< Anden Krønikebog 19 >

1 Kong Josafat af Juda derimod vendte uskadt hjem igen til sit Palads i Jerusalem.
Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
2 Da traadte Seeren Jehu, Hananis Søn, frem for ham, og han sagde til Kong Josafat: »Skal man hjælpe de ugudelige? Elsker du dem, der hader HERREN? For den Sags Skyld er HERRENS Vrede over dig!
Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
3 Noget godt er der dog hos dig, thi du har udryddet Asjererne af Landet, og du har vendt dit Hjerte til at søge Gud.«
Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
4 Josafat blev nu i Jerusalem, Saa drog han atter ud blandt Folket fra Be'ersjeba til Efraims Bjerge og førte dem tilbage til HERREN, deres Fædres Gud.
Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
5 Og han indsatte Dommere i Landet i hver enkelt af de befæstede Byer i Juda.
Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
6 Og han sagde til Dommerne: »Se til, hvad I gør, thi det er ikke for Mennesker, men for HERREN, I fælder Dom, og han er hos eder, naar I afsiger Kendelser.
Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
7 Derfor være HERRENS Frygt over eder! Vær varsomme med, hvad I foretager eder, thi hos HERREN vor Gud er der hverken Uret eller Personsanseelse, ej heller tager han imod Bestikkelse!«
Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
8 Ogsaa i Jerusalem indsatte Josafat nogle af Leviterne, Præsterne og Overhovederne for Israels Fædrenehuse til at dømme i HERRENS Sager og i Stridigheder mellem Jerusalems Indbyggere.
Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
9 Og han bød dem: »Saaledes skal I gøre i HERRENS Frygt, i Sanddruhed og med redeligt Hjerte:
Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
10 Hver Gang der forelægges eder en Retssag af eders Brødre, der bor i deres Byer, hvad enten det drejer sig om Blodskyld eller om Love, Anordninger og Lovbud, skal I hjælpe dem til Rette, at de ikke skal paadrage sig Skyld for HERREN, saa der kommer Vrede over eder og eders Brødre; gør saaledes for ikke at paadrage eder Skyld.
Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
11 I alle HERRENS Sager skal Ypperstepræsten Amarja være eders foresatte, i alle Kongens Sager Zebadja, Jisjmaels Søn, Fyrsten i Judas Hus; og Leviterne staar eder til Tjeneste som Retsskrivere. Gaa nu frimodigt til Værket, HERREN vil være med enhver, der gør sin Pligt.«
“Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”

< Anden Krønikebog 19 >