skrev Moses paa den Dag denne Sang op og lærte Israeliterne den.
Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
23 Derpaa bød han Josua, Nuns Søn, og sagde: »Vær frimodig og stærk; thi du skal føre Israeliterne ind i det Land, jeg tilsvor dem. Jeg vil være med dig!«
Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
24 Da Moses var færdig med at nedskrive denne Lovs Ord fra Ende til anden i en Bog,
Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
25 bød han Leviterne, der bar HERRENS Pagts Ark:
ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
26 »Tag denne Lovbog og læg den ved Siden af HERREN eders Guds Pagts Ark, for at den der kan være Vidne imod dig;
“Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
27 thi jeg keder din Genstridighed og Halsstarrighed. Se, endnu i mit levende Live har I været genstridige mod HERREN, hvor meget mere da ikke, naar jeg er død!
Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
28 Kald nu alle eders Stammers Ældste og eders Tilsynsmænd sammen hos mig, for at jeg kan fremsige disse Ord for dem og kalde Himmelen og Jorden til Vidne imod dem:
Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
29 Thi jeg ved, at naar jeg er død, vil I handle ilde og vige bort fra den Vej, jeg har anvist eder, og Ulykken skal ramme eder i de kommende Tider, fordi I gør, hvad der er ondt i HERRENS Øjne, og krænker ham med eders Hænders Gerning.«
Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
30 Derpaa fremsagde Moses denne Sang fra Ende til anden for hele Israels Forsamling:
Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli:

< 5 Mosebog 31 >