< Anden Krønikebog 16 >
1 Men i Asas seks og tredivte Regeringsaar drog Kong Ba'sja af Israel op imod Juda og befæstede Rama for at hindre, at nogen af Kong Asa af Judas Folk drog ud og ind.
Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
2 Da tog Asa Sølv og Guld ud af Skatkamrene i HERRENS Hus og i Kongens Palads og sendte det til Kong Benhadad af Aram, som boede i Darmaskus, idet han lod sige:
Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
3 »Der bestaar en Pagt mellem mig og dig og mellem min Fader og din Fader; her sender jeg dig en Gave af Sølv og Guld; bryd derfor din Pagt med Kong Ba'sja af Israel, saa at han nødes til at drage bort fra mig!«
“Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
4 Benhadad gik ind paa Kong Asas Forslag og sendte sine Hærførere mod Israels Byer og indtog Ijjon, Dan, Abel-Majim og Forraadshusene i Naftalis Byer.
Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
5 Da Ba'sja hørte det, opgav han at befæste Rama og standsede Arbejdet.
Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
6 Men Kong Asa tog hele Juda til at føre Stenene og Træværket, som Ba'sja havde brugt ved Befæstningen af Rama, bort, og han befæstede dermed Geba og Mizpa.
Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
7 Paa den Tid kom Seeren Hanani til Kong Asa af Juda og sagde til ham: »Fordi du søgte Støtte hos Aramæerkongen og ikke hos HERREN din Gud, skal Aramæerkongens Hær slippe dig af Hænde!
Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
8 Var ikke Kusjiterne og Libyerne en vældig Hær med en vældig Mængde Vogne og Ryttere? Men da du søgte Støtte hos HERREN, gav han dem i din Haand!
Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
9 Thi HERRENS Øjne skuer omkring paa hele Jorden, og han viser sig stærk til at hjælpe dem, hvis Hjerte er helt med ham. I denne Sag har du handlet som en Daare; thi fra nu af skal du altid ligge i Krig!«
Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
10 Men Asa blev fortørnet paa Seeren og satte ham i Huset med Blokken, thi han var blevet vred paa ham derfor. Asa for ogsaa haardt frem mod nogle af Folket paa den Tid.
Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
11 Asas Historie fra først til sidst staar jo optegnet i Bogen om Judas og Israels Konger.
Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
12 I sit ni og tredivte Regeringsaar fik Asa en Sygdom i Fødderne, og Sygdommen blev meget alvorlig. Heller ikke under sin Sygdom søgte han dog HERREN, men Lægerne.
Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
13 Saa lagde Asa sig til Hvile hos sine Fædre og døde i sit een og fyrretyvende Regeringsaar.
Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
14 Man jordede ham i en Grav, han havde ladet sig udhugge i Davidsbyen, og lagde ham paa et Leje, som man havde fyldt med vellugtende Urter og Stoffer, tillavet som Salve, og tændte et vældigt Baal til hans Ære.
wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.