< 5 Mosebog 24 >

1 Naar en Mand tager en Kvinde til Ægte, og hun ikke vinder hans Yndest, fordi han finder noget ved hende, der vækker Ubehag hos ham, og han skriver hende et Skilsmissebrev og giver hende det i Hænde og sender hende ud af sit Hjem,
Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
2 saa maa hun efter at have forladt hans Hjem gaa hen og gifte sig med en anden Mand;
tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
3 faar denne anden Mand ogsaa Uvilje imod hende og skriver hende et Skilsmissebrev og giver hende det i Hænde og sender hende ud af sit Hjem, eller dør den anden Mand, der havde taget hende til Ægte,
àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
4 saa har hendes første Mand, som havde sendt hende bort, ikke Ret til igen at tage hende til Hustru, efter at hun er blevet uren. Thi det er HERREN en Vederstyggelighed, og du maa ikke bringe Brøde over det Land, HERREN din Gud vil give dig i Eje.
nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
5 Naar en Mand nylig har taget sig en Hustru, skal han ikke drage med i Krig, og der skal ikke paalægges ham nogen som helst Forpligtelse; han skal have Frihed til at blive hjemme et Aar og glæde sin Hustru, som han har ægtet.
Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
6 Man maa ikke tage en Haandkværn i Pant, heller ikke den øverste Møllesten; thi det var at tage Livet selv i Pant.
Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
7 Naar nogen gribes i at stjæle en af sine Brødre blandt Israeliterne og gør ham Fortræd eller sælger ham, da skal en saadan Tyv lade sit Liv. Du skal udrydde det onde af din Midte.
Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
8 Tag dig i Vare med Spedalskhed, saa du meget omhyggeligt handler efter alt, hvad Levitpræsterne lærer eder; som jeg har paabudt dem, skal I omhyggeligt handle.
Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
9 Kom i Hu, hvad HERREN din Gud gjorde ved Mirjam undervejs, da I drog bort fra Ægypten.
Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
10 Naar du yder din Næste et Laan, maa du ikke gaa ind i hans Hus for at tage Pant af ham.
Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
11 Du skal blive staaende udenfor, og den Mand, du yder Laanet, skal bringe Pantet ud til dig.
Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
12 Hvis han er en fattig Mand, maa du ikke lægge dig til Hvile med hans Pant;
Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
13 ved Solnedgang skal du give ham Pantet tilbage, for at han kan lægge sig til Hvile i sin Kappe. Da velsigner han dig derfor, og du staar retfærdiggjort for HERREN din Guds Aasyn.
Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
14 Du maa ikke forurette en nødlidende, fattig Daglejer, hvad enten han hører til dine Brødre eller de fremmede inden dine Porte nogetsteds i dit Land.
Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
15 Dag for Dag skal du give ham hans Løn, saa at Solen ikke gaar ned derover, thi han er nødlidende og venter med Længsel derpaa. Ellers raaber han til HERREN over dig, og du paadrager dig Skyld.
San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
16 Fædre skal ikke lide Døden for Børns Skyld, og Børn skal ikke lide Døden for Fædres Skyld. Enhver skal lide Døden for sin egen Synd.
Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
17 Du maa ikke bøje Retten for den fremmede og den faderløse, og du maa ikke tage Enkens Klædning i Pant.
Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
18 Men kom i Hu, at du var Træl i Ægypten, og at HERREN din Gud udløste dig derfra. Derfor byder jeg dig at handle saaledes.
Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
19 Naar du bjærger din Høst paa din Mark og glemmer et Neg paa Marken, maa du ikke vende tilbage for at hente det; det skal tilfalde den fremmede, den faderløse og Enken, for at HERREN din Gud kan velsigne dig i alt, hvad du tager dig for.
Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
20 Naar du slaar dine Oliven ned, maa du ikke bagefter gennemsøge Grenene; den fremmede, den faderløse og Enken skal det tilfalde.
Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
21 Naar du høster din Vin, maa du ikke holde Efterhøst; den fremmede, den faderløse og Enken skal det tilfalde.
Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
22 Kom i Hu, at du selv var Træl i Ægypten; derfor byder jeg dig at handle saaledes.
Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.

< 5 Mosebog 24 >