< 5 Mosebog 17 >
1 Du maa ikke ofre HERREN din Gud en Okse eller et Stykke Smaakvæg, som har nogen Lyde, nogen som helst Fejl; thi det er HERREN din Gud en Vederstyggelighed.
Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
2 Naar der et steds i din Midte inden dine Porte, som HERREN din Gud vil give dig, findes nogen, Mand eller Kvinde, der gør, hvad der er ondt i HERREN din Guds Øjne, og overtræder hans Pagt,
Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
3 idet han gaar hen og dyrker andre Guder og tilbeder dem, Solen, Maanen eller Himmelens hele Hær, hvad jeg ikke har paalagt eder,
èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
4 og det bliver dig meldt, saa du faar det at høre, da skal du omhyggeligt undersøge Sagen, og hvis det viser sig, at det virkelig forholder sig saaledes, at der er øvet en saadan Vederstyggelighed i Israel,
tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
5 da skal du føre Manden eller Kvinden, som har øvet denne Udaad, ud til Byporten, hvad enten det nu er en Mand eller en Kvinde, og stene dem til Døde.
Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
6 Paa to eller tre Vidners Udsagn skal Dødsdommen udføres; den maa ikke udføres paa et enkelt Vidnes Udsagn.
Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
7 Vidnernes Haand skal først løfte sig imod ham for at slaa ham ihjel, siden alle de andres Haand. Saaledes skal du udrydde det onde af din Midte.
Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
8 Naar en Retssag angaaende Blodsudgydelse eller et Ejendomsspørgsmaal eller Legemsskade, naar i det hele en eller anden Retstrætte inden dine Porte er dig for vanskelig, skal du staa op og drage til det Sted, HERREN din Gud udvælger,
Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
9 og henvende dig til Levitpræsterne og den Dommer, som er der til den Tid, og spørge dem til Raads, saa skal de give dig til Kende, hvorledes der skal dømmes i Sagen.
Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
10 Og du skal rette dig efter den Afgørelse, de giver dig til Kende fra det Sted, HERREN udvælger, og omhyggeligt handle efter alt det, som de lærer dig.
Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
11 Efter den Vejledning, de giver dig, og efter den Kendelse, de kundgør dig, skal du handle uden at vige til højre eller venstre fra, hvad de giver dig til Kende.
Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
12 Og den Mand, der formaster sig til ikke at lyde Præsten, som gør Tjeneste der for HERREN din Gud, eller Dommeren, den Mand skal dø, og du skal udrydde det onde af Israel.
Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
13 Og det skal høres i hele Folket, saa de gribes af Frygt og ikke mere handler formasteligt.
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
14 Naar du kommer ind i det Land, HERREN din Gud vil give dig, og faar taget det i Besiddelse og fæstet Bo der, og du saa faar den Tanke, at du vil have en Konge over dig ligesom alle de andre Folk rundt om dig,
Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
15 saa maa du kun sætte den Mand til Konge over dig, som HERREN din Gud udvælger. Af dine Brødres Midte skal du tage dig en Konge. En fremmed, der ikke hører til dine Brødre, maa du ikke tage til Konge over dig.
Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
16 Kun maa han ikke holde mange Heste og sende Folket tilbage til Ægypten for at skaffe sig mange Heste; thi HERREN har jo sagt til eder: »I maa ikke mere vende tilbage ad den Vej!«
Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
17 Heller ikke maa han have mange Hustruer, for at hans Hjerte ikke skal forledes til Frafald, og han maa ikke samle sig Sølv og Guld i Overflod.
Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
18 Naar han saa har sat sig paa Tronen, skal han skaffe sig en Afskrift af denne Lov hos Levitpræsterne;
Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
19 og han skal have den hos sig og læse i den alle sine Levedage, at han kan lære at frygte HERREN sin Gud, saa han tager Vare paa alle denne Lovs Ord og paa disse Anordninger og holder dem,
Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
20 for at hans Hjerte ikke skal hovmode sig over hans Brødre eller vige til højre eller venstre fra Budet, at han og hans Sønner i lange Tider maa have Kongemagten i Israel.
Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.