< Første Kongebog 17 >

1 Tisjbiten Elias fra Tisjbe i Gilead sagde til Akab: »Saa sandt HERREN, Israels Gud, lever, han, for hvis Aasyn jeg staar, i de kommende Aar skal der ikke falde Dug eller Regn uden paa mit udtrykkelige Bud!«
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 Derpaa kom HERRENS Ord til ham saaledes:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 »Gaa bort herfra og begiv dig østerpaa og hold dig skjult ved Bækken Krit østen for Jordan;
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 du skal drikke af Bækken, og Ravnene har jeg paalagt at sørge for Føde til dig der.«
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 Da gik han og gjorde efter HERRENS Ord, han gik hen og tog Bolig ved Bækken Krit østen for Jordan;
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 og Ravnene bragte ham Brød om Morgenen og Kød om Aftenen, og han drak af Bækken.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Men nogen Tid efter tørrede Bækken ud, eftersom der ingen Regn faldt i Landet.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 Da kom HERRENS Ord til ham saaledes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 »Begiv dig til Zarepta, som hører til Zidon, og tag Bolig der; se, jeg har paalagt en Enke der at sørge for Føde til dig.«
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 Saa begav han sig til Zarepta, og da han kom til Byens Port, fik han Øje paa en Enke, som var ved at sanke Brænde, og raabte til hende: »Hent mig lidt Vand i et Kar, for at jeg kan drikke!«
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 Og da hun gik bort for at hente det, raabte han efter hende: »Tag ogsaa et Stykke Brød med til mig!«
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 Men hun svarede: »Saa sandt HERREN din Gud lever, jeg ejer ikke Brød, men kun en Haandfuld Mel i Krukken og lidt Olie i Dunken; jeg var netop ved at sanke et Par Stykker Brænde for at gaa hjem og tillave det til mig og min Søn; og naar vi har spist det, maa vi dø!«
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Da sagde Elias til hende: »Frygt ikke! Gaa hjem og gør, som du siger; men lav først et lille Brød deraf til mig og bring mig det; siden kan du lave noget til dig selv og din Søn!
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Thi saa siger HERREN, Israels Gud: Melkrukken skal ikke blive tom, og Olien i Dunken skal ikke slippe op, før den Dag HERREN sender Regn over Jorden!«
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 Da gik hun og gjorde, som Elias sagde; og baade hun og han og hendes Søn havde noget at spise en Tid lang.
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Melkrukken blev ikke tom, og Olien i Dunken slap ikke op, efter det Ord HERREN havde talet ved Elias.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 Men nogen Tid efter blev Kvindens, Husets Ejerindes, Søn syg, og hans Sygdom tog heftigt til, saa der til sidst ikke mere var Liv i ham.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Da sagde hun til Elias: »Hvad har jeg med dig at gøre, du Guds Mand! Er du kommet for at bringe min Synd i Erindring og volde min Søns Død?«
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 Men han svarede hende: »Lad mig faa din Søn!« Og han tog ham fra hendes Skød og bar ham op i Stuen paa Taget, hvor han boede, og lagde ham paa sin Seng.
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 Saa raabte han til HERREN: »HERRE min Gud, vil du virkelig handle saa ilde mod den Enke; i hvis Hus jeg er Gæst, at du lader hendes Søn dø?«
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 Derpaa strakte han sig tre Gange hen over Drengen og raabte til HERREN: »HERRE min Gud, lad dog Drengens Sjæl vende tilbage!«
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 Og HERREN hørte Elias's Røst; Drengens Sjæl vendte tilbage, saa han blev levende.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Saa tog Elias Drengen og bragte ham fra Stuen paa Taget ned i Huset og gav hans Moder ham, idet han sagde: »Se, din Søn lever!«
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 Da sagde Kvinden til Elias: »Nu ved jeg vist, at du er en Guds Mand, og at HERRENS Ord i din Mund er Sandhed.«
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”

< Første Kongebog 17 >