< Anden Krønikebog 34 >

1 Josias var otte Aar gammel, da han blev Konge, og han herskede en og tredive Aar i Jerusalem.
Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
2 Han gjorde, hvad der var ret i HERRENS Øjne, og vandrede i sin lader Davids Spor uden al vige til højre eller venstre.
Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
3 I sit ottende Regeringsaar, endnu ganske ung, begyndte han at søge sin Fader Davids Gud, og i det tolvte Aar begyndte han at rense Juda og Jerusalem for Offerhøjene, Asjerastøtterne og de udskaarne og støbte Billeder.
Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
4 I hans Paasyn nedrev man Ba'alernes Altre; Solstøtterne, der stod oven paa dem, huggede han om, og Asjerastøtterne og de udskaarne og støbte Billeder lod han sønderhugge og knuse og strø ud paa deres Grave, som havde ofret til dem;
Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
5 Benene af Præsterne lod han brænde paa deres Altre. Saaledes rensede han Juda og Jerusalem.
Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
6 Men ogsaa i Byerne i Manasse, Efraim og Simeon og lige til Naftali, rundt om i deres Ruinhobe,
Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
7 lod han Altrene nedbryde, Asjerastøtterne og Gudebillederne sønderslaa og knuse og alle Solstøtterne omhugge i hele Israels Land; saa vendte han tilbage til Jerusalem.
Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
8 I sit attende Regeringsaar gav han sig til at rense Landet og Templet; han sendte Sjafan, Azaljas Søn, Byens Øverste Ma'aseja og Kansleren Joa, Joahaz's Søn, hen for at istandsætte HERREN hans Guds Hus.
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
9 Da de kom til Ypperstepræsten Hilkija, afleverede de Pengene, der var kommet ind til Guds Hus, dem, som Leviterne, der holdt Vagt ved Tærskelen, havde samlet hos Manasse og Efraim og det øvrige Israel og hos hele Juda og Benjamin og Jerusalems Indbyggere;
Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
10 de overgav Pengene til dem, der stod for Arbejdet, dem, der havde Tilsyn med HERRENS Hus; og de, der stod for Arbejdet paa HERRENS Hus, brugte dem til at udbedre og istandsætte Templet,
Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
11 idet de overgav dem til Tømrerne og Bygningsmændene til Indkøb af tilhugne Sten og Tømmer til Tværbjælker og til Bjælker i de Bygninger, Judas Konger havde ødelagt.
Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
12 Folkene udførte Arbejdet samvittighedsfuldt; og Tilsynet med dem var overdraget Leviterne Jahat og Obadja af Merariterne og Zekarja og Mesjullam af Kehatiternes Sønner, for at de skulde lede dem.
Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
13 Og Leviterne havde Tilsyn med Lastdragerne og ledede alle dem, der havde med de forskellige Arbejder at gøre. Og af Leviterne var nogle Skrivere, Fogeder og Dørvogtere.
Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
14 Men da de tog Pengene frem, der var kommet ind til HERRENS Hus, fandt Præsten Hilkija Bogen med HERRENS Lov, som var givet ved Moses;
Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
15 og Hilkija tog til Orde og sagde til Statsskriveren Sjafan: »Jeg har fundet Lovbogen i HERRENS Hus!« Og Hilkija gav Sjafan Bogen,
Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
16 og Sjafan bragte Bogen til Kongen og aflagde der hos Beretning for ham, idet han sagde: »Alt, hvad dine Trælle er sat til, udfører de;
Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
17 de har taget de Penge frem, der fandtes i HERRENS Hus, og givet dem til Tilsynsmændene og dem, der staar for Arbejdet.«
Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
18 Derpaa gav Statsskriveren Sjafan Kongen den Meddelelse: »Præsten Hilkija gav mig en Bog.« Og Sjafan læste op af den for Kongen.
Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
19 Men da Kongen hørte, hvad der stod i Loven, sønderrev han sine Klæder;
Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
20 og Kongen bød Hilkija, Ahikam. Sjafans Søn, Abdon, Mikas Søn, Statsskriveren Sjafan og Kongens Tjener Asaja:
Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
21 »Gaa hen og raadspørg HERREN paa mine Vegne og paa deres, som er blevet tilovers i Israel og Juda, om Indholdet af denne Bog, der er fundet; thi stor er Vreden, der er blusset op hos HERREN imod os, fordi vore Fædre ikke adlød HERRENS Ord og handlede nøje efter, hvad der staar skrevet i denne Bog!«
“Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
22 Hilkija og de andre, Kongen sendte af Sted, gik da hen og talte derom med Profetinden Hulda, som var gift med Sjallum, Opsynsmanden over Tøjet, en Søn af Hasras Søn Tokhat, og som boede i Jerusalem i den nye Bydel.
Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
23 Hun sagde til dem: »Saa siger HERREN, Israels Gud: Sig til den Mand, der sendte eder til mig:
Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
24 Saa siger HERREN: Se, jeg vil bringe Ulykke over dette Sted og dets Indbyggere, alle de Forbandelser, der er optegnet i den Bog, som er læst op for Judas Konge,
‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
25 til Straf for at de har forladt mig og tændt Offerild for andre Guder, saa de krænkede mig med alt deres Hænders Værk, og min Vrede vil blusse op mod dette Sted uden at slukkes!
Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
26 Men til Judas Konge, der sendte eder for at raadspørge HERREN, skal I sige saaledes: Saa siger HERREN, Israels Gud: De Ord, du har hørt, staar fast;
Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
27 men efterdi dit Hjerte bøjede sig og du ydmygede dig for Gud, da du hørte hans Ord mod dette Sted og dets Indbyggere, og efterdi du ydmygede dig for mit Aasyn og sønderrev, dine Klæder og græd for mit Aasyn, saa har ogsaa jeg hørt dig, lyder det fra HERREN!
Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
28 Saa vil jeg da lade dig samles til dine Fædre, og du skal samles til dem i Fred i din Grav, uden at dine Øjne faar al den Ulykke at se, som jeg vil bringe over dette Sted og dets Beboere!« Det Svar bragte de til Kongen.
Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
29 Da sendte Kongen Bud og lod alle Judas og Jerusalems Ældste kalde sammen.
Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
30 Derpaa gik Kongen op i HERRENS Hus, fulgt af alle Judas Mænd og Jerusalems Indbyggere, Præsterne, Leviterne og alt Folket, store og smaa, og han forelæste dem alt, hvad der stod i Pagtsbogen, som var fundet i HERRENS Hus.
Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
31 Derpaa stillede Kongen sig paa sin Plads og sluttede Pagt for HERRENS Aasyn om, at de skulde holde sig til HERREN og holde hans Bud, Vidnesbyrd og Anordninger af hele deres Hjerte og hele deres Sjæl, for at han kunde opfylde Pagtens Ord, dem, der var skrevet i denne Bog.
Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
32 Og han lod alle dem, der var til Stede i Jerusalem, indgaa Pagten; og Jerusalems Indbyggere handlede efter Guds, deres Fædres Guds, Pagt.
Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
33 Derpaa fjernede Josias alle Vederstyggelighederne fra alle de Landsdele, der tilhørte Israeliterne, og sørgede for, at enhver i Israel dyrkede HERREN deres Gud. Saa længe han levede, veg de ikke fra HERREN, deres Fædres Gud.
Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.

< Anden Krønikebog 34 >