< 5 Mosebog 10 >

1 Ved denne Tid sagde HERREN til mig: »Tilhug dig to Stentavler ligesom de forrige og stig op til mig paa Bjerget; lav dig ogsaa en Ark af Træ!
Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Gbé wàláà òkúta méjì bí i ti àkọ́kọ́ kí o sì gòkè tọ̀ mí wá. Kí o sì tún fi igi kan àpótí kan.
2 Saa vil jeg paa Tavlerne skrive de Ord, der stod paa de forrige Tavler, som du knuste, og du skal lægge dem ned i Arken!«
Èmi yóò sì kọ ọ̀rọ̀ tí ó wà lára wàláà àkọ́kọ́ tí ìwọ fọ́, sára wàláà wọ̀nyí. Ìwọ yóò sì fi wọ́n sínú àpótí náà.”
3 Da lavede jeg en Ark af Akacietræ og tilhuggede to Stentavler ligesom de forrige og steg op paa Bjerget med de to Tavler i Haanden.
Mo sì kan àpótí náà pẹ̀lú igi kasia, mo sì gbẹ́ wàláà òkúta méjì náà jáde bí i ti ìṣáájú. Mo sì gòkè lọ pẹ̀lú wàláà méjèèjì lọ́wọ́ mí.
4 Og han skrev paa Tavlerne det samme, som var skrevet første Gang, de ti Ord, som HERREN havde talt til eder paa Bjerget ud fra Ilden, den Dag I var forsamlet. Og HERREN overgav mig dem.
Olúwa tún ohun tí ó ti kọ tẹ́lẹ̀ kọ sórí wàláà wọ̀nyí. Àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó ti sọ fún un yín lórí òkè, láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀. Olúwa sì fi wọ́n fún mi.
5 Saa vendte jeg mig bort og steg ned fra Bjerget og lagde Tavlerne i den Ark, jeg havde lavet, og der blev de liggende, som HERREN havde paalagt mig.
Mo sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà, mo sì ki àwọn wàláà òkúta náà sínú àpótí tí mo ti kàn, bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi, wọ́n sì wà níbẹ̀ di ìsinsin yìí.
6 Og Israeliterne drog fra Be'erot-bene-Ja'akan til Mosera. Der døde Aron, og der blev han jordet, og hans Søn Eleazar blev Præst i hans Sted.
(Àwọn ará Israẹli sì gbéra láti kànga àwọn ará Jaakani dé Mosera. Níbí ni Aaroni kú sí, tí a sì sin ín, Eleasari ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ bí i àlùfáà.
7 Derfra drog de til Gudgoda og fra Gudgoda til Jotbata, en Egn med Vandløb.
Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti rìn lọ sí Gudgoda, títí dé Jotbata, ilẹ̀ tí o kún fún odò tí ó ń sàn.
8 Paa den Tid udskilte HERREN Levis Stamme til at bære HERRENS Pagts Ark og til at staa for HERRENS Aasyn og tjene ham og velsigne i hans Navn, som det sker den Dag i Dag.
Ní ìgbà yìí ni Olúwa yan àwọn ẹ̀yà Lefi láti máa ru àpótí ẹ̀rí Olúwa, láti máa dúró níwájú Olúwa láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, àti láti fi orúkọ Olúwa súre bí wọ́n ti ń ṣe títí di òní yìí.
9 Derfor fik Levi ikke Arvelod og Del sammen med sine Brødre; HERREN selv er hans Arvelod, som HERREN din Gud lovede ham.
Ìdí nìyí tí àwọn ẹ̀yà Lefi kò fi ní ìpín tàbí ogún kan láàrín àwọn arákùnrin wọn. Olúwa ni ogún wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti sọ fún un yín.)
10 Men jeg blev paa Bjerget lige saa længe som forrige Gang, fyrretyve Dage og fyrretyve Nætter, og HERREN bønhørte mig ogsaa denne Gang; HERREN vilde ikke tilintetgøre dig.
Mo tún dúró ní orí òkè náà fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, bí mo ti ṣe ní ìgbà àkọ́kọ́, Olúwa sì gbọ́ tèmi ní àkókò yìí bákan náà. Kì í ṣe ìfẹ́ rẹ̀ láti run yín.
11 Da sagde HERREN til mig: »Rejs dig og bryd op i Spidsen for Folket, for at de kan komme og tage det Land i Besiddelse, jeg tilsvor deres Fædre at ville give dem!«
Olúwa sọ fún mi pé, “Lọ darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọ̀nà wọn, kí wọn bá à lè wọ ilẹ̀ náà, kí wọn sì gba ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba wọn láti fún wọn.”
12 Og nu, Israel! Hvad andet kræver HERREN din Gud af dig, end at du skal frygte HERREN din Gud, saa du vandrer paa alle hans Veje, og at du skal elske ham og tjene HERREN din Gud af hele dit Hjerte og hele din Sjæl,
Nísinsin yìí ìwọ Israẹli, kín ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè lọ́wọ́ rẹ? Bí kò ṣe kí ìwọ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ àti láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti fẹ́ràn rẹ̀, láti fi gbogbo ọkàn rẹ sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ọkàn àti àyà rẹ,
13 saa du holder HERRENS Bud og Anordninger, som jeg i Dag paalægger dig, for at det maa gaa dig vel.
àti láti máa kíyèsi àṣẹ àti ìlànà Olúwa tí mo ń fún ọ lónìí, fún ìre ara à rẹ.
14 Se, Himmelen og Himlenes Himle og Jorden med alt, hvad der er paa den, tilhører HERREN din Gud;
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ni ọ̀run àní àwọn ọ̀run tó ga ju ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.
15 men kun til dine Fædre fattede han Velbehag, saa han elskede dem, og eder, deres Afkom, udvalgte han af alle Folkeslag, som det nu er kendeligt.
Síbẹ̀ Olúwa sì tún fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn fún àwọn baba ńlá a yín, Ó sì fẹ́ wọn Ó sì yan ẹ̀yin ọmọ wọn láti borí gbogbo orílẹ̀-èdè títí di òní.
16 Saa omskær nu eders Hjerters Forhud og gør ikke mer eders Nakker stive!
Ẹ kọ ọkàn yín ní ilà, kí ẹ má sì ṣe jẹ́ olórí kunkun mọ́ láti òní lọ.
17 Thi HERREN eders Gud er Gudernes Gud og Herrernes Herre, den store, vældige, forfærdelige Gud, som ikke viser Personsanseelse eller lader sig købe,
Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín, ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn olúwa. Ọlọ́run alágbára, tí ó tóbi tí ó sì lẹ́rù, tí kì í ṣe ojúsàájú kì í sì í gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
18 som skaffer den faderløse og Enken Ret og elsker den fremmede og giver ham Brød og klæder.
Ó máa ń gbẹjọ́ aláìní baba àti opó rò, Ó fẹ́ràn àjèjì, Òun fi aṣọ àti oúnjẹ fún wọn.
19 Derfor skal I elske den fremmede, thi I var selv fremmede i Ægypten.
Ẹ gbọdọ̀ fẹ́ràn àwọn àjèjì, torí pé ẹ̀yin pẹ̀lú ti jẹ́ àjèjì rí ní Ejibiti.
20 HERREN din Gud skal du frygte: ham skal du tjene, ved ham skal du holde fast, og ved hans Navn skal du sværge!
Ẹ bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ sì máa sìn ín. Ẹ dìímú ṣinṣin, kí ẹ sì búra ní orúkọ rẹ̀.
21 Han er din Lovsang, og han er din Gud, han, som har gjort disse store og forfærdelige Ting imod dig, som du med egne Øjne har set!
Òun ni ìyìn in yín, Òun sì ni Ọlọ́run yín, tí ó ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu ńlá àti ohun ẹ̀rù, tí ẹ fojú ara yín rí.
22 Halvfjerdsindstyve i Tal drog dine Fædre ned til Ægypten, og nu har HERREN din Gud gjort dig talrig som Himmelens Stjerner!
Àádọ́rin péré ni àwọn baba ńlá a yín tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín ti mú un yín pọ̀ sí i ní iye bí àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run.

< 5 Mosebog 10 >